Dataset Viewer
Auto-converted to Parquet
labels
class label
5 classes
headline
stringlengths
38
163
text
stringlengths
74
42.6k
headline_text
stringlengths
142
42.7k
url
stringlengths
35
53
2health
Tí ìgbẹ́ tóò ń yà bá rí báyìí? Àìsàn jẹjẹrẹ ikùn ló dé o! Wo bí wàá ṣe dàa mọ̀
Ìlera ní Yorùbá pè ní oògùn ọrọ̀, àláfíà ẹni kọ̀ọ̀kan wa kò sì ní di fíafìa. Onírúurú àìsàn ló wà lóde òní tó jẹ́ wí pé àìní àkíyèsí àwọn ènìyàn tó ló jẹ́ kí ẹlòmíràn bá àìsàn náà lọ. Lára àwọn àìsàn tí àwọn ènìyàn kò le tètè kọbi ara sí ni àìsàn jẹjẹrẹ inú ikún nítorí àwọn nǹkan tó rọ̀ mọ. Àìsàn jẹjẹrẹ ikùn ni jẹjẹrẹ tó máa ń mú ènìyàn nínú ìfun. Òhun ni àwọn olóyìnbó ń pè ní Bowel cancer tàbí Colon/Rectal cancer. Dame Deborah James, tó pàdánù ẹ̀mí rẹ̀ sọ́wọ́ jẹjẹrẹ ikùn lẹ́ni ogójì ọdún ní UK rọ àwọn ènìyàn ṣaájú kó tó kú láti máa yẹ ìgbẹ́ wọn wò nígbàkúgbà tí wọ́n bá ti ya ìgbẹ́. Àwọn àpẹẹrẹ mẹ́ta ló ṣe pàtàkì jùlọ láti mọ̀ bóyá ènìyàn ní àìsàn jẹjẹrẹ ikùn. Kò túmọ̀ sí pé tí àwọn nǹkan wọ̀nyí bá ń ṣe ènìyàn onítọ̀hún ti ní àìsàn jẹjẹrẹ ikún àmọ́ ó ṣe pàtàkì fún irú ẹni bẹ́ẹ̀ láti lọ rí àwọn dókítà fún àyẹ̀wò tó péye pàápàá tó bá ti lé ní ọ̀sẹ̀ mẹ́ta tí àwọn àpẹẹrẹ yìí bá ti ń wà lára. Àwọn nǹkan náà nìyí: Àwọn àpẹẹrẹ mìíràn ni Gẹ́gẹ́ bí àwọn àìsàn jẹjẹrẹ yòókù, tí ènìyàn bá tètè mọ̀ wí pé ó wà lára, ó ṣeéṣe kí ènìyàn rí ìtọ́jú tó péye gbà lórí àìsàn náà. Bákan náà ni àìsàn jẹjẹrẹ ikùn lé ṣokùnfà kí ènìyàn má rì í ìgbẹ́ yà, tó sì lè dá àárẹ̀ sára ènìyàn. Lára ohun tí ó dára kí ènìyàn máa ṣe ni yíyẹ ìgbẹ́ ènìyàn tí ènìyàn bá ti ya ìgbẹ́ tán láti mọ bí ó ṣe rí nítorí bí ìgbẹ́ ènìyàn bá ṣe rí jẹ́ ọ̀nà láti fi mọ ìlera ènìyàn. Wò bóyá kò sí ẹ̀jẹ̀ nínú ìgbẹ́ rẹ tàbí ní ìdí rẹ. Ìgbà mìíràn tó jẹ́ wí pé jẹ̀dí ló máa ń fa kí ẹ̀jẹ̀ wà nínú ìgbẹ́ ènìyàn àmọ́ àìsàn jẹjẹrẹ ikùn náà máa ń fà á. Kò ì tíì sí ìwádìí kankan tó fi ohun tó ń fa àìsàn jẹjẹrẹ ikùn múlẹ̀ àmọ́ àwọn nǹkan wà tó le mú kí àìsàn yìí tètè dàgbà lára. Gẹ́gẹ́ bí ibi tí ìwádìí mọ báyìí, àìsàn jẹjẹrẹ kò le ràn láti ìyá tàbí bàbá sọ́mọ àmọ́ ó ṣe pàtàkì kí ẹni tí wọ́n bá ti ní àìsàn yìí ní ìran rẹ̀ fi tó àwọn dókítà létí. Bákan náà ẹni tó bá ní àìsàn Lynch syndrome ṣeéṣe kó ní àìsàn jẹjẹrẹ ikùn ṣùgbọ́n ó ṣe é mójútó tí àwọn dókítà bá tètè mọ̀. Bákan náà tí ènìyàn bá ń gbé ìgbé ayé àláfíà, tó ń jẹ àwọn oúnjẹ tó le ṣe ara ní àǹfàní le mórí bọ́ lọ́wọ́ àìsàn jẹjẹrẹ. Colonoscopy jẹ́ ọ̀nà tí wọ́n máa ń fi ẹ̀rọ ayàwòrán wo inú ènìyàn láti mọ irú nǹkan tó wà níbẹ̀. Wọ́n le fi ẹ̀rọ yìí mọ̀ tí ènìyǹ bá ní àìsàn jẹjẹrẹ ikùn. Àìsàn jẹjẹrẹ ṣe é tọ́jú tí wọ́n bá tètè ṣàwárí rẹ̀ nígbà tó bá ṣẹ̀ṣẹ̀ bẹ̀rẹ̀. Ìdá àádọ́sàn-án ènìyàn tí wọ́n bá tètè mọ̀ wí pé ó ní àìsàn ló ní àǹfàní láti lo ọdún márùn-ún sí láyé nígbà kan àmọ́ wọ́n ní ẹni náà le lo ọdún mẹ́wàá sí báyìí. Kò sí ìpele tí àìsàn náà bá wà tí kò sí ìtọ́jú fún gẹ̀gẹ̀ bí àwọn onímọ̀ ṣe ṣọ. Ìpele mẹ́rin ni àìsàn jẹjẹrẹ máa ń wà A lérò wí pé ẹ ti di ohun kan tàbí òmíràn mú, tí ẹ ó sì mú ìlera ara yín ní ọ̀kúnkúndùn, ẹ ò ní máa sáré dìde kúrò ní yàrá ìgbọ̀nsẹ̀ tí ẹ bá ti yàgbẹ́ tán. Yẹ ìgbẹ́ rẹ wò kí o tó kúrò nílé ìgbọ̀nsẹ̀ fún ìlera ara rẹ.
Tí ìgbẹ́ tóò ń yà bá rí báyìí? Àìsàn jẹjẹrẹ ikùn ló dé o! Wo bí wàá ṣe dàa mọ̀ Ìlera ní Yorùbá pè ní oògùn ọrọ̀, àláfíà ẹni kọ̀ọ̀kan wa kò sì ní di fíafìa. Onírúurú àìsàn ló wà lóde òní tó jẹ́ wí pé àìní àkíyèsí àwọn ènìyàn tó ló jẹ́ kí ẹlòmíràn bá àìsàn náà lọ. Lára àwọn àìsàn tí àwọn ènìyàn kò le tètè kọbi ara sí ni àìsàn jẹjẹrẹ inú ikún nítorí àwọn nǹkan tó rọ̀ mọ. Àìsàn jẹjẹrẹ ikùn ni jẹjẹrẹ tó máa ń mú ènìyàn nínú ìfun. Òhun ni àwọn olóyìnbó ń pè ní Bowel cancer tàbí Colon/Rectal cancer. Dame Deborah James, tó pàdánù ẹ̀mí rẹ̀ sọ́wọ́ jẹjẹrẹ ikùn lẹ́ni ogójì ọdún ní UK rọ àwọn ènìyàn ṣaájú kó tó kú láti máa yẹ ìgbẹ́ wọn wò nígbàkúgbà tí wọ́n bá ti ya ìgbẹ́. Àwọn àpẹẹrẹ mẹ́ta ló ṣe pàtàkì jùlọ láti mọ̀ bóyá ènìyàn ní àìsàn jẹjẹrẹ ikùn. Kò túmọ̀ sí pé tí àwọn nǹkan wọ̀nyí bá ń ṣe ènìyàn onítọ̀hún ti ní àìsàn jẹjẹrẹ ikún àmọ́ ó ṣe pàtàkì fún irú ẹni bẹ́ẹ̀ láti lọ rí àwọn dókítà fún àyẹ̀wò tó péye pàápàá tó bá ti lé ní ọ̀sẹ̀ mẹ́ta tí àwọn àpẹẹrẹ yìí bá ti ń wà lára. Àwọn nǹkan náà nìyí: Àwọn àpẹẹrẹ mìíràn ni Gẹ́gẹ́ bí àwọn àìsàn jẹjẹrẹ yòókù, tí ènìyàn bá tètè mọ̀ wí pé ó wà lára, ó ṣeéṣe kí ènìyàn rí ìtọ́jú tó péye gbà lórí àìsàn náà. Bákan náà ni àìsàn jẹjẹrẹ ikùn lé ṣokùnfà kí ènìyàn má rì í ìgbẹ́ yà, tó sì lè dá àárẹ̀ sára ènìyàn. Lára ohun tí ó dára kí ènìyàn máa ṣe ni yíyẹ ìgbẹ́ ènìyàn tí ènìyàn bá ti ya ìgbẹ́ tán láti mọ bí ó ṣe rí nítorí bí ìgbẹ́ ènìyàn bá ṣe rí jẹ́ ọ̀nà láti fi mọ ìlera ènìyàn. Wò bóyá kò sí ẹ̀jẹ̀ nínú ìgbẹ́ rẹ tàbí ní ìdí rẹ. Ìgbà mìíràn tó jẹ́ wí pé jẹ̀dí ló máa ń fa kí ẹ̀jẹ̀ wà nínú ìgbẹ́ ènìyàn àmọ́ àìsàn jẹjẹrẹ ikùn náà máa ń fà á. Kò ì tíì sí ìwádìí kankan tó fi ohun tó ń fa àìsàn jẹjẹrẹ ikùn múlẹ̀ àmọ́ àwọn nǹkan wà tó le mú kí àìsàn yìí tètè dàgbà lára. Gẹ́gẹ́ bí ibi tí ìwádìí mọ báyìí, àìsàn jẹjẹrẹ kò le ràn láti ìyá tàbí bàbá sọ́mọ àmọ́ ó ṣe pàtàkì kí ẹni tí wọ́n bá ti ní àìsàn yìí ní ìran rẹ̀ fi tó àwọn dókítà létí. Bákan náà ẹni tó bá ní àìsàn Lynch syndrome ṣeéṣe kó ní àìsàn jẹjẹrẹ ikùn ṣùgbọ́n ó ṣe é mójútó tí àwọn dókítà bá tètè mọ̀. Bákan náà tí ènìyàn bá ń gbé ìgbé ayé àláfíà, tó ń jẹ àwọn oúnjẹ tó le ṣe ara ní àǹfàní le mórí bọ́ lọ́wọ́ àìsàn jẹjẹrẹ. Colonoscopy jẹ́ ọ̀nà tí wọ́n máa ń fi ẹ̀rọ ayàwòrán wo inú ènìyàn láti mọ irú nǹkan tó wà níbẹ̀. Wọ́n le fi ẹ̀rọ yìí mọ̀ tí ènìyǹ bá ní àìsàn jẹjẹrẹ ikùn. Àìsàn jẹjẹrẹ ṣe é tọ́jú tí wọ́n bá tètè ṣàwárí rẹ̀ nígbà tó bá ṣẹ̀ṣẹ̀ bẹ̀rẹ̀. Ìdá àádọ́sàn-án ènìyàn tí wọ́n bá tètè mọ̀ wí pé ó ní àìsàn ló ní àǹfàní láti lo ọdún márùn-ún sí láyé nígbà kan àmọ́ wọ́n ní ẹni náà le lo ọdún mẹ́wàá sí báyìí. Kò sí ìpele tí àìsàn náà bá wà tí kò sí ìtọ́jú fún gẹ̀gẹ̀ bí àwọn onímọ̀ ṣe ṣọ. Ìpele mẹ́rin ni àìsàn jẹjẹrẹ máa ń wà A lérò wí pé ẹ ti di ohun kan tàbí òmíràn mú, tí ẹ ó sì mú ìlera ara yín ní ọ̀kúnkúndùn, ẹ ò ní máa sáré dìde kúrò ní yàrá ìgbọ̀nsẹ̀ tí ẹ bá ti yàgbẹ́ tán. Yẹ ìgbẹ́ rẹ wò kí o tó kúrò nílé ìgbọ̀nsẹ̀ fún ìlera ara rẹ.
https://www.bbc.com/yoruba/articles/c0w5qxr417zo
2health
Breastfeeding: Wo àwọn oúnjẹ́ tí yóò mú kí omi ọmú pọ̀ si fún ìyálọ́mọ́
Ọpọlọpọ ounjẹ lo wa, to le ṣe awọn iyalọmọ to n fun ọmọ ni ọyan ni anfaani, ki omi ọmu wọn le pọ si. Iru ounjẹ ti obinrin to n tọ ikoko lọwọ ba jẹ, ni yoo sọ bi ilera oun ati ọmọ rẹ yoo se ri. Ṣugbọn ṣa, ọpọlọpọ obinrin lo maa n jẹ oriṣiriṣi 'ijẹkujẹ', lasiko ti wọn ba n fun ọmọ ni ọmu, nitori pe wọn ko mọ nipa iru ounjẹ ti wọn le ma a jẹ. BBC ba onimọ nipa ounjẹ, Florence Uchendu ati onimọ nipa bi obinrin ṣe n fun ọmọ ni ọmu, Maryam Sanuth sọrọ, lati ṣalaye iru ounjẹ ti obinrin le ma a jẹ, ki omi ọmu rẹ le pọ si. Gẹgẹ bi Arabinrin Sanuth Maryam ṣe sọ, ti oyun obinrin ba ti pe ogún ọsẹ, ni ọmu rẹ yoo ti ma a ni omi. O ṣalaye pe lasiko yii ni obinrin yoo ṣakiyesi pe ọmu oun n tobi si i. Ni kete ti obinrin naa ba si bimọ tan, eroja ara ti wọn n pe ni prolactin ati oxytocin yoo bẹrẹ si ni jade sinu ọmu. Awọn ounjẹ to le mu ki omi ọmu pọ si: Florence Uchendu sọ pe, o ṣe pataki fun obinrin to sẹṣẹ bimọ lati ma a jẹ awọn nkan wọnyii, nitori pe o ni ipa pataki fun ipese omi ọmu. O ni wọn tun ma n mu ki awọn ẹjẹ to di sinu ile ọmọ, tete ṣan jade kuro ninu ara. Yatọ si eyi, o tun sọ pe yoo jẹ ki ọmu obinrin duro daadaa. Arabinrin Sanuth sọ pe mimu ẹkọ gbigbona naa ṣe koko fun ipese omi ọyan. Uchendu paapaa fikun pe, lootọ ni ẹkọ mimu dara fun obinrin to n fun ọmọ ni ọmu, amọ o dara ko mu ẹkọ naa pẹlu miliki lai ni ṣuga, to le koba ọmọ tuntun. O ni eroja aṣara loore protein to wa ninu miliki ṣe pataki fun awọn obinrin to n fun ọmọ ni ọyan. Ata ilẹ ati alubọsa ayu (Ginger ati Garlic) Arabinrin Maryam Sanuth sọ pe galiiki ni anfaani pupọ, paapaa fun awọn obinrin to n fun ọmọ ni ọyan. O ni wọn tun le fi sinu omi ti ko gbona ju, fun mimu. Sanuth sọ pe eroja aṣaraloore Fiber ati ọpọlọpọ eroja mii lo wa ninu oat, eyi to mu ko dara fun iyalọmọ ni jijẹ ni gbogbo igba. Bakan naa lo tun ni awọn ounjẹ onikoro bi imumu ati ẹpa naa dara. Imumu, ti wọn n pe ni tigernut ni ede Gẹẹsi, ni wọn fi n ṣe Kunnu Aya. O ni ti obinrin ba n mu bi ẹẹmẹta lojumọ, yoo mu ki omi pọ daadaa ni ọmu rẹ, o O ni iyalọmọ le ma a mu ṣibi ewe moringa ti wọn gun lojoojumọ. Florence Uchendu sọ pe o ṣe koko fun obinrin to n fun ọmọ ni ọmu lati ma a jẹun daadaa, nitori pe yoo tete ma a rẹ ẹ. Fun awọn obinrin to ni aisan itọ ṣuga, Uchendu sọ pe bi wọn ṣe n jẹun tẹlẹ ki wọn o to bimọ, naa ni ki wọn o tẹsiwaju. O ni o le jẹ ọgẹdẹ dodo ti ko pọn, tabi iṣu sise.
Breastfeeding: Wo àwọn oúnjẹ́ tí yóò mú kí omi ọmú pọ̀ si fún ìyálọ́mọ́ Ọpọlọpọ ounjẹ lo wa, to le ṣe awọn iyalọmọ to n fun ọmọ ni ọyan ni anfaani, ki omi ọmu wọn le pọ si. Iru ounjẹ ti obinrin to n tọ ikoko lọwọ ba jẹ, ni yoo sọ bi ilera oun ati ọmọ rẹ yoo se ri. Ṣugbọn ṣa, ọpọlọpọ obinrin lo maa n jẹ oriṣiriṣi 'ijẹkujẹ', lasiko ti wọn ba n fun ọmọ ni ọmu, nitori pe wọn ko mọ nipa iru ounjẹ ti wọn le ma a jẹ. BBC ba onimọ nipa ounjẹ, Florence Uchendu ati onimọ nipa bi obinrin ṣe n fun ọmọ ni ọmu, Maryam Sanuth sọrọ, lati ṣalaye iru ounjẹ ti obinrin le ma a jẹ, ki omi ọmu rẹ le pọ si. Gẹgẹ bi Arabinrin Sanuth Maryam ṣe sọ, ti oyun obinrin ba ti pe ogún ọsẹ, ni ọmu rẹ yoo ti ma a ni omi. O ṣalaye pe lasiko yii ni obinrin yoo ṣakiyesi pe ọmu oun n tobi si i. Ni kete ti obinrin naa ba si bimọ tan, eroja ara ti wọn n pe ni prolactin ati oxytocin yoo bẹrẹ si ni jade sinu ọmu. Awọn ounjẹ to le mu ki omi ọmu pọ si: Florence Uchendu sọ pe, o ṣe pataki fun obinrin to sẹṣẹ bimọ lati ma a jẹ awọn nkan wọnyii, nitori pe o ni ipa pataki fun ipese omi ọmu. O ni wọn tun ma n mu ki awọn ẹjẹ to di sinu ile ọmọ, tete ṣan jade kuro ninu ara. Yatọ si eyi, o tun sọ pe yoo jẹ ki ọmu obinrin duro daadaa. Arabinrin Sanuth sọ pe mimu ẹkọ gbigbona naa ṣe koko fun ipese omi ọyan. Uchendu paapaa fikun pe, lootọ ni ẹkọ mimu dara fun obinrin to n fun ọmọ ni ọmu, amọ o dara ko mu ẹkọ naa pẹlu miliki lai ni ṣuga, to le koba ọmọ tuntun. O ni eroja aṣara loore protein to wa ninu miliki ṣe pataki fun awọn obinrin to n fun ọmọ ni ọyan. Ata ilẹ ati alubọsa ayu (Ginger ati Garlic) Arabinrin Maryam Sanuth sọ pe galiiki ni anfaani pupọ, paapaa fun awọn obinrin to n fun ọmọ ni ọyan. O ni wọn tun le fi sinu omi ti ko gbona ju, fun mimu. Sanuth sọ pe eroja aṣaraloore Fiber ati ọpọlọpọ eroja mii lo wa ninu oat, eyi to mu ko dara fun iyalọmọ ni jijẹ ni gbogbo igba. Bakan naa lo tun ni awọn ounjẹ onikoro bi imumu ati ẹpa naa dara. Imumu, ti wọn n pe ni tigernut ni ede Gẹẹsi, ni wọn fi n ṣe Kunnu Aya. O ni ti obinrin ba n mu bi ẹẹmẹta lojumọ, yoo mu ki omi pọ daadaa ni ọmu rẹ, o O ni iyalọmọ le ma a mu ṣibi ewe moringa ti wọn gun lojoojumọ. Florence Uchendu sọ pe o ṣe koko fun obinrin to n fun ọmọ ni ọmu lati ma a jẹun daadaa, nitori pe yoo tete ma a rẹ ẹ. Fun awọn obinrin to ni aisan itọ ṣuga, Uchendu sọ pe bi wọn ṣe n jẹun tẹlẹ ki wọn o to bimọ, naa ni ki wọn o tẹsiwaju. O ni o le jẹ ọgẹdẹ dodo ti ko pọn, tabi iṣu sise.
https://www.bbc.com/yoruba/awon-iroyin-miran-55609159
4religion
Pastor Adeboye: Ìyàwó Adeboye ní ó jẹ́ okùnrin tí gbogbo obìnrin fẹ́ràn láti fi ṣe ọkọ
Iyawo pasitọ Enoch Adeboye, Foluke Adeboye ti sapajuwe ọkọ rẹ gẹgẹ bi ọkunrin akinkanju ti gbogbo obinrin fẹran lati fi ṣe ọkọ. Foluke Adeboye sọ bẹẹ ni oju ọpọ ikansiraẹni Twitter rẹ lasiko ti wọn ṣe ayẹyẹ pasitọ Adeboye to pe ẹni ọdun mọkandinlọgọrin. Pasitọ Adeboye ni adari ijọ irapada, The Redeemed Christian Church of God kaakiri gbogbo agbayẹ. Pasitọ Foluke ni Ọlọrun nigba to n ṣẹda Enoch Adeboye ni nkan bi ọdun mọkandinlọgọrin ṣẹyin ṣe ẹda rẹ fun oun Foluke gẹgẹ bi ade ori. O ni Ọlọrun mọ wi pe oun nilọ akinkanju ọkunrin, ọba, alufaa, woli ati ọkunrin to nirẹlẹ to ṣe e mu yangan, ti pasitọ Adeboye jẹ. ''Adeboye, O da mi loju wi pe Ọlọrun da ẹ fun mi ni o'' ''Mo dupẹ lọwọ rẹ fun ifẹ to fihan mi, emi naa si fẹran rẹ tọkantọkan.'' ''Iwọ ni ọkunrin naa ti gbogbo obinrin fẹ fi ṣe ọkọ wọn, ti gbogbo ọmọ fẹ ko jẹ baba wọn'' Iyawo Adeboye gbadura fun ọkọ rẹ pe ki Ọlọrun da ẹmi rẹ si , ko si ṣe ọpọlọpọ ọdun laye. Bakan naa lo gbadura wi pe ki ilera ati ọrọ kun igbeaye pasitọ Adeboye, ki awọn si gbepọ ni irẹpọ titi opin aye wọn. Ọjọ Keji, Oṣu Kẹta ni Pasitọ Adeboye to jẹ adari ijọ irapada, The Redeemed Christian Church of God pe ẹni ọdun mọkandinlọgọrin.
Pastor Adeboye: Ìyàwó Adeboye ní ó jẹ́ okùnrin tí gbogbo obìnrin fẹ́ràn láti fi ṣe ọkọ Iyawo pasitọ Enoch Adeboye, Foluke Adeboye ti sapajuwe ọkọ rẹ gẹgẹ bi ọkunrin akinkanju ti gbogbo obinrin fẹran lati fi ṣe ọkọ. Foluke Adeboye sọ bẹẹ ni oju ọpọ ikansiraẹni Twitter rẹ lasiko ti wọn ṣe ayẹyẹ pasitọ Adeboye to pe ẹni ọdun mọkandinlọgọrin. Pasitọ Adeboye ni adari ijọ irapada, The Redeemed Christian Church of God kaakiri gbogbo agbayẹ. Pasitọ Foluke ni Ọlọrun nigba to n ṣẹda Enoch Adeboye ni nkan bi ọdun mọkandinlọgọrin ṣẹyin ṣe ẹda rẹ fun oun Foluke gẹgẹ bi ade ori. O ni Ọlọrun mọ wi pe oun nilọ akinkanju ọkunrin, ọba, alufaa, woli ati ọkunrin to nirẹlẹ to ṣe e mu yangan, ti pasitọ Adeboye jẹ. ''Adeboye, O da mi loju wi pe Ọlọrun da ẹ fun mi ni o'' ''Mo dupẹ lọwọ rẹ fun ifẹ to fihan mi, emi naa si fẹran rẹ tọkantọkan.'' ''Iwọ ni ọkunrin naa ti gbogbo obinrin fẹ fi ṣe ọkọ wọn, ti gbogbo ọmọ fẹ ko jẹ baba wọn'' Iyawo Adeboye gbadura fun ọkọ rẹ pe ki Ọlọrun da ẹmi rẹ si , ko si ṣe ọpọlọpọ ọdun laye. Bakan naa lo gbadura wi pe ki ilera ati ọrọ kun igbeaye pasitọ Adeboye, ki awọn si gbepọ ni irẹpọ titi opin aye wọn. Ọjọ Keji, Oṣu Kẹta ni Pasitọ Adeboye to jẹ adari ijọ irapada, The Redeemed Christian Church of God pe ẹni ọdun mọkandinlọgọrin.
https://www.bbc.com/yoruba/56262187
2health
Charles Olumo Agbako ń ṣe àìsàn ńlá, ó ní ara ń ni òun
Òdú ni gbajúgbajà òṣèré tíátà nnì, Abdulsalam Ishola ẹni tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ mọ̀ sí Charles Olúmọ Àgbákò lagbo tiata. Láàárín ọdún 1990 sí ìbẹ̀rẹ̀ ọdún 2000, àwọn ipa líle tí Charles Olúmọ Àgbákò máa ń kó nínú eré jẹ́ kó di ìlú mọ̀ọ́kà láàárín àwọn àgbà òṣèré. Ní ìbẹ̀rẹ̀ ọdún yìí, gbajúmọ̀ òṣèré yìí gba ikọ̀ BBC Yorùbá ní àlejò, tí baba naa sì ṣàlàyé bí ìrìnàjò wọn nínú eré sinimá ṣe bẹ̀rẹ̀. Bakan naa lo tun salaye àwọn ipa ribiribi to ti ko sẹyin ninu eré sinimá nínú ìgbésí ayé wọn. Kódà bàbá Charles Olúmọ Àgbákò fi yé wa nígbà náà wí pé, kokoko ni ara ọta oun le. Agbako ni oun ṣì lè ṣeré tíátà ti wọ́n bá pe oun sí iṣẹ́ pẹ̀lú bí ọjọ́ orí oun ṣe ti ń súnmọ́ ọgọ́rùn-ún ọdún lọ. Eyi lo mu ko jẹ ìyàlẹ́nu nla fún BBC Yoruba nígbà tí a gbọ́ wí pé bàbá tó ń fò sókè ní bi oṣù mélòó kan sẹ́yìn ni òjòjò ń ṣe Ògún rẹ̀ báyìí. Nígbà tí BBC News Yorùbá kàn sí ilé bàbá Charles Olúmọ Àgbákò láti mọ ipò ìlera tí bàbá náà wà, àgbà òṣèré náà ṣàlàyé bí àárẹ̀ tó ń ba jà ṣe bẹ̀rẹ̀ ní bí ọdún díẹ̀ sẹ́yìn. Àgbákò ṣàlàyé pé ní ọdún díẹ̀ sẹ́yìn ni òun ṣàdédé ri wí pé òun kò le yàgbẹ́ tàbí tọ̀ ní ìrọ̀rùn. Ó ní èyí ló mú kí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ òun gbé òun lọ sí ilé ìwòsàn fún ìtọ́jú, tí àwọn dókítà sì ní iṣẹ́ abẹ ló le tán ìṣòro ohun tó ń bá òun fínra lọ́dún náà. Ó fi kun pé, lẹ́yìn ìgbà díẹ̀ tí wọ́n ṣe iṣẹ́ abẹ náà tán, ni ojú ọgbẹ́ ibi tí wọ́n ti ṣe iṣẹ́ abẹ ọ̀hún máa ń da òun láàmú tí òun sì tún padà lọ sí ilé ìwòsàn náà. "Nígbà tí mo padà lọ sí ilé ìwòsàn, wọ́n fún mi ní àwọn òògùn àti nǹkan mìíràn láti máa lò láti fi tọ́jú ibi ojú ọgbẹ́ náà" Charles Olúmọ Àgbákò tẹ̀síwájú pé, lẹ́nu ọjọ́ mẹ́ta yìí ni òun tún ń ri pé àti yàgbẹ́ àti tọ̀, tún bẹ̀rẹ̀ sí ní di ìjọ̀gbọ̀n. Ó ní dókítà ní ó jẹ́ kí ó yé òun wí pé, iṣẹ́ abẹ ọjọ́ kìíní kò jìnà wọnú èyí ló sì fa àìlera gbogbo ìgbà tó ń bá òun fínra báyìí. Bákan náà ló ní wọ́n jẹ́ kó yé òun wí pé ìfun òun ti já sínú ẹpọ̀n òun tí àwọn sì nílò láti ko kúrò níbẹ̀, ko le bọ́ sí àyè tó yẹ kó wà gangan nínú ikùn. Ó ṣàlàyé pé bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn dókítà ní òun kò le ṣe iṣẹ́ abẹ bíi ti ìgbà àkọ́kọ́ mọ́, àwọn ìgbésẹ̀ wà tí wọn yóò gbé láti mú kí ìfun náà padà sí ààyè rẹ̀, kí ìnira tí ó ń kó bá òun náà dínkù jọjọ. "Nígbà tí mo dé ilé ìwòsàn, dókítà ní mi ò le ṣe iṣẹ́ abẹ mọ́, wọ́n ní ki n ṣáà ma lọ lo oògùn, gbogbo ògùn tí wọ́n ń kọ fún mi ni mò ń rà, tí àwọn ènìyàn mi dẹ̀ ń rà fún mi." Àgbákò ní lóòótọ́ ni àwọn ògùn tí àwọn dókítà kọ fún òun ń ṣiṣẹ́ àmọ́ ọjọ́ mẹ́ta mẹ́ta ni òun gba abẹ́rẹ́. O ni awọn abẹrẹ yii lo wa láti fi mú àdínkù bá ìnira tí àìlera ọhun ń kó bá òun. Ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ owó ni àwọn ń run sórí àwọn ògùn àti abẹ́rẹ́ yìí, tó sì jẹ́ wí pé kò sí òkun àti ìlera pípé fún òun láti lọ sí oko eré sinimá mọ́. Agbako ni ọ̀wọ́ nǹkan tí àwọn ènìyàn fi ń ran òun lọ́wọ́ nikan lo ku, ti oun n jẹ. Ìyàwó ọmọ Charles Olúmọ Àgbákò, Olamide tó ń tọ́jú bàbá ṣàlàyé fún BBC News Yorùbá pé láti nǹkan bí oṣù mẹ́fà sẹ́yìn, tí ara bàbá kò ti yá, ni òun ti wà pẹ̀lú wọn. Olamide ní ó jẹ́ ohun tó máa ń ba òun àti àwọn ọmọ bàbá lọ́kàn jẹ́ nígbà tí bàbá bá ń tọrọ ikú fún ara wọn nítorí bí ara ṣe ń ni wọn. Ó ní lóòótọ́ ni pé bàbá Àgbákò ti dàgbà, àmọ́ àwọn ò mọ iye ọdún tí Ọlọ́run kọ fún wọn nítorí náà kò ní wù wá kí wọ́n lo ìgbésí ayé wọn tó kù nínú ìnira. Ó fi kun pé ìrànlọ́wọ́ àwọn ọmọ Nàìjíríà ni bàbá Àgbákò nílò lásìkò láti fi bọ́ lọ́wọ́ ìnira tí bàbá náà ń kojú lásìkò yìí.
Charles Olumo Agbako ń ṣe àìsàn ńlá, ó ní ara ń ni òun Òdú ni gbajúgbajà òṣèré tíátà nnì, Abdulsalam Ishola ẹni tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ mọ̀ sí Charles Olúmọ Àgbákò lagbo tiata. Láàárín ọdún 1990 sí ìbẹ̀rẹ̀ ọdún 2000, àwọn ipa líle tí Charles Olúmọ Àgbákò máa ń kó nínú eré jẹ́ kó di ìlú mọ̀ọ́kà láàárín àwọn àgbà òṣèré. Ní ìbẹ̀rẹ̀ ọdún yìí, gbajúmọ̀ òṣèré yìí gba ikọ̀ BBC Yorùbá ní àlejò, tí baba naa sì ṣàlàyé bí ìrìnàjò wọn nínú eré sinimá ṣe bẹ̀rẹ̀. Bakan naa lo tun salaye àwọn ipa ribiribi to ti ko sẹyin ninu eré sinimá nínú ìgbésí ayé wọn. Kódà bàbá Charles Olúmọ Àgbákò fi yé wa nígbà náà wí pé, kokoko ni ara ọta oun le. Agbako ni oun ṣì lè ṣeré tíátà ti wọ́n bá pe oun sí iṣẹ́ pẹ̀lú bí ọjọ́ orí oun ṣe ti ń súnmọ́ ọgọ́rùn-ún ọdún lọ. Eyi lo mu ko jẹ ìyàlẹ́nu nla fún BBC Yoruba nígbà tí a gbọ́ wí pé bàbá tó ń fò sókè ní bi oṣù mélòó kan sẹ́yìn ni òjòjò ń ṣe Ògún rẹ̀ báyìí. Nígbà tí BBC News Yorùbá kàn sí ilé bàbá Charles Olúmọ Àgbákò láti mọ ipò ìlera tí bàbá náà wà, àgbà òṣèré náà ṣàlàyé bí àárẹ̀ tó ń ba jà ṣe bẹ̀rẹ̀ ní bí ọdún díẹ̀ sẹ́yìn. Àgbákò ṣàlàyé pé ní ọdún díẹ̀ sẹ́yìn ni òun ṣàdédé ri wí pé òun kò le yàgbẹ́ tàbí tọ̀ ní ìrọ̀rùn. Ó ní èyí ló mú kí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ òun gbé òun lọ sí ilé ìwòsàn fún ìtọ́jú, tí àwọn dókítà sì ní iṣẹ́ abẹ ló le tán ìṣòro ohun tó ń bá òun fínra lọ́dún náà. Ó fi kun pé, lẹ́yìn ìgbà díẹ̀ tí wọ́n ṣe iṣẹ́ abẹ náà tán, ni ojú ọgbẹ́ ibi tí wọ́n ti ṣe iṣẹ́ abẹ ọ̀hún máa ń da òun láàmú tí òun sì tún padà lọ sí ilé ìwòsàn náà. "Nígbà tí mo padà lọ sí ilé ìwòsàn, wọ́n fún mi ní àwọn òògùn àti nǹkan mìíràn láti máa lò láti fi tọ́jú ibi ojú ọgbẹ́ náà" Charles Olúmọ Àgbákò tẹ̀síwájú pé, lẹ́nu ọjọ́ mẹ́ta yìí ni òun tún ń ri pé àti yàgbẹ́ àti tọ̀, tún bẹ̀rẹ̀ sí ní di ìjọ̀gbọ̀n. Ó ní dókítà ní ó jẹ́ kí ó yé òun wí pé, iṣẹ́ abẹ ọjọ́ kìíní kò jìnà wọnú èyí ló sì fa àìlera gbogbo ìgbà tó ń bá òun fínra báyìí. Bákan náà ló ní wọ́n jẹ́ kó yé òun wí pé ìfun òun ti já sínú ẹpọ̀n òun tí àwọn sì nílò láti ko kúrò níbẹ̀, ko le bọ́ sí àyè tó yẹ kó wà gangan nínú ikùn. Ó ṣàlàyé pé bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn dókítà ní òun kò le ṣe iṣẹ́ abẹ bíi ti ìgbà àkọ́kọ́ mọ́, àwọn ìgbésẹ̀ wà tí wọn yóò gbé láti mú kí ìfun náà padà sí ààyè rẹ̀, kí ìnira tí ó ń kó bá òun náà dínkù jọjọ. "Nígbà tí mo dé ilé ìwòsàn, dókítà ní mi ò le ṣe iṣẹ́ abẹ mọ́, wọ́n ní ki n ṣáà ma lọ lo oògùn, gbogbo ògùn tí wọ́n ń kọ fún mi ni mò ń rà, tí àwọn ènìyàn mi dẹ̀ ń rà fún mi." Àgbákò ní lóòótọ́ ni àwọn ògùn tí àwọn dókítà kọ fún òun ń ṣiṣẹ́ àmọ́ ọjọ́ mẹ́ta mẹ́ta ni òun gba abẹ́rẹ́. O ni awọn abẹrẹ yii lo wa láti fi mú àdínkù bá ìnira tí àìlera ọhun ń kó bá òun. Ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ owó ni àwọn ń run sórí àwọn ògùn àti abẹ́rẹ́ yìí, tó sì jẹ́ wí pé kò sí òkun àti ìlera pípé fún òun láti lọ sí oko eré sinimá mọ́. Agbako ni ọ̀wọ́ nǹkan tí àwọn ènìyàn fi ń ran òun lọ́wọ́ nikan lo ku, ti oun n jẹ. Ìyàwó ọmọ Charles Olúmọ Àgbákò, Olamide tó ń tọ́jú bàbá ṣàlàyé fún BBC News Yorùbá pé láti nǹkan bí oṣù mẹ́fà sẹ́yìn, tí ara bàbá kò ti yá, ni òun ti wà pẹ̀lú wọn. Olamide ní ó jẹ́ ohun tó máa ń ba òun àti àwọn ọmọ bàbá lọ́kàn jẹ́ nígbà tí bàbá bá ń tọrọ ikú fún ara wọn nítorí bí ara ṣe ń ni wọn. Ó ní lóòótọ́ ni pé bàbá Àgbákò ti dàgbà, àmọ́ àwọn ò mọ iye ọdún tí Ọlọ́run kọ fún wọn nítorí náà kò ní wù wá kí wọ́n lo ìgbésí ayé wọn tó kù nínú ìnira. Ó fi kun pé ìrànlọ́wọ́ àwọn ọmọ Nàìjíríà ni bàbá Àgbákò nílò lásìkò láti fi bọ́ lọ́wọ́ ìnira tí bàbá náà ń kojú lásìkò yìí.
https://www.bbc.com/yoruba/articles/cjrn5w951r4o
4religion
US Fake Marriage Pastor: Ẹ̀wọ̀n ọdún márùn-ún ni ìkọ̀ọ̀kan ẹ̀sùn jìbìtì àti irọ́ pípa tí wọn fi kan Pásítọ̀ gbérù
Olusọagutan kan ni Maryland lorilẹede Amẹrika, tii se ẹni aadọta ọdun, Joshua Olatokunbo Shonubi ni wọn ti fi ẹsun kan pe o se ọpọ ayederu igbeyawo laarin awọn mẹkunnu nilẹ Amẹrika atawọn ajeji lọna ati gba iwe igbelu. Wọn fi ẹsun kan Pasitọ naa pe o se magomago loju ọna ati gba iwe igbelu ni Amẹrika, to si n se ayederu igbeyawo, ayederu iwe igbelu ati genje iwe adehun gbigba ile. Joshua Olatokunbo Shonubi, to tun n jẹ Olatokunbo Joshua Shonubi, ni awọn agbẹjọro ijọba nilu naa wọ lọ sile ẹjọ pe o n lu jibiti nipa igbeyawo ati iwe asẹ iwọlu taa mọ si Visa, to si tun ko awọn genje iwe ẹri awọn ileesẹ ijọba silẹ. Atẹjade tawọn agbefọba naa fisita ni Shonubi gbe nilu Bowie, to si tun jẹ Pasitọ ijọ New Life City to wa lẹba Hyattsville ni Maryland yii kan naa amọ maili mejila ni ilu mejeeji fi jinna sira wọn. Atẹjade naa ni lati ọdun 2014 titi di ọdun 2021 ni Pasitọ Shonubi fi se magomago yii, to si gba ẹgbẹlẹgbẹ dọla lati ọwọ awọn ajeji ni orilẹede miran pe oun yoo bawọn seto igbeyawo pẹlu awọn ọmọ ilẹ Amẹrika. Bakan naa ni wọn tun fi ẹsun kan Shonubi pe gẹgẹ bii Pasitọ, o n gba awọn eeyan ti ko ni agbara lati tọju ara wọn sọdọ rẹ, to si n kọ wọn lati maa se igbeyawo pẹlu awọn ọmọ ilẹ Amẹrika, eyi to ni yoo tete jẹ ki wọn ni iwe igbelu. Nigba mii, Shonubi yii ni wọn lo maa n seto igbeyawo yii funra ara rẹ nile ijọsin rẹ tabi ko ran tọkọ taya naa lọ si Virginia fun ayẹyẹ igbeyawo nla. Awọn agbefọba naa ni ni kete tawọn eeyan naa ba ti se igbeyawo tan, ti wọn si san owo nla fun Shonubi, oun ni yoo ba wọn seto iwe ti wọn yoo fi sọwọ si ileesẹ to n ri si ọrọ iwe igbelu, ti yoo si fi adirẹsi rẹ sibẹ, ọwọ rẹ si ni iwe tabi iroyin nipa igbesẹ naa yoo maa de si. Shonubi yii tun ni wọn ni yoo fi awọn ayederu iwe sọwọ si ileesẹ naa pẹ́lu iwe sọọsi rẹ, ti yoo si sọ nipa bo se mọ tọkọ taya naa si, to si maa n tọ wọn sọna ninu ẹmi ati bi igbeyawo wọn se da lori ifẹ pipe. Wọn ni o to iru ayederu iwe ẹri bayii bii mejidinlogoji ti Shonubi ti se fawọn ofege lọkọ laya, ti yoo si tun pese ẹbu iwe to fihan pe awọn tọkọ tiyawo naa dijọ n gbe papọ ni. Ikọ agbẹjọro agbefọba naa ni Shonubi ni ọwọ ti tẹ bayii, to si ti yọju siwaju adajọ ni Baltimore lọjọ, to si seese ko fi ẹwọn ọdun marun marun jura lori awọn koko ẹsun lilu jibiti ati irọ pipa ti wọn fi kan.
US Fake Marriage Pastor: Ẹ̀wọ̀n ọdún márùn-ún ni ìkọ̀ọ̀kan ẹ̀sùn jìbìtì àti irọ́ pípa tí wọn fi kan Pásítọ̀ gbérù Olusọagutan kan ni Maryland lorilẹede Amẹrika, tii se ẹni aadọta ọdun, Joshua Olatokunbo Shonubi ni wọn ti fi ẹsun kan pe o se ọpọ ayederu igbeyawo laarin awọn mẹkunnu nilẹ Amẹrika atawọn ajeji lọna ati gba iwe igbelu. Wọn fi ẹsun kan Pasitọ naa pe o se magomago loju ọna ati gba iwe igbelu ni Amẹrika, to si n se ayederu igbeyawo, ayederu iwe igbelu ati genje iwe adehun gbigba ile. Joshua Olatokunbo Shonubi, to tun n jẹ Olatokunbo Joshua Shonubi, ni awọn agbẹjọro ijọba nilu naa wọ lọ sile ẹjọ pe o n lu jibiti nipa igbeyawo ati iwe asẹ iwọlu taa mọ si Visa, to si tun ko awọn genje iwe ẹri awọn ileesẹ ijọba silẹ. Atẹjade tawọn agbefọba naa fisita ni Shonubi gbe nilu Bowie, to si tun jẹ Pasitọ ijọ New Life City to wa lẹba Hyattsville ni Maryland yii kan naa amọ maili mejila ni ilu mejeeji fi jinna sira wọn. Atẹjade naa ni lati ọdun 2014 titi di ọdun 2021 ni Pasitọ Shonubi fi se magomago yii, to si gba ẹgbẹlẹgbẹ dọla lati ọwọ awọn ajeji ni orilẹede miran pe oun yoo bawọn seto igbeyawo pẹlu awọn ọmọ ilẹ Amẹrika. Bakan naa ni wọn tun fi ẹsun kan Shonubi pe gẹgẹ bii Pasitọ, o n gba awọn eeyan ti ko ni agbara lati tọju ara wọn sọdọ rẹ, to si n kọ wọn lati maa se igbeyawo pẹlu awọn ọmọ ilẹ Amẹrika, eyi to ni yoo tete jẹ ki wọn ni iwe igbelu. Nigba mii, Shonubi yii ni wọn lo maa n seto igbeyawo yii funra ara rẹ nile ijọsin rẹ tabi ko ran tọkọ taya naa lọ si Virginia fun ayẹyẹ igbeyawo nla. Awọn agbefọba naa ni ni kete tawọn eeyan naa ba ti se igbeyawo tan, ti wọn si san owo nla fun Shonubi, oun ni yoo ba wọn seto iwe ti wọn yoo fi sọwọ si ileesẹ to n ri si ọrọ iwe igbelu, ti yoo si fi adirẹsi rẹ sibẹ, ọwọ rẹ si ni iwe tabi iroyin nipa igbesẹ naa yoo maa de si. Shonubi yii tun ni wọn ni yoo fi awọn ayederu iwe sọwọ si ileesẹ naa pẹ́lu iwe sọọsi rẹ, ti yoo si sọ nipa bo se mọ tọkọ taya naa si, to si maa n tọ wọn sọna ninu ẹmi ati bi igbeyawo wọn se da lori ifẹ pipe. Wọn ni o to iru ayederu iwe ẹri bayii bii mejidinlogoji ti Shonubi ti se fawọn ofege lọkọ laya, ti yoo si tun pese ẹbu iwe to fihan pe awọn tọkọ tiyawo naa dijọ n gbe papọ ni. Ikọ agbẹjọro agbefọba naa ni Shonubi ni ọwọ ti tẹ bayii, to si ti yọju siwaju adajọ ni Baltimore lọjọ, to si seese ko fi ẹwọn ọdun marun marun jura lori awọn koko ẹsun lilu jibiti ati irọ pipa ti wọn fi kan.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-59033802
1entertainment
Yinka Ayefele: Ìrọ́ ni pé ń kò le ṣe bíi ọkùnrin, mò ń ta pútú dàadáa
Awọn agba ni ẹni ti yoo ga, ẹsẹ rẹ yoo tiirin, bẹẹ si ni bi ẹni ti yoo ba ni ogo, yoo ri ohun sọ nitori inu ẹgbin ni ọla n gbe. Idi ree ti ilumọọka akọrin ẹmi Tungba nni, Ọmọwe Olayinka Joel Ayefele (MON) fi n se alaye ọpọ ohun ti oju rẹ ri, ko to di eeyan lasiko to n ba BBC Yoruba sọrọ. Ayefele, ninu ifọrọwerọ naa, tun salaye bo se bẹrẹ igbesi aye rẹ, awọn isẹ to ti se, ko to ja oju ọna pẹlu bo se ni ijamba ọkọ to da joko sori kẹkẹ lai le rin. Bakan naa ni gbajumọ akọrin ẹmi ati agbohunsafẹfẹ naa tun sọrọ lori oniruuru ahesọ ọrọ tawọn eeyan n gbe kiri nipa oun lati igba ti ijamba ọkọ naa ti waye. Ayefele salaye fun BBC pe ileesẹ redio ijọba apapọ, ta mọ si Radio Nigeria ni oun ti bẹrẹ isẹ ni ibẹrẹ aye oun. O ni isẹ ki oun maa ba wọn gbe baba Keresi lopin ọdun ni oun kọkọ fi bẹrẹ lọdun 1997, ti wọn si n fun oun ni aadọta naira ni ojumọ. O salaye pe asiko yii ni wọn ri ẹbun ohun agbohunsafẹfẹ lara oun, ti wọn si gba ki oun maa se eto lori redio wọn. O ni awọn ẹbun orin ti ohun tun ni tẹlẹ tun ni oun n lo lati maa mu owo wọle nibẹ nipasẹ ipolowo ọja ati ikede, ti oun si pade oloogbe Kola Olawuyi nibẹ. Ayefele tẹsiwaju pe oun ti sisẹ atagija lẹyin awọn agba osere olorin ri, lara wọn ni Baba Toye Ajagun, Wale Thompson, Micho Ade ati bẹẹ bẹẹ lọ. O ni oun tun maa n ba awọn ile ijọsin ta gita kaakiri lasiko isin pẹlu, ki oun to wa yan isẹ agbohunsafẹfẹ ni aayo. Olayinka Ayefele ni ọjọ Kejila osu Kejila ọdun 1997 ni ijamba se elesu lẹyin ọkọ fun oun, ti oun si bẹrẹ irin ajo orin kikọ. “Osu mọkanla ni mo lo nile iwosan UCH nilu Ibadan fun itọja ara lasiko ti mo ni ijamba ọkọ naa, ti mo si maa n da gbọ awọn orin kekeke ti mo ti kọ tẹlẹ́. Awọn kekeke yii ni mo n gbọ lasiko ti awọn ọrẹ mi wa ki mi, ti wọn si gbe imọran kalẹ pe ka se akojọpọ awọn orin naa, ka si se ifilọlẹ rẹ lati ri owo. Owo yii ni wọn ni maa lo lati lọ fi se itọju ara mi ni oke okun, ti mo si gbe awo orin Bitter Experience jade. Amọ awọn eeyan tẹwọgba orin naa, ti mo si ri pe ọbẹ wa nibẹ, bi mo se bẹrẹ niyẹn. Nigba to n sọ nipa ọpọ ahesọ ọrọ ti awọn eeyan n sọ nipa bo se di olokiki lẹyin to ni ijamba ọkọ tan, Ayefele ni ahesọ ọrọ lasan ni awọn ọrọ naa. “Se o rọrun ki eeyan fi igbesi aye rẹ se oogun okiki tori ko le lowo, ko joko sori kẹkẹ, rara, ko ri bẹẹ. Wọn tun ni mo fi eegun ẹyin mi se oogun okiki ni, ki n wa ni ori kẹkẹ lo wu mi ki n joko si, ẹhun ọrọ lasan ni Koda, wọn tun sọ pe o seese ki n ma le se bii ọkunrin amọ ko ri bẹẹ, mo le se daadaa.” Olayinka Joel Ayefele jẹ akọrin, agbohunsafẹfẹ ati oludasilẹ ileesẹ Redio kaakiri ilẹ Yoruba. Ọmọ bibi ilu Ipoti Ekiti nipinlẹ Ekiti ni, to si dele aye ni ọdun ọjọ kinni osu Keji ọdun 1968, eyiun ọdun mẹrinlelaadọta sẹyin. Ọdun 1997 lo ni ijamba ọkọ to kan eegun ẹyin rẹ, ti ko si le fi ẹsẹ mejeeji rin mọ, eyi to mu ko maa lo kẹkẹ. Yinka Ayefele, ẹni ti ijba apapọ fi ami ẹyẹ MON da lọla lo ti gbe ọpọ awo orin jade, o ni iyawo, to si bi ibẹta.
Yinka Ayefele: Ìrọ́ ni pé ń kò le ṣe bíi ọkùnrin, mò ń ta pútú dàadáa Awọn agba ni ẹni ti yoo ga, ẹsẹ rẹ yoo tiirin, bẹẹ si ni bi ẹni ti yoo ba ni ogo, yoo ri ohun sọ nitori inu ẹgbin ni ọla n gbe. Idi ree ti ilumọọka akọrin ẹmi Tungba nni, Ọmọwe Olayinka Joel Ayefele (MON) fi n se alaye ọpọ ohun ti oju rẹ ri, ko to di eeyan lasiko to n ba BBC Yoruba sọrọ. Ayefele, ninu ifọrọwerọ naa, tun salaye bo se bẹrẹ igbesi aye rẹ, awọn isẹ to ti se, ko to ja oju ọna pẹlu bo se ni ijamba ọkọ to da joko sori kẹkẹ lai le rin. Bakan naa ni gbajumọ akọrin ẹmi ati agbohunsafẹfẹ naa tun sọrọ lori oniruuru ahesọ ọrọ tawọn eeyan n gbe kiri nipa oun lati igba ti ijamba ọkọ naa ti waye. Ayefele salaye fun BBC pe ileesẹ redio ijọba apapọ, ta mọ si Radio Nigeria ni oun ti bẹrẹ isẹ ni ibẹrẹ aye oun. O ni isẹ ki oun maa ba wọn gbe baba Keresi lopin ọdun ni oun kọkọ fi bẹrẹ lọdun 1997, ti wọn si n fun oun ni aadọta naira ni ojumọ. O salaye pe asiko yii ni wọn ri ẹbun ohun agbohunsafẹfẹ lara oun, ti wọn si gba ki oun maa se eto lori redio wọn. O ni awọn ẹbun orin ti ohun tun ni tẹlẹ tun ni oun n lo lati maa mu owo wọle nibẹ nipasẹ ipolowo ọja ati ikede, ti oun si pade oloogbe Kola Olawuyi nibẹ. Ayefele tẹsiwaju pe oun ti sisẹ atagija lẹyin awọn agba osere olorin ri, lara wọn ni Baba Toye Ajagun, Wale Thompson, Micho Ade ati bẹẹ bẹẹ lọ. O ni oun tun maa n ba awọn ile ijọsin ta gita kaakiri lasiko isin pẹlu, ki oun to wa yan isẹ agbohunsafẹfẹ ni aayo. Olayinka Ayefele ni ọjọ Kejila osu Kejila ọdun 1997 ni ijamba se elesu lẹyin ọkọ fun oun, ti oun si bẹrẹ irin ajo orin kikọ. “Osu mọkanla ni mo lo nile iwosan UCH nilu Ibadan fun itọja ara lasiko ti mo ni ijamba ọkọ naa, ti mo si maa n da gbọ awọn orin kekeke ti mo ti kọ tẹlẹ́. Awọn kekeke yii ni mo n gbọ lasiko ti awọn ọrẹ mi wa ki mi, ti wọn si gbe imọran kalẹ pe ka se akojọpọ awọn orin naa, ka si se ifilọlẹ rẹ lati ri owo. Owo yii ni wọn ni maa lo lati lọ fi se itọju ara mi ni oke okun, ti mo si gbe awo orin Bitter Experience jade. Amọ awọn eeyan tẹwọgba orin naa, ti mo si ri pe ọbẹ wa nibẹ, bi mo se bẹrẹ niyẹn. Nigba to n sọ nipa ọpọ ahesọ ọrọ ti awọn eeyan n sọ nipa bo se di olokiki lẹyin to ni ijamba ọkọ tan, Ayefele ni ahesọ ọrọ lasan ni awọn ọrọ naa. “Se o rọrun ki eeyan fi igbesi aye rẹ se oogun okiki tori ko le lowo, ko joko sori kẹkẹ, rara, ko ri bẹẹ. Wọn tun ni mo fi eegun ẹyin mi se oogun okiki ni, ki n wa ni ori kẹkẹ lo wu mi ki n joko si, ẹhun ọrọ lasan ni Koda, wọn tun sọ pe o seese ki n ma le se bii ọkunrin amọ ko ri bẹẹ, mo le se daadaa.” Olayinka Joel Ayefele jẹ akọrin, agbohunsafẹfẹ ati oludasilẹ ileesẹ Redio kaakiri ilẹ Yoruba. Ọmọ bibi ilu Ipoti Ekiti nipinlẹ Ekiti ni, to si dele aye ni ọdun ọjọ kinni osu Keji ọdun 1968, eyiun ọdun mẹrinlelaadọta sẹyin. Ọdun 1997 lo ni ijamba ọkọ to kan eegun ẹyin rẹ, ti ko si le fi ẹsẹ mejeeji rin mọ, eyi to mu ko maa lo kẹkẹ. Yinka Ayefele, ẹni ti ijba apapọ fi ami ẹyẹ MON da lọla lo ti gbe ọpọ awo orin jade, o ni iyawo, to si bi ibẹta.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-60329281
1entertainment
Ìdí tí àwọn ìbejì mi, Twinz love ṣe ń rí mi mú fi ṣe “prank” wọn rèé – Ìyá Ìbejì
“A ṣe prank gbe ọkan lara wa loyun fun iya ibeji, wọn sọkun gidi gan, koda bi a ṣe pada sọ pe irọ ni, wọn ṣi balẹ sile iwosan”. Ṣe ẹ ranti bi awọn ibeji yii ṣe ti di gbajumọ lori ayelujara bayii pẹlu orukọ wọn “Twinz Love”?\nỌjọ tun ti gun ọjọ ori wọn ti awọn mejeji si ti n ṣe ọpọlọpọ nkan kun ohun ti wọn ba bẹrẹ iṣẹ adẹrinpoṣonu lori ayelujara. iya to bi Moyinoluwa ati Doyin Oladimeji ti ba BBC Yoruba sọrọ. Lọjọ ti a kọkọ ṣe “Facebook Live pẹlu awọn ibeji naa, iya wọn ko fẹ fi oju han. “Mi o fẹran keeyan wọ aṣọ, ko jẹun, ko maa gbe e si ori afẹfẹ fun gbogbo aye amọ, awọn ọmọ yii...” Arabinrin Adeyinka Oladimeji tun ṣalaye pe lati kekere, oun fun wọn ni aaye lati sunmọ oun daadaa. “Mo ni aaye fun wọn lati sun mọ mi ni gbogbo ọna tori naa ẹru kii ba wọn lati sun mọ mi tabi sọ ọrọ nipa ara wọn fun mi”. Bi awọn naa ṣe n ṣalaye bi wọn ṣe de oke ninu iṣẹ ti wọn yan. Wọn ni awọn ko kọkọ ri eeyan to fẹran nkan ti awọn fi sita amọ o pada yi biri ti “likes” n tu puupuu. Kehinde: Lori Instagram, a kọkọ lo Moyin&Doyin amọ Instagram kọọ, mo kan ronu ni pe ṣebi ibeji ni wa a dẹ fẹran ara wa, bi Twinz Love ṣe jade niyẹn ti gbogbo eeyan fẹran ẹ. Bi wọ́n ṣe jẹ́ gbajúmọ̀ tó, wọn kawe tan ni Fasiti amọ awọn mejeeji gan ko ri iṣẹ. Taiye: Bi emi nisinyi, mo ka “History and International Relations” ni ile ẹkọ amọ, mo maa n ji lati din ipapanu Doughnut laraarọ ni. Iya wọn taa ba sọrọ naa sọ iriri rẹ nipa ere ẹfẹ kan ti wọn ti sọ fun oun pe ọkan lara wọn loyun eyi to lagbara gan. O ni ọjọ naa dabii pe opin ti de ba gbogbo laalaa oun lori wọn. Lootọ, lọpọ igba kii tete mọ pe ere ni wọn n ṣe. “Ti mo ba sọ fawọn eeyan pe ọpọlọpọ nkan ti wọn ṣe yii, mi o mọ nipa rẹ rara. Omii gan wọn o le fi sita tori igba mii ti mo ba ti mọ, mo ma n daa ru fun wọn gidi gan ti mo maa binu”.
Ìdí tí àwọn ìbejì mi, Twinz love ṣe ń rí mi mú fi ṣe “prank” wọn rèé – Ìyá Ìbejì “A ṣe prank gbe ọkan lara wa loyun fun iya ibeji, wọn sọkun gidi gan, koda bi a ṣe pada sọ pe irọ ni, wọn ṣi balẹ sile iwosan”. Ṣe ẹ ranti bi awọn ibeji yii ṣe ti di gbajumọ lori ayelujara bayii pẹlu orukọ wọn “Twinz Love”?\nỌjọ tun ti gun ọjọ ori wọn ti awọn mejeji si ti n ṣe ọpọlọpọ nkan kun ohun ti wọn ba bẹrẹ iṣẹ adẹrinpoṣonu lori ayelujara. iya to bi Moyinoluwa ati Doyin Oladimeji ti ba BBC Yoruba sọrọ. Lọjọ ti a kọkọ ṣe “Facebook Live pẹlu awọn ibeji naa, iya wọn ko fẹ fi oju han. “Mi o fẹran keeyan wọ aṣọ, ko jẹun, ko maa gbe e si ori afẹfẹ fun gbogbo aye amọ, awọn ọmọ yii...” Arabinrin Adeyinka Oladimeji tun ṣalaye pe lati kekere, oun fun wọn ni aaye lati sunmọ oun daadaa. “Mo ni aaye fun wọn lati sun mọ mi ni gbogbo ọna tori naa ẹru kii ba wọn lati sun mọ mi tabi sọ ọrọ nipa ara wọn fun mi”. Bi awọn naa ṣe n ṣalaye bi wọn ṣe de oke ninu iṣẹ ti wọn yan. Wọn ni awọn ko kọkọ ri eeyan to fẹran nkan ti awọn fi sita amọ o pada yi biri ti “likes” n tu puupuu. Kehinde: Lori Instagram, a kọkọ lo Moyin&Doyin amọ Instagram kọọ, mo kan ronu ni pe ṣebi ibeji ni wa a dẹ fẹran ara wa, bi Twinz Love ṣe jade niyẹn ti gbogbo eeyan fẹran ẹ. Bi wọ́n ṣe jẹ́ gbajúmọ̀ tó, wọn kawe tan ni Fasiti amọ awọn mejeeji gan ko ri iṣẹ. Taiye: Bi emi nisinyi, mo ka “History and International Relations” ni ile ẹkọ amọ, mo maa n ji lati din ipapanu Doughnut laraarọ ni. Iya wọn taa ba sọrọ naa sọ iriri rẹ nipa ere ẹfẹ kan ti wọn ti sọ fun oun pe ọkan lara wọn loyun eyi to lagbara gan. O ni ọjọ naa dabii pe opin ti de ba gbogbo laalaa oun lori wọn. Lootọ, lọpọ igba kii tete mọ pe ere ni wọn n ṣe. “Ti mo ba sọ fawọn eeyan pe ọpọlọpọ nkan ti wọn ṣe yii, mi o mọ nipa rẹ rara. Omii gan wọn o le fi sita tori igba mii ti mo ba ti mọ, mo ma n daa ru fun wọn gidi gan ti mo maa binu”.
https://www.bbc.com/yoruba/articles/ck5zyy5319eo
1entertainment
Pasuma: Ọ̀gáńlá Fújì ní ominú ń kọ òun lórí ọ̀dá àwọn ìràwọ̀ tuntun lágbo orin Fújì
Gbajugbaja akọrin Fuji ni, Alhaji Wasiu Alabi ti ọpọ eeyan mọ si Pasuma Wonder, iba wasi baba baraka ti ṣalaye pe ọrọ iyawo nini fun oun kii ṣe afi waduwadu ṣe o. Alhaji Pasuma ṣalaye pe idi ti oun ko tii fi ni iyawo lọwọ yii naa ni pe oun fẹ ṣe ohun gbogbo bi o ti yẹ ko le baa ri bose yẹ ko ri. Paso ni ohun lawọn obinrin to bimọ fun oun o, ṣugbọn ọrọ iyawo afẹsile ko tii yọ fun oun bayii. Ọganla Fuji ni nigba to ba ya oun yoo niyawo ṣugbọn suuru lo gba. Ninu ifọrọwerọ rẹ pẹlu BBC News Yoruba ni Ba wasi ti sọ ọrọ yii. Bakan naa lo sọrọ lori ahesọ ọrọ to n wi pe ọjọṣepọ ifẹ n bẹ laarin oun ati gbajumọ oṣere tiata, Jaiye Kuti. Pasuma ni ere tiata lo da awọn mejeeji pọ. Bakan naa lo fi kun un pe ọrẹ lasan loun ati gbajugbaja oṣere tiata, Ronkẹ Ididowo ti ko si si ohun ifẹ ikọkọ kankan to pa wọn pọ. Bakan naa lo kọminu lori ọda awọn irawọ tuntun lagbo fuji. O ni ohun to mi oun lọkan ni bi o ṣe jẹ pe awọn ọdọ olorin ko fẹ kọ orin Fuji mọ bi ko ṣe orin takasufe, HipHop. O fi kun un pe oun yoo sa ipa oun gẹgẹ bii aṣiwaju lati mu idagbasoke ba awọn ọdọ to ba fẹ yan orin Fuji laayo
Pasuma: Ọ̀gáńlá Fújì ní ominú ń kọ òun lórí ọ̀dá àwọn ìràwọ̀ tuntun lágbo orin Fújì Gbajugbaja akọrin Fuji ni, Alhaji Wasiu Alabi ti ọpọ eeyan mọ si Pasuma Wonder, iba wasi baba baraka ti ṣalaye pe ọrọ iyawo nini fun oun kii ṣe afi waduwadu ṣe o. Alhaji Pasuma ṣalaye pe idi ti oun ko tii fi ni iyawo lọwọ yii naa ni pe oun fẹ ṣe ohun gbogbo bi o ti yẹ ko le baa ri bose yẹ ko ri. Paso ni ohun lawọn obinrin to bimọ fun oun o, ṣugbọn ọrọ iyawo afẹsile ko tii yọ fun oun bayii. Ọganla Fuji ni nigba to ba ya oun yoo niyawo ṣugbọn suuru lo gba. Ninu ifọrọwerọ rẹ pẹlu BBC News Yoruba ni Ba wasi ti sọ ọrọ yii. Bakan naa lo sọrọ lori ahesọ ọrọ to n wi pe ọjọṣepọ ifẹ n bẹ laarin oun ati gbajumọ oṣere tiata, Jaiye Kuti. Pasuma ni ere tiata lo da awọn mejeeji pọ. Bakan naa lo fi kun un pe ọrẹ lasan loun ati gbajugbaja oṣere tiata, Ronkẹ Ididowo ti ko si si ohun ifẹ ikọkọ kankan to pa wọn pọ. Bakan naa lo kọminu lori ọda awọn irawọ tuntun lagbo fuji. O ni ohun to mi oun lọkan ni bi o ṣe jẹ pe awọn ọdọ olorin ko fẹ kọ orin Fuji mọ bi ko ṣe orin takasufe, HipHop. O fi kun un pe oun yoo sa ipa oun gẹgẹ bii aṣiwaju lati mu idagbasoke ba awọn ọdọ to ba fẹ yan orin Fuji laayo
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-51780573
3politics
Ekiti state PDP Congress: Fayose, Olujimi, Oni ń forígbárí nítorí ìdìbò wọ́ọ̀dù tó wáyé lẹ́gbẹ́ òṣèlú PDP l'Ekiti
Ina edeaiyede n jo laarin awọn eekan oloṣelu lẹgbẹ oṣelu PDP ni ipinlẹ Ekiti paapaa laarin igun gomina tẹlẹ, Ayọ Fayose ati igbakeji rẹ nigbakan ri to tun jẹ sẹnetọ lọwọ bayii nileegbimọ aṣofin apapọ Naijiria. Ko si ohun meji to n fa awuyewuye laarin wọn ju abajade eto idibo ati yan awọn aṣoju ẹgbẹ oṣelu PDP ni wọọdu to waye nipinlẹ Ekiti lọjọ Satide, ọjọ karundinlogun oṣu kinni ọdun 2022. Ninu ọrọ to ba BBC News Yoruba sọ, Sẹnetọ Abiọdun Olujimi ṣalaye pe lara ọna ati mu iṣọkan igbọraẹniye ati alaafia pada sagbo ẹgbẹ naa nipinlẹ Ekiti lawọn fi wo eto naa. O ni igbagbọ awọn ṣaaju eto naa ni pe gbogbo ẹgun iṣaaju to da wahala silẹ ni wọn yoo dana sun. Amọsa, o ni ọrọ ko ri bẹẹ nigba ti awọn rii pe meji ninu awọn eeyan to wa nidi wahala naa lati ipilẹ wa ni wọn tun yan lati ṣe akoso idibo aṣoju naa. Sẹnatọ Abiọdun Olujimi fi ẹsun kan Oloye Ayọ Fayose pe oun gan ni eku ẹda to n da ina alaafia PDP ru paapa pẹlu ti idibo aṣoju wọọdu naa. Sẹnetọ naa ṣalaye pe inu kọrọ ile kan ni awọn igun OPA to jẹ ti Fayoṣe ti kọ orukọ awọn aṣoju ti wọn fẹ laifi ti awọn igun ti 'Repositioning' to wa pẹlu Olujimi ṣe. Amọṣa ninu ọrọ to ba BBC News Yoruba sọ, gomina tẹlẹ nipinlẹ Ekiti, Ayọdele Fayoṣe ṣalaye pe oun o ba ẹnikẹni ja. O ni eeyan oun ni gbogbo wọn, oun ko si tii ṣe ohnunkohun to buru gẹgẹ bii aṣiwaju ẹgbẹ oṣelu naa. Fayoṣe ṣalaye pe oun o mọ idi ti awọn oludije ti ọrọ kan ṣe n pariwo oun nigba ti wọn mọ pe oun kii ṣe Oludije. Oṣoko, gẹgẹ bi orukọ inagijẹ ti ọpọ maa n pe e ṣalaye pe niwọn igba to jẹ wi pe nitori pe awọn oludije naa ri oun gẹgẹ bii eeyan pataki lagbo oṣelu ni wọn fi n da orukọ oun. O ni gbogbo awọn ileeṣẹ agbofinro ni wọn ni akọsilẹ pe eto idibo ati yan awọn aṣoju ẹgbẹ oṣelu PDP ni wọọdu waye nipinlẹ Ekiti, oun kọ lo si gba wọn siṣẹ. Lara awọn eekan oloṣelu ni ipinlẹ Ekiti to n gbaradi lati dije fun ipo gomina labẹ aṣia ẹgbẹ oṣelu PDP ni ipinlẹ Ekiti, Biọdun Olujimi ati Ṣẹgun Oni fọn si igboro ilu Ado Ekiti lati ṣe iwọde takogomina ipinlẹ naa tẹlẹ, Ayọdele Fayose. Ẹsun ti wọn n fi kan Fayose ni pe o ti n dọwọ ru pẹlu ibo yiyan awọn adari ati aṣoju ẹgbẹ naa lẹsẹpupu wọọdu eyi to waye lọjọ Satide ọjọ karundinlogun, oṣu Kinni dun 2022. Awọn ọmọ ẹgbẹ oṣelu PDP kan dara pọ wọ iwọde naa ti wọn si n ke sawọn alaṣẹ ẹgbẹ oṣelu naa lati fofin de Fayoṣe lẹgbẹ oṣelu naa. Wọn ni o n ṣe agbẹyinbẹbọjẹ fun gbogbo ilakaka awọn alaṣẹ ẹgbẹ oṣelu naa nipa dida ṣe idibo yiyan awọn adari wọdu ni gbọngan adani rẹ kan lasiko to si jẹ pe ipade idibo ti ẹgbẹ fọwọ si gan n lọ kaakiri awọn wọọdu mẹtadinlọgọsan nipinlẹ naa. Awọn oludije mejeeji naa wa ke sawọn adari ẹgbẹ oṣelu naa lati maṣẹ fọwọ kan iwe orukọ awọn adari wọọdu yoowu ti Ayọdele Fayose ba fi ranṣẹ si wọn nitori pe, ni ti awọn o, ipade idibo yiyan adari ẹgbẹ oṣelu PDP lawọn wọọdu nipinlẹ Ekiti ko waye. Awọn alaṣẹ apapọ ẹgbẹ oṣelu PDP ni awọn ti tẹwọ gba abajade ipade idibo yiyan awọn adari ati aṣoju ẹgbẹ naa lẹsẹpupu wọọdu lati ipinlẹ Ekiti. Ninu atẹjade kan ti wọn fi si oju opo ikanni Twitter ẹgbẹ oṣelu PDP awọn alaṣẹ ẹgbẹ oṣelu naa ni awọn yoo wa ojutu si awọn aawọ to suyọ lasiko ipade idibo naa. Atẹjade ọhun ti alukoro ẹgbẹ oṣelu PDP lapapọ, Debọ Ologunagba fọwọ si ṣalaye pe bi wọn ṣe n tẹwọ gba esi idibo naa ni wọn tun tẹwọ gba awọn iwe ẹhonu latọdọ awọn mọ ẹgbẹ to ni ẹhonu kan kabi omiran. O ni gbogbo rẹ ni wọn yoo yẹwo lati rii daju pe alaafia n jọba.
Ekiti state PDP Congress: Fayose, Olujimi, Oni ń forígbárí nítorí ìdìbò wọ́ọ̀dù tó wáyé lẹ́gbẹ́ òṣèlú PDP l'Ekiti Ina edeaiyede n jo laarin awọn eekan oloṣelu lẹgbẹ oṣelu PDP ni ipinlẹ Ekiti paapaa laarin igun gomina tẹlẹ, Ayọ Fayose ati igbakeji rẹ nigbakan ri to tun jẹ sẹnetọ lọwọ bayii nileegbimọ aṣofin apapọ Naijiria. Ko si ohun meji to n fa awuyewuye laarin wọn ju abajade eto idibo ati yan awọn aṣoju ẹgbẹ oṣelu PDP ni wọọdu to waye nipinlẹ Ekiti lọjọ Satide, ọjọ karundinlogun oṣu kinni ọdun 2022. Ninu ọrọ to ba BBC News Yoruba sọ, Sẹnetọ Abiọdun Olujimi ṣalaye pe lara ọna ati mu iṣọkan igbọraẹniye ati alaafia pada sagbo ẹgbẹ naa nipinlẹ Ekiti lawọn fi wo eto naa. O ni igbagbọ awọn ṣaaju eto naa ni pe gbogbo ẹgun iṣaaju to da wahala silẹ ni wọn yoo dana sun. Amọsa, o ni ọrọ ko ri bẹẹ nigba ti awọn rii pe meji ninu awọn eeyan to wa nidi wahala naa lati ipilẹ wa ni wọn tun yan lati ṣe akoso idibo aṣoju naa. Sẹnatọ Abiọdun Olujimi fi ẹsun kan Oloye Ayọ Fayose pe oun gan ni eku ẹda to n da ina alaafia PDP ru paapa pẹlu ti idibo aṣoju wọọdu naa. Sẹnetọ naa ṣalaye pe inu kọrọ ile kan ni awọn igun OPA to jẹ ti Fayoṣe ti kọ orukọ awọn aṣoju ti wọn fẹ laifi ti awọn igun ti 'Repositioning' to wa pẹlu Olujimi ṣe. Amọṣa ninu ọrọ to ba BBC News Yoruba sọ, gomina tẹlẹ nipinlẹ Ekiti, Ayọdele Fayoṣe ṣalaye pe oun o ba ẹnikẹni ja. O ni eeyan oun ni gbogbo wọn, oun ko si tii ṣe ohnunkohun to buru gẹgẹ bii aṣiwaju ẹgbẹ oṣelu naa. Fayoṣe ṣalaye pe oun o mọ idi ti awọn oludije ti ọrọ kan ṣe n pariwo oun nigba ti wọn mọ pe oun kii ṣe Oludije. Oṣoko, gẹgẹ bi orukọ inagijẹ ti ọpọ maa n pe e ṣalaye pe niwọn igba to jẹ wi pe nitori pe awọn oludije naa ri oun gẹgẹ bii eeyan pataki lagbo oṣelu ni wọn fi n da orukọ oun. O ni gbogbo awọn ileeṣẹ agbofinro ni wọn ni akọsilẹ pe eto idibo ati yan awọn aṣoju ẹgbẹ oṣelu PDP ni wọọdu waye nipinlẹ Ekiti, oun kọ lo si gba wọn siṣẹ. Lara awọn eekan oloṣelu ni ipinlẹ Ekiti to n gbaradi lati dije fun ipo gomina labẹ aṣia ẹgbẹ oṣelu PDP ni ipinlẹ Ekiti, Biọdun Olujimi ati Ṣẹgun Oni fọn si igboro ilu Ado Ekiti lati ṣe iwọde takogomina ipinlẹ naa tẹlẹ, Ayọdele Fayose. Ẹsun ti wọn n fi kan Fayose ni pe o ti n dọwọ ru pẹlu ibo yiyan awọn adari ati aṣoju ẹgbẹ naa lẹsẹpupu wọọdu eyi to waye lọjọ Satide ọjọ karundinlogun, oṣu Kinni dun 2022. Awọn ọmọ ẹgbẹ oṣelu PDP kan dara pọ wọ iwọde naa ti wọn si n ke sawọn alaṣẹ ẹgbẹ oṣelu naa lati fofin de Fayoṣe lẹgbẹ oṣelu naa. Wọn ni o n ṣe agbẹyinbẹbọjẹ fun gbogbo ilakaka awọn alaṣẹ ẹgbẹ oṣelu naa nipa dida ṣe idibo yiyan awọn adari wọdu ni gbọngan adani rẹ kan lasiko to si jẹ pe ipade idibo ti ẹgbẹ fọwọ si gan n lọ kaakiri awọn wọọdu mẹtadinlọgọsan nipinlẹ naa. Awọn oludije mejeeji naa wa ke sawọn adari ẹgbẹ oṣelu naa lati maṣẹ fọwọ kan iwe orukọ awọn adari wọọdu yoowu ti Ayọdele Fayose ba fi ranṣẹ si wọn nitori pe, ni ti awọn o, ipade idibo yiyan adari ẹgbẹ oṣelu PDP lawọn wọọdu nipinlẹ Ekiti ko waye. Awọn alaṣẹ apapọ ẹgbẹ oṣelu PDP ni awọn ti tẹwọ gba abajade ipade idibo yiyan awọn adari ati aṣoju ẹgbẹ naa lẹsẹpupu wọọdu lati ipinlẹ Ekiti. Ninu atẹjade kan ti wọn fi si oju opo ikanni Twitter ẹgbẹ oṣelu PDP awọn alaṣẹ ẹgbẹ oṣelu naa ni awọn yoo wa ojutu si awọn aawọ to suyọ lasiko ipade idibo naa. Atẹjade ọhun ti alukoro ẹgbẹ oṣelu PDP lapapọ, Debọ Ologunagba fọwọ si ṣalaye pe bi wọn ṣe n tẹwọ gba esi idibo naa ni wọn tun tẹwọ gba awọn iwe ẹhonu latọdọ awọn mọ ẹgbẹ to ni ẹhonu kan kabi omiran. O ni gbogbo rẹ ni wọn yoo yẹwo lati rii daju pe alaafia n jọba.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-60034883
5sports
Mama Arsenal: Ẹgbẹ́ kan ti fún màmá ní ẹ̀bùn owó
Bi a ba ku, iṣe o tan ni Yoruba maa n wi. Bẹẹ gẹlẹ ni ọrọ ri pẹlu mama agba ololufẹ ẹgbẹ agbabọọlu Arsenal, Nosimatu Hassan. Mama to jẹ ẹni ọdun mẹtadinlọgọrin di ẹni ti ọgọọrọ eeyan n sọ nipa rẹ lori ayelujara lẹyin ti sọ ọpọ ọrọ nipa ẹgbẹ agbabọọlu to yan laayo. Lati igba naa ọpọ ẹlẹyinju aanu ọmọ Naijiria ti n ṣeleri lati fun mama ni ẹbun kan tabi omiiran. Ṣugbọn ni bayii, ẹgbẹ ololufẹ awọn ikọ agbabọọlu Naijiria, Authentic Nigeria Supporters' Club ti fun mama ni ẹbun owo rọgun rọgun. Owo ti ẹgbẹ ololufẹ agbabọọlu Naijiria naa fun mama Arsenal ni ṣe ẹgbẹrun un lọna ọta le lugba o din mẹwaa. Ọlọ́run ló yàn mí ti Arsenal, mi ò lè fi wọ́n sílẹ̀ láéláé- Mama Arsenal yarí Ara meriri , mo ri ori ologbo lori atẹ ni ọrọ mama agba kan, Nosimatu Hazzan, ti ọpọ eeyan mọ si mama Arsenal. Mama agba yii, to nifẹ ẹgbẹ agbabọọlu Arsenal bii oju, ti ọjọ ori rẹ yoo si to aadọrin ọdun, lo nifẹ ere bọọlu ju ọmọde tabi awọn ọkunrin miran lọ. Lasiko ti BBC se abẹwo si ọdọ mama naa, ti ọpọ eeyan mọ si Mama Arsenal nitori bo se nifẹ si ẹgbẹ agbabọslu Arsenal, ẹnu ko gba iroyin. Ko fẹẹ si agbabọọlu Arsenal tẹlẹ abi lọwọlọwọ bayii ti mama naa ko lee darukọ, to si ni oun maa n wo bọọlu ninu ile oun tabi lọ sawọn ibudo ti wọn ti n wo bọọlu. Bakan naa lo ni oun maa n lọ sawọn papa isere idaraya nilu Eko lati wo ere bọọlu, ti oun si nifẹ ere sisa, awọn ere idaraya miran lorisirisi, paapaa ẹgbẹ agbabọọlu Arsenal.
Mama Arsenal: Ẹgbẹ́ kan ti fún màmá ní ẹ̀bùn owó Bi a ba ku, iṣe o tan ni Yoruba maa n wi. Bẹẹ gẹlẹ ni ọrọ ri pẹlu mama agba ololufẹ ẹgbẹ agbabọọlu Arsenal, Nosimatu Hassan. Mama to jẹ ẹni ọdun mẹtadinlọgọrin di ẹni ti ọgọọrọ eeyan n sọ nipa rẹ lori ayelujara lẹyin ti sọ ọpọ ọrọ nipa ẹgbẹ agbabọọlu to yan laayo. Lati igba naa ọpọ ẹlẹyinju aanu ọmọ Naijiria ti n ṣeleri lati fun mama ni ẹbun kan tabi omiiran. Ṣugbọn ni bayii, ẹgbẹ ololufẹ awọn ikọ agbabọọlu Naijiria, Authentic Nigeria Supporters' Club ti fun mama ni ẹbun owo rọgun rọgun. Owo ti ẹgbẹ ololufẹ agbabọọlu Naijiria naa fun mama Arsenal ni ṣe ẹgbẹrun un lọna ọta le lugba o din mẹwaa. Ọlọ́run ló yàn mí ti Arsenal, mi ò lè fi wọ́n sílẹ̀ láéláé- Mama Arsenal yarí Ara meriri , mo ri ori ologbo lori atẹ ni ọrọ mama agba kan, Nosimatu Hazzan, ti ọpọ eeyan mọ si mama Arsenal. Mama agba yii, to nifẹ ẹgbẹ agbabọọlu Arsenal bii oju, ti ọjọ ori rẹ yoo si to aadọrin ọdun, lo nifẹ ere bọọlu ju ọmọde tabi awọn ọkunrin miran lọ. Lasiko ti BBC se abẹwo si ọdọ mama naa, ti ọpọ eeyan mọ si Mama Arsenal nitori bo se nifẹ si ẹgbẹ agbabọslu Arsenal, ẹnu ko gba iroyin. Ko fẹẹ si agbabọọlu Arsenal tẹlẹ abi lọwọlọwọ bayii ti mama naa ko lee darukọ, to si ni oun maa n wo bọọlu ninu ile oun tabi lọ sawọn ibudo ti wọn ti n wo bọọlu. Bakan naa lo ni oun maa n lọ sawọn papa isere idaraya nilu Eko lati wo ere bọọlu, ti oun si nifẹ ere sisa, awọn ere idaraya miran lorisirisi, paapaa ẹgbẹ agbabọọlu Arsenal.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-53304170
3politics
Shuahib Afolabi Salisu: Òótọ́ ni mo súnmọ́ Gómìnà ṣùgbọ́n mo kúnjú òṣùwọ̀n ni mo ṣe gba láti díje dupò
Ẹgbẹ APC nikan lo fẹ́ ẹ ku ninu gbogbo ẹgbẹ nipainlẹ Ogun bayii- Omo Yayi Alhaji Shuahib Afolabi Salisu to n dije dupo aṣojuṣofin fun ẹkun aarin gbungbun ipinle Ogun ba BBC Yoruba sọrọ lori ohun to n ṣẹlẹ ni ipinlẹ Ogun bayii. O mẹnuba iriri rẹ ninu oṣelu lati kekere titi di asiko yii. O sọ awọn ipenija, aṣẹyọri ati ikuna to ti koju ninu iṣelu titi di asiko yii ki awọn ọdọ le kọ ẹkọ ti o yẹ. Omọ Yayi tun ṣalaye ohun to ni lọkan lati ṣe fun ọdọ, awọn obinrin ati awọn Oludibo lapapọ. O mẹnuba ohun to maa jẹ ki ara rọ gbogbo ilu lasiko yii. Bakan naa ni Shuahib Afolabi Salisu sọrọ lori ibi ti iselu ipinlẹ Ogun dẹ duro ati ajọṣepọ to wa laarin Gomina Dapo Abiodun ati awọn ẹka iṣẹjoba to ku nibẹ. O ni pe ko si rukerudo ninu ile igbimọ Aṣofin ni ipinlẹ Ogun bayii.
Shuahib Afolabi Salisu: Òótọ́ ni mo súnmọ́ Gómìnà ṣùgbọ́n mo kúnjú òṣùwọ̀n ni mo ṣe gba láti díje dupò Ẹgbẹ APC nikan lo fẹ́ ẹ ku ninu gbogbo ẹgbẹ nipainlẹ Ogun bayii- Omo Yayi Alhaji Shuahib Afolabi Salisu to n dije dupo aṣojuṣofin fun ẹkun aarin gbungbun ipinle Ogun ba BBC Yoruba sọrọ lori ohun to n ṣẹlẹ ni ipinlẹ Ogun bayii. O mẹnuba iriri rẹ ninu oṣelu lati kekere titi di asiko yii. O sọ awọn ipenija, aṣẹyọri ati ikuna to ti koju ninu iṣelu titi di asiko yii ki awọn ọdọ le kọ ẹkọ ti o yẹ. Omọ Yayi tun ṣalaye ohun to ni lọkan lati ṣe fun ọdọ, awọn obinrin ati awọn Oludibo lapapọ. O mẹnuba ohun to maa jẹ ki ara rọ gbogbo ilu lasiko yii. Bakan naa ni Shuahib Afolabi Salisu sọrọ lori ibi ti iselu ipinlẹ Ogun dẹ duro ati ajọṣepọ to wa laarin Gomina Dapo Abiodun ati awọn ẹka iṣẹjoba to ku nibẹ. O ni pe ko si rukerudo ninu ile igbimọ Aṣofin ni ipinlẹ Ogun bayii.
https://www.bbc.com/yoruba/63658710
5sports
Odion Ighalo: Ó di 2021 kí Ighalo tó fi Manchester United
Ẹgbẹ agbabọọlu Manchester United ti sọ idi ti wọn fi ṣe adehun tuntun pẹlu ẹlẹsẹ ayo, Odion Ighalo eyi ti yoo mu un di oṣu ọdun 2021 pẹlu ikọ naa. Lori opo ayelujara ikansiraẹni Twitter ni Man U ti fidi ọrọ naa mulẹ lọjọ Aje. Lasiko ti ọja rira agbabọọlu ṣi silẹ ninu oṣu kinni ọdun 2020 ni Ighalo darapọ mọ Manchester United lati ikọ agbabọọlu China, Shanghai Shenhua. Ighalo ti gba goolu mẹrin sawọn lẹẹmẹrin ninu ifẹsẹwọnsẹ mẹjọ to lanfaani lati ṣoju Man U ninu rẹ ki o to di wi pe wọn so ere bọọlu rọ nilẹ Gẹẹsi nitori ajakalẹ aarun coronavirus. Ẹwẹ, ẹgbẹ agbabọọlu Man U ti sọ loju opo Twitter pe ohun to jẹ kawọn ṣe adehun tuntun pẹlu Ighalo ni pe o farajin ṣiṣẹ atawọn goolu to ti gba sawọn. Ti ẹ ko ba gbagbe, Ighalo gan an fun ra rẹ ṣalaye laipẹ yii bi o ti fi owo ounjẹ ọsan rẹ lọ wo ere bọọlu Man U. O ni oun atawọn ẹgbọn ati aburo oun maa n ya owo sọtọ ninu owo ounjẹ lati le lanfaani wo Manchester United. Akọnimọọgba ẹgbẹ agbabọọlu Man U, Ole Gunnar Solskjaer sọ pe oun fẹ ki Ighalo gba ife ẹyẹ pẹlu Man U ko to fi ẹgbẹ agbabọọlu naa silẹ.
Odion Ighalo: Ó di 2021 kí Ighalo tó fi Manchester United Ẹgbẹ agbabọọlu Manchester United ti sọ idi ti wọn fi ṣe adehun tuntun pẹlu ẹlẹsẹ ayo, Odion Ighalo eyi ti yoo mu un di oṣu ọdun 2021 pẹlu ikọ naa. Lori opo ayelujara ikansiraẹni Twitter ni Man U ti fidi ọrọ naa mulẹ lọjọ Aje. Lasiko ti ọja rira agbabọọlu ṣi silẹ ninu oṣu kinni ọdun 2020 ni Ighalo darapọ mọ Manchester United lati ikọ agbabọọlu China, Shanghai Shenhua. Ighalo ti gba goolu mẹrin sawọn lẹẹmẹrin ninu ifẹsẹwọnsẹ mẹjọ to lanfaani lati ṣoju Man U ninu rẹ ki o to di wi pe wọn so ere bọọlu rọ nilẹ Gẹẹsi nitori ajakalẹ aarun coronavirus. Ẹwẹ, ẹgbẹ agbabọọlu Man U ti sọ loju opo Twitter pe ohun to jẹ kawọn ṣe adehun tuntun pẹlu Ighalo ni pe o farajin ṣiṣẹ atawọn goolu to ti gba sawọn. Ti ẹ ko ba gbagbe, Ighalo gan an fun ra rẹ ṣalaye laipẹ yii bi o ti fi owo ounjẹ ọsan rẹ lọ wo ere bọọlu Man U. O ni oun atawọn ẹgbọn ati aburo oun maa n ya owo sọtọ ninu owo ounjẹ lati le lanfaani wo Manchester United. Akọnimọọgba ẹgbẹ agbabọọlu Man U, Ole Gunnar Solskjaer sọ pe oun fẹ ki Ighalo gba ife ẹyẹ pẹlu Man U ko to fi ẹgbẹ agbabọọlu naa silẹ.
https://www.bbc.com/yoruba/media-52887815
3politics
Iná sọ nílé Akin Ogunbiyi tó ń díje du ípò gómìnà ní ìpínlẹ̀ Osun, ọ̀pọ̀ dúkìá ṣòfò
Ina ti jo ile oludije sipo gomina nipinlẹ Osun labẹ asia ẹgbẹ oṣelu Accord, Akin Ogunbiyi. Iroyin ni aarọ kutu ọjọ Isinimi ni ina ọhun dede ṣẹyọ, to si ba ile naa atawọn dukia mii to wa ninu ọhun jẹ ni Ileogbo, to wa ni ijọba ibilẹ Ayedire. Ile ọhun, to dojukọ ọọfisi ijọba ibilẹ Ayedire ni Ogunbi sọ pe oun ko mọ ohun to ṣokunfa bi ina ṣe sọ nibẹ. Nigba ti BBC Yoruba kan si Ogunbiyi, agbẹnusọ rẹ, Steven Owolabi ṣalayae pe ile ijọsin ni oludije naa wa ki wọn to ke si pe ina ti sọ ninu ile rẹ. O ni “Lootọ ni ina jo ile naa, amọ a ti yanju gbogbo rẹ.” “A ko mọ ohun to ṣokunfa ina naa titi di asiko yii, bẹẹ ina ọhun kii ṣe ina kekere.” “Inu yara rẹ ni ina naa ti bẹrẹ, gbogbo yara naa lo jona, bẹẹ naa ni awọn iwe kan to ṣe pataki ba ina ọhun lọ.” Owolabi ṣalaye siwaju si pe “Ọna ile ijọsin ló wa ki wọn to ke si pe ile rẹ ti n jona, adupẹ lọwọ Ọlọrun pe kii ṣe oru ọganjọ ni ina ọhun ṣẹyọ, ohun ti a n sọ bayii kọ ni a ba maa sọ... nitori ko si nnkankan to ṣeku ninu yara yẹn.” O pari ọrọ rẹ pe ko si ẹnikẹni to farapa ninu ijamba ina ọhun.
Iná sọ nílé Akin Ogunbiyi tó ń díje du ípò gómìnà ní ìpínlẹ̀ Osun, ọ̀pọ̀ dúkìá ṣòfò Ina ti jo ile oludije sipo gomina nipinlẹ Osun labẹ asia ẹgbẹ oṣelu Accord, Akin Ogunbiyi. Iroyin ni aarọ kutu ọjọ Isinimi ni ina ọhun dede ṣẹyọ, to si ba ile naa atawọn dukia mii to wa ninu ọhun jẹ ni Ileogbo, to wa ni ijọba ibilẹ Ayedire. Ile ọhun, to dojukọ ọọfisi ijọba ibilẹ Ayedire ni Ogunbi sọ pe oun ko mọ ohun to ṣokunfa bi ina ṣe sọ nibẹ. Nigba ti BBC Yoruba kan si Ogunbiyi, agbẹnusọ rẹ, Steven Owolabi ṣalayae pe ile ijọsin ni oludije naa wa ki wọn to ke si pe ina ti sọ ninu ile rẹ. O ni “Lootọ ni ina jo ile naa, amọ a ti yanju gbogbo rẹ.” “A ko mọ ohun to ṣokunfa ina naa titi di asiko yii, bẹẹ ina ọhun kii ṣe ina kekere.” “Inu yara rẹ ni ina naa ti bẹrẹ, gbogbo yara naa lo jona, bẹẹ naa ni awọn iwe kan to ṣe pataki ba ina ọhun lọ.” Owolabi ṣalaye siwaju si pe “Ọna ile ijọsin ló wa ki wọn to ke si pe ile rẹ ti n jona, adupẹ lọwọ Ọlọrun pe kii ṣe oru ọganjọ ni ina ọhun ṣẹyọ, ohun ti a n sọ bayii kọ ni a ba maa sọ... nitori ko si nnkankan to ṣeku ninu yara yẹn.” O pari ọrọ rẹ pe ko si ẹnikẹni to farapa ninu ijamba ina ọhun.
https://www.bbc.com/yoruba/articles/cjk0d566d02o
1entertainment
Kunle Adeyanju ti gun orí àpáta Kilimanjaro rí, ó sì ti gun alùpùpù láti Naijiria lọ sí Ghana
Arakunrin ọmọ orileede Naijiria to n gun alaupupu bọ lati London ti balẹ si Naijiria bayii. Kunle Adeyanju bẹrẹ irinajo yi lati London to si kan si awọn orileede Afrika ko to de ilẹ baba rẹ lọjọ Aiku yi. Nise lawọn eeyan to ti n fi ọkan ba irinajo rẹ bọ tu yaya jade lati wa pade rẹ Ni ibode Naijiria pẹlu orileede Benin to wa ni Seme ni awọn ololufẹ rẹ ti wa ki kaabọ. Shina Peller àti Teslim Folarin tahùn síra wọn lórí ẹ̀sùn ìpànìyàn, wàhálà ṣẹlẹ̀ n'ídìbò abẹ́nú Oyo 'Ìdí rèé tí mo fi ń sin ẹkùn méjì nínú ilé mí' "Kunle Adeyanju ti gun orí àpáta Kilimanjaro rí, ó sì ti gun alùpùpù láti Naijiria lọ sí Ghana". Ọmọ Naijiria to n wa alupupu lati ilu London nilẹ Gẹẹsi, siluu Eko ni Naijiria, Kunle Adeyanju ti ṣalaye eredi to ṣe gbe igbesẹ naa. Ninu ifọrọwerọ pẹlu BBC Yoruba, Adeyanju ni ọna ati tan iṣoro awọn eeyan lo mu ki oun gbe igbesẹ naa. O ni oun tun gbe igbesẹ ọhun nitori oun jẹ ẹnikan to fẹran lati maa rin irinajo to le. Kunle Adeyanju sọ fun BBC Yoruba pe kii ṣe igba akọkọ ree ti oun yoo gun alupupu lati orilẹ-ede kan si omiran. O ni ''Mo fẹran lati maa ṣe awon ohun akinkanju, mo si fẹran irinajo to le.'' ''Mo ti gun ori apata Kilimanjaro ri, eyii to jẹ ori apata to ga julọ nilẹ Afrika.'' ''Bakan naa ni mo ti wa alupupu lati Naijiria lọ si orilẹ-ede Ghana ri, ti mo tun gun alupupu pada wa si Naijiria.'' ''Nigba ti mo pinnu lati rin irinajo yii lati ilu London si Naijiria, mo woye pe bawo ni mo ṣe le ṣe lati fi tu awọn eeyan lọrun ki n si fi ṣe awọn araalu loore.'' O ni yatọ si pe oun fẹran awọn irinajo to le, oun tun gunle irinajo naa lati ṣe ikowojọ fun awọn alaini, ati lati fi gbogun ti aisan to n ba awọn eeyan finra bii polio. Ọjọ kọkandinlogun, oṣu Kẹrin, ọdun 2022 yii ni Adeyanju gbera kuro niluu London pẹlu alupupu rẹ, ti ireti ṣi wa pe yoo gunlẹ si Naijiria lọjọ Isinmi, ọjọ kọkandinlọgbọn, oṣu Karun un, ọdun 2022.
Kunle Adeyanju ti gun orí àpáta Kilimanjaro rí, ó sì ti gun alùpùpù láti Naijiria lọ sí Ghana Arakunrin ọmọ orileede Naijiria to n gun alaupupu bọ lati London ti balẹ si Naijiria bayii. Kunle Adeyanju bẹrẹ irinajo yi lati London to si kan si awọn orileede Afrika ko to de ilẹ baba rẹ lọjọ Aiku yi. Nise lawọn eeyan to ti n fi ọkan ba irinajo rẹ bọ tu yaya jade lati wa pade rẹ Ni ibode Naijiria pẹlu orileede Benin to wa ni Seme ni awọn ololufẹ rẹ ti wa ki kaabọ. Shina Peller àti Teslim Folarin tahùn síra wọn lórí ẹ̀sùn ìpànìyàn, wàhálà ṣẹlẹ̀ n'ídìbò abẹ́nú Oyo 'Ìdí rèé tí mo fi ń sin ẹkùn méjì nínú ilé mí' "Kunle Adeyanju ti gun orí àpáta Kilimanjaro rí, ó sì ti gun alùpùpù láti Naijiria lọ sí Ghana". Ọmọ Naijiria to n wa alupupu lati ilu London nilẹ Gẹẹsi, siluu Eko ni Naijiria, Kunle Adeyanju ti ṣalaye eredi to ṣe gbe igbesẹ naa. Ninu ifọrọwerọ pẹlu BBC Yoruba, Adeyanju ni ọna ati tan iṣoro awọn eeyan lo mu ki oun gbe igbesẹ naa. O ni oun tun gbe igbesẹ ọhun nitori oun jẹ ẹnikan to fẹran lati maa rin irinajo to le. Kunle Adeyanju sọ fun BBC Yoruba pe kii ṣe igba akọkọ ree ti oun yoo gun alupupu lati orilẹ-ede kan si omiran. O ni ''Mo fẹran lati maa ṣe awon ohun akinkanju, mo si fẹran irinajo to le.'' ''Mo ti gun ori apata Kilimanjaro ri, eyii to jẹ ori apata to ga julọ nilẹ Afrika.'' ''Bakan naa ni mo ti wa alupupu lati Naijiria lọ si orilẹ-ede Ghana ri, ti mo tun gun alupupu pada wa si Naijiria.'' ''Nigba ti mo pinnu lati rin irinajo yii lati ilu London si Naijiria, mo woye pe bawo ni mo ṣe le ṣe lati fi tu awọn eeyan lọrun ki n si fi ṣe awọn araalu loore.'' O ni yatọ si pe oun fẹran awọn irinajo to le, oun tun gunle irinajo naa lati ṣe ikowojọ fun awọn alaini, ati lati fi gbogun ti aisan to n ba awọn eeyan finra bii polio. Ọjọ kọkandinlogun, oṣu Kẹrin, ọdun 2022 yii ni Adeyanju gbera kuro niluu London pẹlu alupupu rẹ, ti ireti ṣi wa pe yoo gunlẹ si Naijiria lọjọ Isinmi, ọjọ kọkandinlọgbọn, oṣu Karun un, ọdun 2022.
https://www.bbc.com/yoruba/media-61623688
2health
coronavirus: Ìdí tí obìnrin fi leè rù ú là ju ọkùnrin lọ
O n dabi ẹni pe o ṣeeṣe fun ọkunrin lati ku lọwọ arun Coronavirus to n ja nilẹ bayii ju awọn ọkunrin lọ. Bakan naa si ni ko ṣeeṣe fawọn ọmọde lati ku nipasẹ arun naa to bi awọn agba lọ. Ọpọlọpọ awọn eeyan lo jẹ wi pe arun yii yoo kan ṣi ni fila lọ ni, ṣugbọn awọn miran a maa tipasẹ arun yii dero ọrun. Ti o ba ri bẹẹ, ki wa gan an lo n fa iyatọ laarin bi ọṣẹ arun yii ṣe le si laarin ẹya akọ atabo tabi ara awọn ọmọ wẹwẹ ati agbalagba? Gbogbo awọn iroyin ti a ri kojọ lori eyi wa latawọn iwadii gbankọ gbi tawọn ibudo amojuto ajakalẹ arun lorilẹede China ṣe, Chinese Centers of Disease Control. ẹgbẹrun mẹrinlelogoji (44,000) ni iwadii naa gbe yẹwo ninu eyi to ti fihan pe ida mẹta din diẹ ninu ọgọrun (2.8%) awọn ọkunrin to ko arun Coronavirus yii lo jade laye; bẹẹni ida meji o din diẹ ninu ọgọrun (1.7%) awọn obirin to ko arun naa lo jade laye. Bẹẹni ko tilẹ sun mọ ida kan ninu ọgọrun (0.2%) awọn ọmọde ati ọṣọrọ ọdọ to ko arun yii to jade laye; nigba ti ida marundinlogun (15%) awọn agbalagba ti ọjọ ori wọn ti ju ọgọrin ọdun lọ laisan Coronavirus ti ran lọ sọrun. Ọna meji ni a le gba ṣalaye abajade iwadii naa lori eyii. Yala ko jẹ wi pe awọn obirin atọmọde ko lee saba ko arun yii tabi ko jẹ wi pe awọn ẹya ara wọn lagbara lati koju kokoro arun coronavirus ọhun. 'Koko pataki kan ni wi pe, kokoro arun tuntun yii n tan kalẹ, gbogbo eeyan lo si lee ko o." Eyi jẹ ọrọ Dokita Bharat Pankhania lati fasiti Exeter sọ. Idi eyi ni pe ko si ajẹsara kankan ninu agọ ara to lee dena arun yii nitori ko si ẹnu to lugbadi rẹ ṣaaju asiko yii ri. Lootọ o, lasiko ti arun naa ṣẹṣẹ bẹẹ, o ṣoro diẹ fun awọn ọmọde lati ko kokoro arun naa. Yoo ya ọ lẹnu pe iyatọ gedegbe wa laarin iye awọn ọkunrin ati obinrin to n ku nipasẹ arun yii? Ṣugbọn eyi ko ya awọn onimọ sayẹnsi lẹnu o. Bi a ko ba ni jayopa, bakan naa lọrọ ṣe rilawọn aisan miran bii otutu. Lara idahun si eyi naa ni pe, igbe aye awọn ọkunrin buru jai ju tawọn obirin lọ lawọn nnkan ti wọn n ṣe bii siga mimu. "Siga n ba ẹdọ jẹ. Iru ẹni bẹẹ ko lee yee rara." Gẹgẹ bi Dokita Nathalie MacDermott lati ile ẹkọ giga Kings College ni ilu London ṣe sọ. Eyi ṣeeṣe ko fa wahala nla lorilẹede China nibi ti iwadii ti fihan pe nnkan bi ida mejilelaadọta ninu ọgọrun awọn ọkunrin wọn lo n ṣana si siga ti o si jẹ pe iwọn perete ida mẹta nini ọgọrun awọn obinrin lo n mu siga nibẹ. Bakan naa ni iwadii fihan pe iyatọ wa laarin eroja ajẹsara abawaye awọn obinrin ati ti ọkunrin ati ọna ti awọn eroja ajẹsara yii maa fi n gbera sọ nigbakugba ti aisan tabi arun kan ba fẹ dide. Làá hàn mí dé, ètò tó ń ṣàlàyé ohun tó yẹ ká ṣe láti dènà àrùn Coronavirus Mi o tíì rí olórí tó fẹ́ràn Naijiria tó Baba Obasanjo- Yoruba Council of Elders Idahun awọn ọjọgbọn ni pe 'rara'ṣugbọn awọn akọṣẹmọṣẹ kan ti n sọ ọ wi pe o ṣeeṣe o ki ọrọ maa ri bẹẹ Oriṣiriṣi nnkan ni oyun nini maa n ṣe fun ara, lara rẹ si ni dindin agbara awọn eroja ajẹsara ara ku. Eyi si maa n mu ki wọn wa larọwọto ọpọlọpọ kokoro arun lasiko oyun yii. Ijọba ilẹ Gẹẹsi ni 'ko si ami kan gboogi' to fihan pe awọn obirin to ba loyun lee fara kaasa arun coronavirus ju awọn ti ko loyun lọ. Awọn ọmọde lee ko arun Coronavirus. Iroyin tilẹ ti fi idi rẹ mulẹ pe ninu awọn to ti ni arun Ccoronavirus lagbaye bayii, ọmọ kekere jojolo ti wọn ṣẹṣẹ bi wa lara wọn. Iyatọ nla wa laarin ilana eroja ajẹsara amuwaye (immune system) ọmọde ati ti agbalagba. Awọn eroja yii lara awọn ọmọde maa n ṣiṣẹ ni kiakia ni; wọn a si maa jẹ iṣẹ kọja ibi ti wọn ba ran wọn de nigba miran. Eleyii lo maa n faa tawọn ọmọde maa fi n saba n ni aisan iba. Bi awọn eroja yii ba n jẹ iṣẹ kọja ala, wọn le ṣe akoba fun awọn eroja ara yoku, ara idi si niyi ti awọn arun coronavirus lee mu iku dani. Amọṣa gẹgẹ bi Dokita MacDermott ṣe sọ, eyi kii waye pẹlu arun Coronavirus lara awọn ọmọde o, ko si si ẹni to mọ ohun ti arun naa n ṣe lara awọn ọmọde ti eyi fi ri bẹẹ.
coronavirus: Ìdí tí obìnrin fi leè rù ú là ju ọkùnrin lọ O n dabi ẹni pe o ṣeeṣe fun ọkunrin lati ku lọwọ arun Coronavirus to n ja nilẹ bayii ju awọn ọkunrin lọ. Bakan naa si ni ko ṣeeṣe fawọn ọmọde lati ku nipasẹ arun naa to bi awọn agba lọ. Ọpọlọpọ awọn eeyan lo jẹ wi pe arun yii yoo kan ṣi ni fila lọ ni, ṣugbọn awọn miran a maa tipasẹ arun yii dero ọrun. Ti o ba ri bẹẹ, ki wa gan an lo n fa iyatọ laarin bi ọṣẹ arun yii ṣe le si laarin ẹya akọ atabo tabi ara awọn ọmọ wẹwẹ ati agbalagba? Gbogbo awọn iroyin ti a ri kojọ lori eyi wa latawọn iwadii gbankọ gbi tawọn ibudo amojuto ajakalẹ arun lorilẹede China ṣe, Chinese Centers of Disease Control. ẹgbẹrun mẹrinlelogoji (44,000) ni iwadii naa gbe yẹwo ninu eyi to ti fihan pe ida mẹta din diẹ ninu ọgọrun (2.8%) awọn ọkunrin to ko arun Coronavirus yii lo jade laye; bẹẹni ida meji o din diẹ ninu ọgọrun (1.7%) awọn obirin to ko arun naa lo jade laye. Bẹẹni ko tilẹ sun mọ ida kan ninu ọgọrun (0.2%) awọn ọmọde ati ọṣọrọ ọdọ to ko arun yii to jade laye; nigba ti ida marundinlogun (15%) awọn agbalagba ti ọjọ ori wọn ti ju ọgọrin ọdun lọ laisan Coronavirus ti ran lọ sọrun. Ọna meji ni a le gba ṣalaye abajade iwadii naa lori eyii. Yala ko jẹ wi pe awọn obirin atọmọde ko lee saba ko arun yii tabi ko jẹ wi pe awọn ẹya ara wọn lagbara lati koju kokoro arun coronavirus ọhun. 'Koko pataki kan ni wi pe, kokoro arun tuntun yii n tan kalẹ, gbogbo eeyan lo si lee ko o." Eyi jẹ ọrọ Dokita Bharat Pankhania lati fasiti Exeter sọ. Idi eyi ni pe ko si ajẹsara kankan ninu agọ ara to lee dena arun yii nitori ko si ẹnu to lugbadi rẹ ṣaaju asiko yii ri. Lootọ o, lasiko ti arun naa ṣẹṣẹ bẹẹ, o ṣoro diẹ fun awọn ọmọde lati ko kokoro arun naa. Yoo ya ọ lẹnu pe iyatọ gedegbe wa laarin iye awọn ọkunrin ati obinrin to n ku nipasẹ arun yii? Ṣugbọn eyi ko ya awọn onimọ sayẹnsi lẹnu o. Bi a ko ba ni jayopa, bakan naa lọrọ ṣe rilawọn aisan miran bii otutu. Lara idahun si eyi naa ni pe, igbe aye awọn ọkunrin buru jai ju tawọn obirin lọ lawọn nnkan ti wọn n ṣe bii siga mimu. "Siga n ba ẹdọ jẹ. Iru ẹni bẹẹ ko lee yee rara." Gẹgẹ bi Dokita Nathalie MacDermott lati ile ẹkọ giga Kings College ni ilu London ṣe sọ. Eyi ṣeeṣe ko fa wahala nla lorilẹede China nibi ti iwadii ti fihan pe nnkan bi ida mejilelaadọta ninu ọgọrun awọn ọkunrin wọn lo n ṣana si siga ti o si jẹ pe iwọn perete ida mẹta nini ọgọrun awọn obinrin lo n mu siga nibẹ. Bakan naa ni iwadii fihan pe iyatọ wa laarin eroja ajẹsara abawaye awọn obinrin ati ti ọkunrin ati ọna ti awọn eroja ajẹsara yii maa fi n gbera sọ nigbakugba ti aisan tabi arun kan ba fẹ dide. Làá hàn mí dé, ètò tó ń ṣàlàyé ohun tó yẹ ká ṣe láti dènà àrùn Coronavirus Mi o tíì rí olórí tó fẹ́ràn Naijiria tó Baba Obasanjo- Yoruba Council of Elders Idahun awọn ọjọgbọn ni pe 'rara'ṣugbọn awọn akọṣẹmọṣẹ kan ti n sọ ọ wi pe o ṣeeṣe o ki ọrọ maa ri bẹẹ Oriṣiriṣi nnkan ni oyun nini maa n ṣe fun ara, lara rẹ si ni dindin agbara awọn eroja ajẹsara ara ku. Eyi si maa n mu ki wọn wa larọwọto ọpọlọpọ kokoro arun lasiko oyun yii. Ijọba ilẹ Gẹẹsi ni 'ko si ami kan gboogi' to fihan pe awọn obirin to ba loyun lee fara kaasa arun coronavirus ju awọn ti ko loyun lọ. Awọn ọmọde lee ko arun Coronavirus. Iroyin tilẹ ti fi idi rẹ mulẹ pe ninu awọn to ti ni arun Ccoronavirus lagbaye bayii, ọmọ kekere jojolo ti wọn ṣẹṣẹ bi wa lara wọn. Iyatọ nla wa laarin ilana eroja ajẹsara amuwaye (immune system) ọmọde ati ti agbalagba. Awọn eroja yii lara awọn ọmọde maa n ṣiṣẹ ni kiakia ni; wọn a si maa jẹ iṣẹ kọja ibi ti wọn ba ran wọn de nigba miran. Eleyii lo maa n faa tawọn ọmọde maa fi n saba n ni aisan iba. Bi awọn eroja yii ba n jẹ iṣẹ kọja ala, wọn le ṣe akoba fun awọn eroja ara yoku, ara idi si niyi ti awọn arun coronavirus lee mu iku dani. Amọṣa gẹgẹ bi Dokita MacDermott ṣe sọ, eyi kii waye pẹlu arun Coronavirus lara awọn ọmọde o, ko si si ẹni to mọ ohun ti arun naa n ṣe lara awọn ọmọde ti eyi fi ri bẹẹ.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-51788497
2health
Anti-vaccine mandate protests: Canada ṣetán láti gbẹ́sẹ̀ lé àkáùntì àwọn tó ń ṣẹ ìwọ́de táko abẹ́rẹ́ covid-19
Olootu ijọba orilẹede Canada, Justin Trudeau ti kede pe ijọba yoo gbẹsẹ le akaunti gbogbo awọn to n ṣe iwọde tako gbigba abẹrẹ ajẹsara covid-19. Trudeau ṣalaye pe awọn ile ifopamọ le gbẹsẹ le akaunti awọn to ba ni ohun kan ṣe pẹlu iwọde tako abẹrẹ covid-19. Ọgọọrọ awọn olouwọde ni wọn ti n fi ẹhonu han tako gbigba abẹrẹ coronavirus. Awọn agbofinro lo tu awọn oluwọde naa ka ni Windsor lọjọ Aiku to kọja. Iwọde to bẹrẹ lati tako ikede ijọba pe gbogbo awọn to wa ọkọ akẹru nla ti wọn n gba ibode Canada ati Amẹrika kọja gbọdọ gba abẹrẹ covid-19. Amọ ifẹhonuhan naa ti di ohun ti wọn n fi tako gbogbo eto ijọba lati dẹna coronavirus bayii. Trudeau ni ''igbesẹ yii wa lati ri pe awọn eeyan Canada ko si ninu ewu. Bakan naa ni a tun n ṣe eleyii lati daabo bo iṣẹ awọn eeyan ni Canada.'' Olootu ijọba ilẹ Canada ni ijọba yoo fawọn ọlọpaa ni irinṣẹ ti wọn nilo lati ju awọn oluwọde si atimọle ati lati daabo bo ohun amayedẹrun. Ọpọ koro oju si Trudeau lori igbesẹ rẹ lẹyin ti wọn lo ṣe atilẹyin fawọn agbẹ ti wọn di ọna mọrosẹ ni India lọdun 2021 lasiko ti wọn n ṣe iwọde. Wọn ni Trudeau lo fẹnu ara rẹ sọ pe Canada ko le ṣalai ṣe atilẹyin fawọn to n ba ṣe iwọde wọọrọwọ. Igbakeji olootu ijọba Canada naa, Chrystia Freeland sọ pe awọn banki le gbẹsẹ le akaunti ẹnikẹni to ba kopa ninu ifẹhonuhan ọhun. Freeland fikun ọrọ rẹ pe iwe adojutofo ọkọ ẹnikẹni to ba ni ohun kan ṣe pẹlu iwọde naa le ni idaduro fun igba diẹ. Freeland ni ijọba n lo eleyii lati mọ awọn to n pese owo fawọn oluwode. O sọrọ yii lẹyin tawọn onijibi ori ayelujara sọ pe eeyan ẹgbẹrun lọna mẹtalelaadọrun lo ṣe irawọn owo to le ni miliọnu mẹjo ($8.4m) fawọn awakọ nla akẹru.
Anti-vaccine mandate protests: Canada ṣetán láti gbẹ́sẹ̀ lé àkáùntì àwọn tó ń ṣẹ ìwọ́de táko abẹ́rẹ́ covid-19 Olootu ijọba orilẹede Canada, Justin Trudeau ti kede pe ijọba yoo gbẹsẹ le akaunti gbogbo awọn to n ṣe iwọde tako gbigba abẹrẹ ajẹsara covid-19. Trudeau ṣalaye pe awọn ile ifopamọ le gbẹsẹ le akaunti awọn to ba ni ohun kan ṣe pẹlu iwọde tako abẹrẹ covid-19. Ọgọọrọ awọn olouwọde ni wọn ti n fi ẹhonu han tako gbigba abẹrẹ coronavirus. Awọn agbofinro lo tu awọn oluwọde naa ka ni Windsor lọjọ Aiku to kọja. Iwọde to bẹrẹ lati tako ikede ijọba pe gbogbo awọn to wa ọkọ akẹru nla ti wọn n gba ibode Canada ati Amẹrika kọja gbọdọ gba abẹrẹ covid-19. Amọ ifẹhonuhan naa ti di ohun ti wọn n fi tako gbogbo eto ijọba lati dẹna coronavirus bayii. Trudeau ni ''igbesẹ yii wa lati ri pe awọn eeyan Canada ko si ninu ewu. Bakan naa ni a tun n ṣe eleyii lati daabo bo iṣẹ awọn eeyan ni Canada.'' Olootu ijọba ilẹ Canada ni ijọba yoo fawọn ọlọpaa ni irinṣẹ ti wọn nilo lati ju awọn oluwọde si atimọle ati lati daabo bo ohun amayedẹrun. Ọpọ koro oju si Trudeau lori igbesẹ rẹ lẹyin ti wọn lo ṣe atilẹyin fawọn agbẹ ti wọn di ọna mọrosẹ ni India lọdun 2021 lasiko ti wọn n ṣe iwọde. Wọn ni Trudeau lo fẹnu ara rẹ sọ pe Canada ko le ṣalai ṣe atilẹyin fawọn to n ba ṣe iwọde wọọrọwọ. Igbakeji olootu ijọba Canada naa, Chrystia Freeland sọ pe awọn banki le gbẹsẹ le akaunti ẹnikẹni to ba kopa ninu ifẹhonuhan ọhun. Freeland fikun ọrọ rẹ pe iwe adojutofo ọkọ ẹnikẹni to ba ni ohun kan ṣe pẹlu iwọde naa le ni idaduro fun igba diẹ. Freeland ni ijọba n lo eleyii lati mọ awọn to n pese owo fawọn oluwode. O sọrọ yii lẹyin tawọn onijibi ori ayelujara sọ pe eeyan ẹgbẹrun lọna mẹtalelaadọrun lo ṣe irawọn owo to le ni miliọnu mẹjo ($8.4m) fawọn awakọ nla akẹru.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-60391949
4religion
Kí ni ìdí ariwo lórí bí Tinubu ṣe yan Musulumi gẹ́gẹ́ bíi igbákejì Ààrẹ? - CAN dáhùn
Ẹgbẹ ọmọlẹyin Kristi lorilẹede Naijiria ti ni awọn ko pa ohun wọn da lori titako ki ẹsin kan naa dije du ipo aarẹ lorilẹede Naijiria. Agbẹnusọ ẹgbẹ CAN, Pasitọ Adebayo Oladeji lo sọ bẹẹ lasiko to n ba BBC Yoruba sọrọ lori iyansipo gomina ipinlẹ Borno tẹlẹ, Kashim Shettima gẹgẹ bi igbakeji oludije lẹgbẹ oṣelu APC. Oladeji ni ki awọn eniyan ma sọrọ nipa asiko MKO Abiola nitori aye dara nigba naa ju asiko yii lọ. ‘’Ko si didara ti oludije to ba yan Musulumi gẹgẹ bi igbakeji yoo ṣe fun wa.’’ ‘’Ki wọn lọ wọ iwe ofin Naijiria lẹyin ogun abẹlẹ, o yẹ ki wọn ṣe didara si gbogbo ẹya ati ẹsin ni Naijiria’’. ‘’Nigba Abiola ko si Boko Haram to n pa awọn Kristeni, to n jo ṣọṣi abi awọn agbebọn to n ji pasitọ gbe ti wọn si n gba ọkọ awọn eniyan lọwọ wọn.’’ Yiyan igbakeji ẹlẹsin kan naa fihan pe wọn ko naani awa ẹlẹsin  Kristẹni ni Naijiria. Amọ wọn fikun un pe ko si ohun ti awọn le ṣe sii yatọ si ki awọn ọmọ Naijiria dibo fun ẹni ti ọkan wọn ba fẹ ni idibo ọ̀dun to n bọ. Ajafẹtọ ọmọ Naijiria, Aisha Yesufu ni yiyan igbakeji lati inu ẹsin kan naa ko bojumu, awọn ọmọ Naijiria ko si ni gba iru rẹ. Ninu ọrọ tirẹ, Ajafẹtọ awọn ọdọ Rinu Oduala ni kii ṣe pe ọrọ ẹlẹsin kan naa lo wa nilẹ bayii, amọ ohun ti awọn eniyan n bere fun ni ki pinpin ẹtọ ọmọniyan dọgba lorilẹede Naijiria. Amọ agbẹjọro Agba lorilẹeede Naijiria, Festus Keyamo ni oun faramọ ohun ti Tinubu ṣe lori ọrọ igbakeji. Keyamo ni ko si orilẹede kankan ni agbaye to jẹ pe idagbasoke niiṣe pẹlu didọgba awọn ẹlẹsin to wa ni orilẹede naa. O ni ṣiṣe ijọba fun idagbasoke kii ṣe lati gboriyin fun awọn adari ẹsin kan tabi jẹ ki nkan lọ bi wọn ṣe fẹ.
Kí ni ìdí ariwo lórí bí Tinubu ṣe yan Musulumi gẹ́gẹ́ bíi igbákejì Ààrẹ? - CAN dáhùn Ẹgbẹ ọmọlẹyin Kristi lorilẹede Naijiria ti ni awọn ko pa ohun wọn da lori titako ki ẹsin kan naa dije du ipo aarẹ lorilẹede Naijiria. Agbẹnusọ ẹgbẹ CAN, Pasitọ Adebayo Oladeji lo sọ bẹẹ lasiko to n ba BBC Yoruba sọrọ lori iyansipo gomina ipinlẹ Borno tẹlẹ, Kashim Shettima gẹgẹ bi igbakeji oludije lẹgbẹ oṣelu APC. Oladeji ni ki awọn eniyan ma sọrọ nipa asiko MKO Abiola nitori aye dara nigba naa ju asiko yii lọ. ‘’Ko si didara ti oludije to ba yan Musulumi gẹgẹ bi igbakeji yoo ṣe fun wa.’’ ‘’Ki wọn lọ wọ iwe ofin Naijiria lẹyin ogun abẹlẹ, o yẹ ki wọn ṣe didara si gbogbo ẹya ati ẹsin ni Naijiria’’. ‘’Nigba Abiola ko si Boko Haram to n pa awọn Kristeni, to n jo ṣọṣi abi awọn agbebọn to n ji pasitọ gbe ti wọn si n gba ọkọ awọn eniyan lọwọ wọn.’’ Yiyan igbakeji ẹlẹsin kan naa fihan pe wọn ko naani awa ẹlẹsin  Kristẹni ni Naijiria. Amọ wọn fikun un pe ko si ohun ti awọn le ṣe sii yatọ si ki awọn ọmọ Naijiria dibo fun ẹni ti ọkan wọn ba fẹ ni idibo ọ̀dun to n bọ. Ajafẹtọ ọmọ Naijiria, Aisha Yesufu ni yiyan igbakeji lati inu ẹsin kan naa ko bojumu, awọn ọmọ Naijiria ko si ni gba iru rẹ. Ninu ọrọ tirẹ, Ajafẹtọ awọn ọdọ Rinu Oduala ni kii ṣe pe ọrọ ẹlẹsin kan naa lo wa nilẹ bayii, amọ ohun ti awọn eniyan n bere fun ni ki pinpin ẹtọ ọmọniyan dọgba lorilẹede Naijiria. Amọ agbẹjọro Agba lorilẹeede Naijiria, Festus Keyamo ni oun faramọ ohun ti Tinubu ṣe lori ọrọ igbakeji. Keyamo ni ko si orilẹede kankan ni agbaye to jẹ pe idagbasoke niiṣe pẹlu didọgba awọn ẹlẹsin to wa ni orilẹede naa. O ni ṣiṣe ijọba fun idagbasoke kii ṣe lati gboriyin fun awọn adari ẹsin kan tabi jẹ ki nkan lọ bi wọn ṣe fẹ.
https://www.bbc.com/yoruba/articles/cd1kww137e6o
1entertainment
Burna Boy yí ìpinnu padà, yóò kópa ní àjọ̀dún orin lórílẹ̀-èdè South Áfríkà
Gbajugbaja olorin takasufe ọmọ Naijiria Burna Boy ti ni oun yoo jọwọ lara owo tawọn ba pa nibi ode orin ti yoo waye lorileede South Africa fawọn to farakasa Xenophobia. Loju opo Twitter rẹ ni akọrin yii ti fi ọrọ naa hande. Ṣaaju asiko yii, Burna Boy ti leri pe oun ko ni fẹsẹ tẹ ilẹ South Afrika nitori idẹyẹsi sawọn ọmọ ilẹ Afrika mIiran to n waye nibẹ. Ajọdun orin ti o fẹ kopa yii ni yoo jẹ igba akọkọ ti Burna Boy yoo tẹ South Afrika lati ọdun 2017. Lara awọn ti wọn yoo jijọ fi orin bẹnu atẹ lu idẹyẹsi awọn eeyan ilẹ miran ní South Afrika la ti ri awọn akọrin bi Kwesta Jidenna ati Busiswa. Akori ajọdun orin naa ti yoo waye lọjọ kẹtalelogun oṣu Kọkanla ni ''Afirika, pawọ pọ''
Burna Boy yí ìpinnu padà, yóò kópa ní àjọ̀dún orin lórílẹ̀-èdè South Áfríkà Gbajugbaja olorin takasufe ọmọ Naijiria Burna Boy ti ni oun yoo jọwọ lara owo tawọn ba pa nibi ode orin ti yoo waye lorileede South Africa fawọn to farakasa Xenophobia. Loju opo Twitter rẹ ni akọrin yii ti fi ọrọ naa hande. Ṣaaju asiko yii, Burna Boy ti leri pe oun ko ni fẹsẹ tẹ ilẹ South Afrika nitori idẹyẹsi sawọn ọmọ ilẹ Afrika mIiran to n waye nibẹ. Ajọdun orin ti o fẹ kopa yii ni yoo jẹ igba akọkọ ti Burna Boy yoo tẹ South Afrika lati ọdun 2017. Lara awọn ti wọn yoo jijọ fi orin bẹnu atẹ lu idẹyẹsi awọn eeyan ilẹ miran ní South Afrika la ti ri awọn akọrin bi Kwesta Jidenna ati Busiswa. Akori ajọdun orin naa ti yoo waye lọjọ kẹtalelogun oṣu Kọkanla ni ''Afirika, pawọ pọ''
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-50378516
2health
Baby Placenta: Ṣé lóòtọ́ọ́ làwọn kan máa ń fi ibi ọmọ ṣe oògùn?
Yoruba ni tibi-tire la wale aye, tibi-tire la se ẹda eeyan, bi aye ire se wa, naa ni aye ibi se wa. Ni ọjọ ti obinrin ba ti kunlẹ bimọ, ti ọmọ jade eyi tii se ire, naa ni olubi ọmọ yoo jade, eyi ti wọn tun n pe ni ibi ọmọ tabi Placenta ni ede oyinbo. Ni aye atijọ, olubi ọmọ yii se pataki fun ibi ọmọ, baba to ba si gba olubi ọmọ tabi sin bo se yẹ, ni asa Yoruba mọ bii baba ọmọ. Baba ọmọ lo maa n gbe olubi ọmọ ni kere ti ọmọ ba ti bọ lara iya ọmọ tan. Olubi ọmọ tawọn kan maa n pe ni ibi ọmọ jẹ ohun to ṣe pataki laarin oriṣiiriṣii ẹya lorilẹ-ede Naijiria. Ko si ọmọ ti kii ni olubi, nitori ohun gan ni atẹle to n ba ọmọ wa sile aye. Sugbọn oniruuru ọrọ ni awọn eeyan maa n sọ nipa pataki olubi ọmọ, eyi to yẹ ki olukaluku mọ boya o tọ abi ko tọ. Dokita Joseph Akinde, to jẹ onimọ nipa itọju awọn alaboyun ṣalaye pe igbagbọ wa ninu aṣa ibilẹ lasan, ni ohun ti ọpọ eeyan maa n sọ nipa olubi ọmọ. Dokita Akinde sọ pe awọn kan tiẹ ni igbagbọ awọn eeyan kan wipe ibi ọmọ ni ohun ṣe pẹlu ayanmọ ọmọ naa laye. Akinde salaye pe ''Igbagbọ awọn eeyan ni pe ohunkohun ti ẹnikẹni ba ṣe pẹlu ibi ọmọ ni nnkan ṣe pẹlu ohun ti ọmọ naa yoo da laye. Ṣugbọn a ko le fidi eleyi mulẹ ninu iṣẹ iṣegun tabi ninu imọ ijinlẹ sayẹnsi, igbagbọ ninu aṣa lasan ni,'' Dokita Akinde ṣalaye. Amọ dokita onimọ nipa itọju obinrin naa sọ pe, dokita ti ko ri ibi ọmọ gbe fun baba ọmọ ti wọ gau. Wọn ni ọpọ awọn dokita ni wọn ti dunkoko mọ lori ibi ọmọ, koda wọn sọ pe awọn eeyan maa n gbe dokita lọ si ileẹjọ lori órọ ibi ọmọ. Amọ, Dokita Akinde ṣalaye pe aṣa lasan an ni gbogbo rẹ, ko ni ohun kan ṣe pẹlu sayẹnsi. Wo igbagbọ awọn eeyan lori olubi ọmọ, ti wọn se maa n fẹ gba a nile iwosan: Nigba to n salaye oniruuru ọna ti awọn eeyan fi ni igbagbọ ọtọọtọ si pataki ohun ti ibi ọmọ jẹ, Dokita Oyede tun sọ iriri rẹ lori bi awn obi se n lakaka lati gba ibi ọmọ kuro nile iwosan. ''Awọn eeyan kan maa n bo olubi ọmọ mọlẹ, igbagbọ wọn ni pe ibikibi ti ọmọ naa ba wa, o gbọdọ de ibi ti wọn ri ibi rẹ mọ lọjọ kan. Awọn mii tun gbagbọ pe wọn maa n fi olubi ọmọ ṣe oogun, idi niyii ti wọn maa fi n gbaa lati ile iwosan. Mo ranti ni bii ọdun diẹ sẹyin bi ẹbi obinrin kan to bimọ si ile iwosan ijọba ṣe dunkoko mọ dotika to gbẹbi fun obinrin naa nitori ko mọ ibi ti ibi ọmọ wa. Niṣe lawọn ẹbi naa lọ sọ fawọn akọroyin pe dokita naa ti ta olubi ọmọ awọn, o si ti ta ayanmọ rẹ laye,'' Dokita Akinde lo sọ bẹẹ. Alaga ẹgbẹ awọn dokita oniṣegun oyinbo nipinlẹ Cross River, Dokita Innocent Abang naa kin ọrọ Ọgbẹni Akinde lẹyin. Dokita Abang ni ọpọ lo gbagbọ pe ibi ti wọn ba ri ibi ọmọ si ni ayanmọ rẹ wa. Dokita sọ pe awọn tiẹ maa n gbin igi agbọn sori ibi ti wọn ba ri ibi ọmọ si, ''wọn gbagbọ pe bi igi naa ṣe n dagba ni ọmọ naa yoo maa dagba.''
Baby Placenta: Ṣé lóòtọ́ọ́ làwọn kan máa ń fi ibi ọmọ ṣe oògùn? Yoruba ni tibi-tire la wale aye, tibi-tire la se ẹda eeyan, bi aye ire se wa, naa ni aye ibi se wa. Ni ọjọ ti obinrin ba ti kunlẹ bimọ, ti ọmọ jade eyi tii se ire, naa ni olubi ọmọ yoo jade, eyi ti wọn tun n pe ni ibi ọmọ tabi Placenta ni ede oyinbo. Ni aye atijọ, olubi ọmọ yii se pataki fun ibi ọmọ, baba to ba si gba olubi ọmọ tabi sin bo se yẹ, ni asa Yoruba mọ bii baba ọmọ. Baba ọmọ lo maa n gbe olubi ọmọ ni kere ti ọmọ ba ti bọ lara iya ọmọ tan. Olubi ọmọ tawọn kan maa n pe ni ibi ọmọ jẹ ohun to ṣe pataki laarin oriṣiiriṣii ẹya lorilẹ-ede Naijiria. Ko si ọmọ ti kii ni olubi, nitori ohun gan ni atẹle to n ba ọmọ wa sile aye. Sugbọn oniruuru ọrọ ni awọn eeyan maa n sọ nipa pataki olubi ọmọ, eyi to yẹ ki olukaluku mọ boya o tọ abi ko tọ. Dokita Joseph Akinde, to jẹ onimọ nipa itọju awọn alaboyun ṣalaye pe igbagbọ wa ninu aṣa ibilẹ lasan, ni ohun ti ọpọ eeyan maa n sọ nipa olubi ọmọ. Dokita Akinde sọ pe awọn kan tiẹ ni igbagbọ awọn eeyan kan wipe ibi ọmọ ni ohun ṣe pẹlu ayanmọ ọmọ naa laye. Akinde salaye pe ''Igbagbọ awọn eeyan ni pe ohunkohun ti ẹnikẹni ba ṣe pẹlu ibi ọmọ ni nnkan ṣe pẹlu ohun ti ọmọ naa yoo da laye. Ṣugbọn a ko le fidi eleyi mulẹ ninu iṣẹ iṣegun tabi ninu imọ ijinlẹ sayẹnsi, igbagbọ ninu aṣa lasan ni,'' Dokita Akinde ṣalaye. Amọ dokita onimọ nipa itọju obinrin naa sọ pe, dokita ti ko ri ibi ọmọ gbe fun baba ọmọ ti wọ gau. Wọn ni ọpọ awọn dokita ni wọn ti dunkoko mọ lori ibi ọmọ, koda wọn sọ pe awọn eeyan maa n gbe dokita lọ si ileẹjọ lori órọ ibi ọmọ. Amọ, Dokita Akinde ṣalaye pe aṣa lasan an ni gbogbo rẹ, ko ni ohun kan ṣe pẹlu sayẹnsi. Wo igbagbọ awọn eeyan lori olubi ọmọ, ti wọn se maa n fẹ gba a nile iwosan: Nigba to n salaye oniruuru ọna ti awọn eeyan fi ni igbagbọ ọtọọtọ si pataki ohun ti ibi ọmọ jẹ, Dokita Oyede tun sọ iriri rẹ lori bi awn obi se n lakaka lati gba ibi ọmọ kuro nile iwosan. ''Awọn eeyan kan maa n bo olubi ọmọ mọlẹ, igbagbọ wọn ni pe ibikibi ti ọmọ naa ba wa, o gbọdọ de ibi ti wọn ri ibi rẹ mọ lọjọ kan. Awọn mii tun gbagbọ pe wọn maa n fi olubi ọmọ ṣe oogun, idi niyii ti wọn maa fi n gbaa lati ile iwosan. Mo ranti ni bii ọdun diẹ sẹyin bi ẹbi obinrin kan to bimọ si ile iwosan ijọba ṣe dunkoko mọ dotika to gbẹbi fun obinrin naa nitori ko mọ ibi ti ibi ọmọ wa. Niṣe lawọn ẹbi naa lọ sọ fawọn akọroyin pe dokita naa ti ta olubi ọmọ awọn, o si ti ta ayanmọ rẹ laye,'' Dokita Akinde lo sọ bẹẹ. Alaga ẹgbẹ awọn dokita oniṣegun oyinbo nipinlẹ Cross River, Dokita Innocent Abang naa kin ọrọ Ọgbẹni Akinde lẹyin. Dokita Abang ni ọpọ lo gbagbọ pe ibi ti wọn ba ri ibi ọmọ si ni ayanmọ rẹ wa. Dokita sọ pe awọn tiẹ maa n gbin igi agbọn sori ibi ti wọn ba ri ibi ọmọ si, ''wọn gbagbọ pe bi igi naa ṣe n dagba ni ọmọ naa yoo maa dagba.''
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-56834292
3politics
Ibi tí Yorùbá ńfẹ́ kọ́ ni Adebanjo kọjú sí, ẹ̀yìn Tinubu ni Afenifere tò sí -Wale Oshun
Aṣiwaju ẹgbẹ ọmọbibi ilẹ Yoruba, Afenifere Renewal Group, Ọgbẹni Olawalu Oshun, ti sọ pe Bọla Tinubu lawọn n ṣe atilẹyin fun, kii ṣe Peter Obi ti ẹgbẹ oṣelu Labour Party. Ṣaaju ni olori Afenifere, Oloye Ayo Adebanjo sọ nibi eto kan lọjọ Aje pe Obi ni ẹgbẹ naa n tilẹyin. Ọgbẹni Oshun sọ fun BBC pe ohun ti Ẹgbẹ Afẹnifẹre Renewal Group duro ti ni ifẹ ọmọ Yoruba nile ati lẹyin odi, ti o si da awon loju pe ohun to ọgọrọ ọmọ Yoruba n fẹ naa ni ki ọmọ Yoruba to kun oju oṣuwọn o wọle sipo aarẹ. O ni kii ṣe pe ẹgbẹ naa ko ni igbagbọ ninu iṣọkan Naijiria, ati wi pe boya awọn eeyan lati ẹya miran ko ni jade. “Ohun to fa ipinnu wa lati duro ti ọmọ Yoruba laarin awọn to n dije bayii ko ju wi pe, oun lo kun oju oṣuwọn julọ ninu gbogbo oludije fun ipo aarẹ. Ọgbẹni Oshun ni Bola Tinubu, ni awọn rii pe yoo lee yanju awọn ipenija ti o n doju kọ ọmọ Naijiria, leyi ti awọn si ti n fọnrere rẹ ṣaaju akoko yii. Ọrọ ti Afẹnifere sọ yii n fidi ohun ti agbẹnusọ fun ileeṣẹ ipolongo ibo Bola Tinubu, Bayọ Ọnanuga sọ pe ọrọ ara oloye Adebanjọ lo n sọkii ṣe ohun ti ẹgbẹ Afẹnifẹre n fe. Asiwaju ẹgbẹ Yoruba kan ti a mọ si Afẹnifẹre, Oloye Ayọ Adebanjọ ti ṣalaye idi ti ẹgbẹ naa ko fi fẹ ti oludije ẹgbẹ oṣelu APC, Bola Ahmed Tinubu tabi ti PDP Atiku Abubakar lẹyin fun ibo aarẹ Naijiria ti yoo waye lọdun 2023. Asiwaju ẹgbẹ Afẹnifẹre, Oloye Ayọ Adebanjọ ṣalaye nibi apero kan to ṣe pẹl’awọn akọroyin pe iṣọkan ati ilana aparo kan ko ga ju ọkan lọ pẹlu idajọ ododo lti ẹgbẹ naa duro fun lo mu ko pinnu eyi. Adebanjọ n fi apero naa fesi si ọrọ ti ileeṣẹ ipolongo idibo aarẹ fun Bola Ahmed Tinubu fi sita laipẹ yii ni ninu eyi to ti sọ ọ di mimọ pe iṣẹ ara oloye Adebanjọ lo n jẹ o ko jẹ iṣẹ ọmọ Yoruba lori Peter Obi to gbe ka ori. Oludari eto ipolongo fun ileesẹ ipolongo ibo fun Bola Tinubu, Bayọ Ọnanuga ṣalaye bu ẹnu atẹ lu bi Ayọ Adebanjọ ṣe n ṣe atilẹyin fun Peter Obi ti ẹgbẹ oṣelu Labour. Onanuga kọ ọ si oju opo Facebook rẹ pe lootọ Adebanjọ lẹtọ si fifi atilẹyin rẹ han fun oludije yoowu to ba wu u ṣugbọn iṣẹ ara rẹ lo n jẹ, ko yẹ ko wa maa lọ ifẹ ara rẹ mọ ẹgbẹ Afẹnifẹre lẹsẹ pe oun ti oun n fẹ naa ni ẹgbẹ ọhun pẹlu nfẹ. Adebanjọ to fesi si eyi ṣalaye iwa aisi irẹjẹ ni Afẹnifẹre n fẹ to fi gbe ijoko joko si ẹyin Peter Obi gẹgẹ bi oludije to fẹ ti lẹyin. O fi kun pe ilana iṣejọba apapọ tootọ ti oyinbo n pe ni Federalism ni Afẹnifẹre n fẹ. Ayọ Adebanjọ ni lootọ ọpọ awọn aṣiwaju ilẹ Yoruba lo ti kọminu lori igbesẹ naa sugbọn ti oun ti la ọrọ naa ye ti oun si ti jẹ ki wọn mọ pe ilana ẹni kan kii jẹ ki ilẹ fẹ ti Action Group ti Awolowo da silẹ laye ọjọun duro le lori lawọn ṣi n tẹlẹ.
Ibi tí Yorùbá ńfẹ́ kọ́ ni Adebanjo kọjú sí, ẹ̀yìn Tinubu ni Afenifere tò sí -Wale Oshun Aṣiwaju ẹgbẹ ọmọbibi ilẹ Yoruba, Afenifere Renewal Group, Ọgbẹni Olawalu Oshun, ti sọ pe Bọla Tinubu lawọn n ṣe atilẹyin fun, kii ṣe Peter Obi ti ẹgbẹ oṣelu Labour Party. Ṣaaju ni olori Afenifere, Oloye Ayo Adebanjo sọ nibi eto kan lọjọ Aje pe Obi ni ẹgbẹ naa n tilẹyin. Ọgbẹni Oshun sọ fun BBC pe ohun ti Ẹgbẹ Afẹnifẹre Renewal Group duro ti ni ifẹ ọmọ Yoruba nile ati lẹyin odi, ti o si da awon loju pe ohun to ọgọrọ ọmọ Yoruba n fẹ naa ni ki ọmọ Yoruba to kun oju oṣuwọn o wọle sipo aarẹ. O ni kii ṣe pe ẹgbẹ naa ko ni igbagbọ ninu iṣọkan Naijiria, ati wi pe boya awọn eeyan lati ẹya miran ko ni jade. “Ohun to fa ipinnu wa lati duro ti ọmọ Yoruba laarin awọn to n dije bayii ko ju wi pe, oun lo kun oju oṣuwọn julọ ninu gbogbo oludije fun ipo aarẹ. Ọgbẹni Oshun ni Bola Tinubu, ni awọn rii pe yoo lee yanju awọn ipenija ti o n doju kọ ọmọ Naijiria, leyi ti awọn si ti n fọnrere rẹ ṣaaju akoko yii. Ọrọ ti Afẹnifere sọ yii n fidi ohun ti agbẹnusọ fun ileeṣẹ ipolongo ibo Bola Tinubu, Bayọ Ọnanuga sọ pe ọrọ ara oloye Adebanjọ lo n sọkii ṣe ohun ti ẹgbẹ Afẹnifẹre n fe. Asiwaju ẹgbẹ Yoruba kan ti a mọ si Afẹnifẹre, Oloye Ayọ Adebanjọ ti ṣalaye idi ti ẹgbẹ naa ko fi fẹ ti oludije ẹgbẹ oṣelu APC, Bola Ahmed Tinubu tabi ti PDP Atiku Abubakar lẹyin fun ibo aarẹ Naijiria ti yoo waye lọdun 2023. Asiwaju ẹgbẹ Afẹnifẹre, Oloye Ayọ Adebanjọ ṣalaye nibi apero kan to ṣe pẹl’awọn akọroyin pe iṣọkan ati ilana aparo kan ko ga ju ọkan lọ pẹlu idajọ ododo lti ẹgbẹ naa duro fun lo mu ko pinnu eyi. Adebanjọ n fi apero naa fesi si ọrọ ti ileeṣẹ ipolongo idibo aarẹ fun Bola Ahmed Tinubu fi sita laipẹ yii ni ninu eyi to ti sọ ọ di mimọ pe iṣẹ ara oloye Adebanjọ lo n jẹ o ko jẹ iṣẹ ọmọ Yoruba lori Peter Obi to gbe ka ori. Oludari eto ipolongo fun ileesẹ ipolongo ibo fun Bola Tinubu, Bayọ Ọnanuga ṣalaye bu ẹnu atẹ lu bi Ayọ Adebanjọ ṣe n ṣe atilẹyin fun Peter Obi ti ẹgbẹ oṣelu Labour. Onanuga kọ ọ si oju opo Facebook rẹ pe lootọ Adebanjọ lẹtọ si fifi atilẹyin rẹ han fun oludije yoowu to ba wu u ṣugbọn iṣẹ ara rẹ lo n jẹ, ko yẹ ko wa maa lọ ifẹ ara rẹ mọ ẹgbẹ Afẹnifẹre lẹsẹ pe oun ti oun n fẹ naa ni ẹgbẹ ọhun pẹlu nfẹ. Adebanjọ to fesi si eyi ṣalaye iwa aisi irẹjẹ ni Afẹnifẹre n fẹ to fi gbe ijoko joko si ẹyin Peter Obi gẹgẹ bi oludije to fẹ ti lẹyin. O fi kun pe ilana iṣejọba apapọ tootọ ti oyinbo n pe ni Federalism ni Afẹnifẹre n fẹ. Ayọ Adebanjọ ni lootọ ọpọ awọn aṣiwaju ilẹ Yoruba lo ti kọminu lori igbesẹ naa sugbọn ti oun ti la ọrọ naa ye ti oun si ti jẹ ki wọn mọ pe ilana ẹni kan kii jẹ ki ilẹ fẹ ti Action Group ti Awolowo da silẹ laye ọjọun duro le lori lawọn ṣi n tẹlẹ.
https://www.bbc.com/yoruba/articles/c031515nkk9o
2health
Rotten Tomatoes: Ìdí tí Tòmátò ẹ̀sà kò ṣe dára fún ìlera yín; wo àwọn kókó márùn-ún yìí
Onimọ nipa fifi ounjẹ wo aisan, Olusola Malomo ti ṣalaye idi ti ko fi yẹ ki awọn eeyan to ba fẹ ra Tòmátò ni ọja maa ra ẹsa Tomato to ba ti fi ara kan isalẹ apẹrẹ. O jẹ ko di mimọ pe ko dara fun ilera eeyan rara labẹ gbogbo akoso bo ti wu ko ri. Ipo ti ipese ounjẹ fi n ja walẹ lati bii ọdun melo kan sẹyin to fi mọ jija walẹ iyi owo ati bi ìṣẹ́ ṣe n pọ sii ti mu ki ọpọlọpọ ọmọ Naijiria maa ra awọn ounjẹ to ti n bajẹ pẹlu ero ati jẹ ẹ bẹẹ bẹẹ. 'Kò sí ǹkan tó jọ tòmátò tó ní májèlé ní Nàìjíríà' Okòòwò márùn ún tí o lè bẹ̀rẹ̀ nínú ilé rẹ̀ Wo àwọn oúnjẹ márùn ún tó ń mú kí àtọ̀ ọkùnrin dára síi Iroyin bojuwo bi awọn onibara kan ṣe pinu lati bẹrẹ si maa ra Tomato to ti n bajẹ tabi fọ lara gẹgẹ bi wọn ṣe sọ ọ tori pe o dinwo ju oju eyi to ṣi n dan lara lọ ati pe yoo pọ diẹ ju u lọ. Lara awọn to n ra a ti pupọ ninu wọn jẹ awọn to n se ounjẹ ta ṣalaye pe bi eeyan ba ti fọ ọ daadaa ti eeyan si bọ ọ lori ina, ṣe ni yoo da wa ni ilera pada to si dara fun jijẹ. Ẹwẹ, onimọ nipa ounjẹ jijẹ fun ilera, Olusola Malomo sọ fun BBC Yoruba ohun to ṣe pataki fun ilera eeyan nipa ẹsa ti awọn mii yan lati maa ra yii. Ìjọba Ìpínlẹ̀ Ondo sọ̀rọ̀ lórí ìdájọ́ tó dá Sotitobire láre pé kò jí ọmọ kankan gbé Akẹ́kọ̀ọ́ márùn-ún ló wọlé lu ọmọ mí tó fi kú, kìí ṣe bọ́ọ̀lù ló gbá - Baba akẹ́kòó Dowen fèsì Ṣé lóòtọ́ ní pé ìlúmọ̀ọ́ká agbábọ́ọ̀lù ayé àtijọ́ Teslim Thunder Balogun gbá ṣọ́ọ̀tì gbígbóná fi pa "Goal keeper"? Ọmọ rẹ̀ sọ̀rọ̀
Rotten Tomatoes: Ìdí tí Tòmátò ẹ̀sà kò ṣe dára fún ìlera yín; wo àwọn kókó márùn-ún yìí Onimọ nipa fifi ounjẹ wo aisan, Olusola Malomo ti ṣalaye idi ti ko fi yẹ ki awọn eeyan to ba fẹ ra Tòmátò ni ọja maa ra ẹsa Tomato to ba ti fi ara kan isalẹ apẹrẹ. O jẹ ko di mimọ pe ko dara fun ilera eeyan rara labẹ gbogbo akoso bo ti wu ko ri. Ipo ti ipese ounjẹ fi n ja walẹ lati bii ọdun melo kan sẹyin to fi mọ jija walẹ iyi owo ati bi ìṣẹ́ ṣe n pọ sii ti mu ki ọpọlọpọ ọmọ Naijiria maa ra awọn ounjẹ to ti n bajẹ pẹlu ero ati jẹ ẹ bẹẹ bẹẹ. 'Kò sí ǹkan tó jọ tòmátò tó ní májèlé ní Nàìjíríà' Okòòwò márùn ún tí o lè bẹ̀rẹ̀ nínú ilé rẹ̀ Wo àwọn oúnjẹ márùn ún tó ń mú kí àtọ̀ ọkùnrin dára síi Iroyin bojuwo bi awọn onibara kan ṣe pinu lati bẹrẹ si maa ra Tomato to ti n bajẹ tabi fọ lara gẹgẹ bi wọn ṣe sọ ọ tori pe o dinwo ju oju eyi to ṣi n dan lara lọ ati pe yoo pọ diẹ ju u lọ. Lara awọn to n ra a ti pupọ ninu wọn jẹ awọn to n se ounjẹ ta ṣalaye pe bi eeyan ba ti fọ ọ daadaa ti eeyan si bọ ọ lori ina, ṣe ni yoo da wa ni ilera pada to si dara fun jijẹ. Ẹwẹ, onimọ nipa ounjẹ jijẹ fun ilera, Olusola Malomo sọ fun BBC Yoruba ohun to ṣe pataki fun ilera eeyan nipa ẹsa ti awọn mii yan lati maa ra yii. Ìjọba Ìpínlẹ̀ Ondo sọ̀rọ̀ lórí ìdájọ́ tó dá Sotitobire láre pé kò jí ọmọ kankan gbé Akẹ́kọ̀ọ́ márùn-ún ló wọlé lu ọmọ mí tó fi kú, kìí ṣe bọ́ọ̀lù ló gbá - Baba akẹ́kòó Dowen fèsì Ṣé lóòtọ́ ní pé ìlúmọ̀ọ́ká agbábọ́ọ̀lù ayé àtijọ́ Teslim Thunder Balogun gbá ṣọ́ọ̀tì gbígbóná fi pa "Goal keeper"? Ọmọ rẹ̀ sọ̀rọ̀
https://www.bbc.com/yoruba/59530664
2health
Nigeria Resident Doctor's Strike: Àwọn dókítà tí fagilé ìyanṣẹ́lódì ọlọ́jọ́ gbọọrọ, sùgbọ́n...
Àwọn ẹgbẹ́ dókítà tí fagilé ìyanṣẹ́lódì ọlọ́jọ́ gbọọrọ ti wọ́n gùnlẹ, sùgbgọ́n wọ́n ṣe ìlérí pé, ọjọ́rú ni àwọn yóò tó wọṣẹ́. Tí ẹ ò bá gbàgbé, àwọn dókítà bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ nínú oṣù kẹjọ lẹ́yìn èdè-àìyede tó bẹ́sílẹ̀ láàrín àwọn àti ìjọba àpapọ̀ lórí àwọn irinṣẹ́ àti ohunèlò tí kò tó láwọn ilé ìwòsàn ìjọba. Nínú àtẹ̀jáde ti wọ́n fi sita lórí àfẹnukò wọn tí akọ̀wé ẹgbẹ́ náà Expe Philips Uche fọwọ́sí lẹ́yìn ìpàdé tí àwọn aṣojú NMA àti NARD ṣe nílùú Abuja ni bi ti ẹgbẹ́ àwọn Dókíta (NMA) tí wọ́n sì gbà wọ́n ni ìmọ̀ràn láti fòpin sí ìyànsẹ́lódì. Nínú ìpàdé náà ẹgbẹ́ NMA paá ni dandan pé kí ìgbìmọ̀ tó n mójú tó mímójú tó àdéhùn ìjọba tí wọ́n fi ọwọ́ sí ni ọjọ́ kọkànlélógún oṣù kẹjọ ọdún yìí ri dájú pé ìjọba mú àdéhùn wọn ṣẹ. Bákan náà lo ni ki ìgbìmọ̀ ọ̀hún jábọ̀ padà fún àwọn alága NMA ìpińlẹ̀ kọ̀ọ̀kan tó fi mọ́ alága ti ilúi Abuja lóòrèkóòrè lórí ilọsíwájú tó bá wáyé. Gẹ́gẹ́ bi alága NARD Godiya Ishaya ṣe sọ, ẹgbẹ́ tí fagilé òyànṣẹ́lódì. Ó ní : " A ti fagilé ìyànṣẹ́lódì, à ọ sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ní aago mẹ́jọ owúrọ̀ Ọjọ́rú. A p ẹnupọ̀ láti fagilé ìyànṣẹ́lódì yìí ní ìdájí owúrọ̀ òní." "A pe ìpàdé pàjáwìrì ni ago márùn àbọ̀ ọj Aikú títí dí òwúrọ̀ òní, à jọ́ ṣe àgbéyẹ̀wò àwọn àṣeyọrí wa, a si wòó pé kí a fopin sí ìyànṣẹ́lódì tó n lọ." Ọ̀sẹ̀ mẹ́sàn gbáko ni ìyànṣẹ́lódì náà pé ní òní ọjọ́ Ajé, èyí tí ó sì tí ṣe àkọ́bá fún àwọn ilé ìwòsàn ìjọba jákèjádò Nàìjíríà, tí ọ̀pọ̀ àwọn aláìsàn sì ti fara gbá nínú rẹ.
Nigeria Resident Doctor's Strike: Àwọn dókítà tí fagilé ìyanṣẹ́lódì ọlọ́jọ́ gbọọrọ, sùgbọ́n... Àwọn ẹgbẹ́ dókítà tí fagilé ìyanṣẹ́lódì ọlọ́jọ́ gbọọrọ ti wọ́n gùnlẹ, sùgbgọ́n wọ́n ṣe ìlérí pé, ọjọ́rú ni àwọn yóò tó wọṣẹ́. Tí ẹ ò bá gbàgbé, àwọn dókítà bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ nínú oṣù kẹjọ lẹ́yìn èdè-àìyede tó bẹ́sílẹ̀ láàrín àwọn àti ìjọba àpapọ̀ lórí àwọn irinṣẹ́ àti ohunèlò tí kò tó láwọn ilé ìwòsàn ìjọba. Nínú àtẹ̀jáde ti wọ́n fi sita lórí àfẹnukò wọn tí akọ̀wé ẹgbẹ́ náà Expe Philips Uche fọwọ́sí lẹ́yìn ìpàdé tí àwọn aṣojú NMA àti NARD ṣe nílùú Abuja ni bi ti ẹgbẹ́ àwọn Dókíta (NMA) tí wọ́n sì gbà wọ́n ni ìmọ̀ràn láti fòpin sí ìyànsẹ́lódì. Nínú ìpàdé náà ẹgbẹ́ NMA paá ni dandan pé kí ìgbìmọ̀ tó n mójú tó mímójú tó àdéhùn ìjọba tí wọ́n fi ọwọ́ sí ni ọjọ́ kọkànlélógún oṣù kẹjọ ọdún yìí ri dájú pé ìjọba mú àdéhùn wọn ṣẹ. Bákan náà lo ni ki ìgbìmọ̀ ọ̀hún jábọ̀ padà fún àwọn alága NMA ìpińlẹ̀ kọ̀ọ̀kan tó fi mọ́ alága ti ilúi Abuja lóòrèkóòrè lórí ilọsíwájú tó bá wáyé. Gẹ́gẹ́ bi alága NARD Godiya Ishaya ṣe sọ, ẹgbẹ́ tí fagilé òyànṣẹ́lódì. Ó ní : " A ti fagilé ìyànṣẹ́lódì, à ọ sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ní aago mẹ́jọ owúrọ̀ Ọjọ́rú. A p ẹnupọ̀ láti fagilé ìyànṣẹ́lódì yìí ní ìdájí owúrọ̀ òní." "A pe ìpàdé pàjáwìrì ni ago márùn àbọ̀ ọj Aikú títí dí òwúrọ̀ òní, à jọ́ ṣe àgbéyẹ̀wò àwọn àṣeyọrí wa, a si wòó pé kí a fopin sí ìyànṣẹ́lódì tó n lọ." Ọ̀sẹ̀ mẹ́sàn gbáko ni ìyànṣẹ́lódì náà pé ní òní ọjọ́ Ajé, èyí tí ó sì tí ṣe àkọ́bá fún àwọn ilé ìwòsàn ìjọba jákèjádò Nàìjíríà, tí ọ̀pọ̀ àwọn aláìsàn sì ti fara gbá nínú rẹ.
https://www.bbc.com/yoruba/media-58783782
4religion
Shiloh 2020: Oyedepo ní òun kò le tòṣì láéláé! Ẹni tó bá ń bínú kàn ń bínú lásán ni
Oludasilẹ ijọ Living Faith ti ọpọ mọ si Winners, Biṣọọbu David Oyedepo tun ti sọ pe oun ko le toṣi laelae! Biṣọọbu Oyedepo sọrọ yii nigba ti o n waasu nibi akanṣe eto ọlọdọọdun ijọ Winners, Shiloh 2020 niluu Ota, ipinlẹ Ogun. Biṣọọbu Oyedepo ni majẹmu ti Ọlọrun ti la kalẹ ninu iwe mimọ ti oun n tẹle ko le jẹ ki oṣi mọ ile oun laelae. O ṣalaye pe niwọn igba ti orun ba n yọ loke ti ilẹ si n su u, majẹmu to sọ oun di ọlọrọ ko le yipada laelae. Biṣọọbu Oyedepo ni Ọlọrun sọ fun oun pe ilọrọ ninu Oluwa kii ṣe ileri, kii sii ṣe ọrọ adura ati aawẹ. Ti eeyan ko ba ko ipa tirẹ, Ọlọrun naa ko ni ṣe ohun kan.'' ''Nigba naa ni mo ke Yeeeehhh! Mo o le toṣi laelae. Ẹni to ba fẹ lọrọ ninu Oluwa ko gbọdọ fi idamẹwa ati ififunni ṣere,'' Oyedepo lo sọ bẹẹ. Ọlọrun tun sọ ohun miiran fun mi lẹyin ti mo ka iwe ti Kenneth ati Gloria Copeland lori ilọrọ ninu Oluwa tan. Oyedepo ni: ''O sọ fun mi pe bi Oun ṣe maa n ṣi ferese ọrun si awọn eeyan naa ni Oun maa ṣi ferese ọrun sori ileeṣẹ. Apẹẹrẹ iru rẹ to wa ninu Bibeli ni Abarahamu to san idamẹwaa lori gbogbo ohun to ko bọ lati oju ogun. Biṣọọbu Oyedepo ni lati igba naa ni ijọ Winners ti bẹrẹ si ni san idamẹwaa eyi ti o si n jẹ ki ferese ọrun maa tubọ ṣi sori ijọ naa sii. Ìjọ 10,000 tuntun ni a dá sílẹ̀ láì gba owó ọrẹ lọ́wọ́ ọmọ ìjọ lásìkò àrùn Coronavirus- Oyedepo Oluṣọ agutan agba ijọ Living Faith, pasitọ David Oyedepo ti ṣi aṣọ loju eegun pe bo tilẹ jẹ arun Covid-19 ba gbogbo agbaye finra lọdun 2020, ẹka ẹgbẹrun mẹwaa tuntun ni ijọ naa ṣi lai gba kọbọ lọwọ ọmọ ijọ kankan. Oyedepo lo sọ ọrọ naa lọjọ Abamẹta to jẹ aṣekagba ipade adura Shiloh, eyii to maa n waye lọdọdun. Gẹgẹ bo ṣe sọ, o ni "bo tilẹ jẹ pe arun naa n dun mọhuru mọhuru, ẹgbẹrun mẹwaa ẹka tuntun ni ijọ yii ṣi lai gba owo ọrẹ kankan, a o fi oju imu eṣu danrin." Nigba to n sọrọ ṣaaju nipa arun Covid-19, Oyedepe sọ pe oun ko gbagbọ pe Covid-19 kan wa nibi kankan . O ni "ti wọn ba bere lọwọ mi nipa Covid-19, esi mi ko ju pe, Covid-19 wa, bẹẹ ni ko si." "Ẹni to ba gbagbọ ninu Covid-19 ni arun naa yoo ran, ẹni ti ko ba gbagbọ ninu rẹ ko ni lugbadi arun naa." Lẹyin naa lo sọ siwaju si pe ọpọ eeyan lo ti ri iwosan gba lọwọ arun Covid-19 ninu ijọ oun.
Shiloh 2020: Oyedepo ní òun kò le tòṣì láéláé! Ẹni tó bá ń bínú kàn ń bínú lásán ni Oludasilẹ ijọ Living Faith ti ọpọ mọ si Winners, Biṣọọbu David Oyedepo tun ti sọ pe oun ko le toṣi laelae! Biṣọọbu Oyedepo sọrọ yii nigba ti o n waasu nibi akanṣe eto ọlọdọọdun ijọ Winners, Shiloh 2020 niluu Ota, ipinlẹ Ogun. Biṣọọbu Oyedepo ni majẹmu ti Ọlọrun ti la kalẹ ninu iwe mimọ ti oun n tẹle ko le jẹ ki oṣi mọ ile oun laelae. O ṣalaye pe niwọn igba ti orun ba n yọ loke ti ilẹ si n su u, majẹmu to sọ oun di ọlọrọ ko le yipada laelae. Biṣọọbu Oyedepo ni Ọlọrun sọ fun oun pe ilọrọ ninu Oluwa kii ṣe ileri, kii sii ṣe ọrọ adura ati aawẹ. Ti eeyan ko ba ko ipa tirẹ, Ọlọrun naa ko ni ṣe ohun kan.'' ''Nigba naa ni mo ke Yeeeehhh! Mo o le toṣi laelae. Ẹni to ba fẹ lọrọ ninu Oluwa ko gbọdọ fi idamẹwa ati ififunni ṣere,'' Oyedepo lo sọ bẹẹ. Ọlọrun tun sọ ohun miiran fun mi lẹyin ti mo ka iwe ti Kenneth ati Gloria Copeland lori ilọrọ ninu Oluwa tan. Oyedepo ni: ''O sọ fun mi pe bi Oun ṣe maa n ṣi ferese ọrun si awọn eeyan naa ni Oun maa ṣi ferese ọrun sori ileeṣẹ. Apẹẹrẹ iru rẹ to wa ninu Bibeli ni Abarahamu to san idamẹwaa lori gbogbo ohun to ko bọ lati oju ogun. Biṣọọbu Oyedepo ni lati igba naa ni ijọ Winners ti bẹrẹ si ni san idamẹwaa eyi ti o si n jẹ ki ferese ọrun maa tubọ ṣi sori ijọ naa sii. Ìjọ 10,000 tuntun ni a dá sílẹ̀ láì gba owó ọrẹ lọ́wọ́ ọmọ ìjọ lásìkò àrùn Coronavirus- Oyedepo Oluṣọ agutan agba ijọ Living Faith, pasitọ David Oyedepo ti ṣi aṣọ loju eegun pe bo tilẹ jẹ arun Covid-19 ba gbogbo agbaye finra lọdun 2020, ẹka ẹgbẹrun mẹwaa tuntun ni ijọ naa ṣi lai gba kọbọ lọwọ ọmọ ijọ kankan. Oyedepo lo sọ ọrọ naa lọjọ Abamẹta to jẹ aṣekagba ipade adura Shiloh, eyii to maa n waye lọdọdun. Gẹgẹ bo ṣe sọ, o ni "bo tilẹ jẹ pe arun naa n dun mọhuru mọhuru, ẹgbẹrun mẹwaa ẹka tuntun ni ijọ yii ṣi lai gba owo ọrẹ kankan, a o fi oju imu eṣu danrin." Nigba to n sọrọ ṣaaju nipa arun Covid-19, Oyedepe sọ pe oun ko gbagbọ pe Covid-19 kan wa nibi kankan . O ni "ti wọn ba bere lọwọ mi nipa Covid-19, esi mi ko ju pe, Covid-19 wa, bẹẹ ni ko si." "Ẹni to ba gbagbọ ninu Covid-19 ni arun naa yoo ran, ẹni ti ko ba gbagbọ ninu rẹ ko ni lugbadi arun naa." Lẹyin naa lo sọ siwaju si pe ọpọ eeyan lo ti ri iwosan gba lọwọ arun Covid-19 ninu ijọ oun.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-55289586
1entertainment
Davido: Àpètàn orukọ̀ ọmọ tuntun náà ní David Adedeji Ifeanyi Adeleke
Ayọ abara tintin. David Adeleke, ti gbogbo eeyan mọ si Davido ti kede pe, Oluwa ti fi ọmọkunrin kan lanti-lanti da oun ati aya oun, Chioma, lọla. Owurọ ọjọ Aiku ni Davido kede bẹẹ loju opo Instagram rẹ, to si ni Ọmọọba ti de, ile iwosan kan nilu London si ni Chioma bimọ naa si. O wa pe orukọ ọmọ ọhun ni David Adedeji Ifeanyi Adeleke Jnr pẹlu afikun pe inu oun dun pupọ si iroyin ayọ naa. Davido ni "Mo nifẹ aya mi pupọ, koda obinrin alagbara ni", to si jẹ pe nigba ti awọn olorin to jẹ akẹẹgbẹ Davido n lọ sibi ami ẹyẹ fawọn olorin, Headies Award, yara igbẹbi ni Davido wa, to n rawọ rasẹ si Ọlọrun pe, ko sọ aya oun kalẹ layọ. Chioma, afẹsọna Davido lo ti kọkọ kede loju opo Twitter rẹ nirọlẹ ana pe oun wa nile igbẹbi, ti ọpọ eeyan si ti n se adura fun pe yoo bi wẹrẹ. Koda, oun naa tun ti kede loju opo Instagram rẹ pe Oluwa ti sọ oun layọ. Wayi o, awọn ọmọ Naijiria ti n se jaginni yodo pẹlu ọba orin naa fun ayọ ọmọkunrin jojolo to baa lalejo naa, bi o tilẹ jẹ pe obinrin meji ọtọọtọ ti bi ọmọbinrin meji fun tẹlẹ.
Davido: Àpètàn orukọ̀ ọmọ tuntun náà ní David Adedeji Ifeanyi Adeleke Ayọ abara tintin. David Adeleke, ti gbogbo eeyan mọ si Davido ti kede pe, Oluwa ti fi ọmọkunrin kan lanti-lanti da oun ati aya oun, Chioma, lọla. Owurọ ọjọ Aiku ni Davido kede bẹẹ loju opo Instagram rẹ, to si ni Ọmọọba ti de, ile iwosan kan nilu London si ni Chioma bimọ naa si. O wa pe orukọ ọmọ ọhun ni David Adedeji Ifeanyi Adeleke Jnr pẹlu afikun pe inu oun dun pupọ si iroyin ayọ naa. Davido ni "Mo nifẹ aya mi pupọ, koda obinrin alagbara ni", to si jẹ pe nigba ti awọn olorin to jẹ akẹẹgbẹ Davido n lọ sibi ami ẹyẹ fawọn olorin, Headies Award, yara igbẹbi ni Davido wa, to n rawọ rasẹ si Ọlọrun pe, ko sọ aya oun kalẹ layọ. Chioma, afẹsọna Davido lo ti kọkọ kede loju opo Twitter rẹ nirọlẹ ana pe oun wa nile igbẹbi, ti ọpọ eeyan si ti n se adura fun pe yoo bi wẹrẹ. Koda, oun naa tun ti kede loju opo Instagram rẹ pe Oluwa ti sọ oun layọ. Wayi o, awọn ọmọ Naijiria ti n se jaginni yodo pẹlu ọba orin naa fun ayọ ọmọkunrin jojolo to baa lalejo naa, bi o tilẹ jẹ pe obinrin meji ọtọọtọ ti bi ọmọbinrin meji fun tẹlẹ.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-50114244
5sports
Egúngún Arsenal tó kọ́kọ́ jó, ìran góòlù méjì ló padà wò lọ́wọ́ Chelsea
Ọrọ naa ṣe awọn ololufẹ ẹgbẹ Arsenal bi ere ṣugbọn nigba ti adari ere yoo fọn fere, wọn ti fidirẹmi lọwọ Chelsea. Goolu meji si ookan ni ikọ Frank Lampard fi tẹyin gberu Arsenal ni agboole wọn tii ṣe Emirates. Pẹlu esi yi, Chelsea ti ni ami marundinlogoji ti wọn si wa ni ipo Kẹrin lori afara liigi Premiership.Arsenal wa ni ipo kejila Pierre Emerick Aubameyang lo kọkọ jẹ goolu fun Arsenal ni abala kini ipade naa. Ninu ẹgbẹ mejeeji,Arsenal lo pitu gidi gaan ni abala kini ti awọn ọmọ Frank Lampard ko si rojutu ara wọn . Ninu abala keji ni nnkan ti yi pada ti Chelsea si fi ina goolu meji jo Arsenal lara mọle. Aṣiṣe lati ọwọ aṣọle Arsenal lo ṣokunfa goolu akọkọ ti Chelsea jẹ lati ọwọ Jorginho. Tammy Abraham tojẹ atamatase Chelsea ti o ni goolu julọ ni saa bọọlu yi lo pari ijo pẹlu goolu ẹlẹkeeji ni iṣeju mẹ́tàdínláàdọ́rùn ún. Bayi,ami mọkanla ni Chelsea yoo fi ṣagba Arsenal wọ ọdun 2020 lori afara liigi Premiership.
Egúngún Arsenal tó kọ́kọ́ jó, ìran góòlù méjì ló padà wò lọ́wọ́ Chelsea Ọrọ naa ṣe awọn ololufẹ ẹgbẹ Arsenal bi ere ṣugbọn nigba ti adari ere yoo fọn fere, wọn ti fidirẹmi lọwọ Chelsea. Goolu meji si ookan ni ikọ Frank Lampard fi tẹyin gberu Arsenal ni agboole wọn tii ṣe Emirates. Pẹlu esi yi, Chelsea ti ni ami marundinlogoji ti wọn si wa ni ipo Kẹrin lori afara liigi Premiership.Arsenal wa ni ipo kejila Pierre Emerick Aubameyang lo kọkọ jẹ goolu fun Arsenal ni abala kini ipade naa. Ninu ẹgbẹ mejeeji,Arsenal lo pitu gidi gaan ni abala kini ti awọn ọmọ Frank Lampard ko si rojutu ara wọn . Ninu abala keji ni nnkan ti yi pada ti Chelsea si fi ina goolu meji jo Arsenal lara mọle. Aṣiṣe lati ọwọ aṣọle Arsenal lo ṣokunfa goolu akọkọ ti Chelsea jẹ lati ọwọ Jorginho. Tammy Abraham tojẹ atamatase Chelsea ti o ni goolu julọ ni saa bọọlu yi lo pari ijo pẹlu goolu ẹlẹkeeji ni iṣeju mẹ́tàdínláàdọ́rùn ún. Bayi,ami mọkanla ni Chelsea yoo fi ṣagba Arsenal wọ ọdun 2020 lori afara liigi Premiership.
https://www.bbc.com/yoruba/ere-idaraya-50941414
1entertainment
Nollywood: Saheed Balogun àti Shina Peters lọ sí ilé Ààrẹ Buhari lÀbuja, wọ́n gba àmì ẹ̀yẹ
Ki ni agba oṣere, Saheed Balogun ati agba akọrin Sir Shina Peters lọ ṣe ni ileeṣẹ aarẹ orilẹede Naijiria nilu Abuja, nibi ti aworan wọn ati awọn atawọn eekan elere tiata miran ti jẹyọ pẹlu amugbalẹgbẹ fun aarẹ lori ọrọ iroyin ati ipolongo, Ọgbẹni Fẹmi Adesina. Agba oṣere ati akọrin meji naa wa lara ikọ ẹgbẹ kan ti wọn pe ni ' Ambassadors of Voice for Change' to ṣe abẹwo si Ọgbẹni Fẹmi Adesina nibi ti wọn ti fi ami ẹyẹ da a lọla nilu Abuja. Awọn agba osere bii Mr. Ibu, Onyekweli Harry B, Gentle Jack, Ben Kure atawọn eekan miran latiẹya gbogbo lorilẹede Naijiria wa lara awọn ti wọn wa ninu ẹgbẹ naa wa nibi abẹwo naa ti Ahmed Bala ko sodi lọ. Amugbalẹgbẹ fun Aarẹ Buhari lori ọrọ iroyin ati ipolongo naa wa kan sara sawọn agba amuludun ọhun fun ipa ti wọn n ko lati rii pe iṣọkan ati alaafia di igi alọye lorilẹede Naijiria. Ọgbẹni Adeṣina fi kun un pe awọn olulaja atawọn to n lepa alaafia lorilẹede Naijiria nilo bayii, kii ṣe awọn ọbayejẹ ti yoo pagidina idagbasoko ati iṣọkan Naijiria. Bakan naa lo tun ṣalaye pe ijọba Buhari yoo tubọ maa ṣe atilẹyin to ba yẹ fun awọn ọmọ Naijiria to n ṣiṣẹ takuntakun lati mu alaafia gbooro sii.
Nollywood: Saheed Balogun àti Shina Peters lọ sí ilé Ààrẹ Buhari lÀbuja, wọ́n gba àmì ẹ̀yẹ Ki ni agba oṣere, Saheed Balogun ati agba akọrin Sir Shina Peters lọ ṣe ni ileeṣẹ aarẹ orilẹede Naijiria nilu Abuja, nibi ti aworan wọn ati awọn atawọn eekan elere tiata miran ti jẹyọ pẹlu amugbalẹgbẹ fun aarẹ lori ọrọ iroyin ati ipolongo, Ọgbẹni Fẹmi Adesina. Agba oṣere ati akọrin meji naa wa lara ikọ ẹgbẹ kan ti wọn pe ni ' Ambassadors of Voice for Change' to ṣe abẹwo si Ọgbẹni Fẹmi Adesina nibi ti wọn ti fi ami ẹyẹ da a lọla nilu Abuja. Awọn agba osere bii Mr. Ibu, Onyekweli Harry B, Gentle Jack, Ben Kure atawọn eekan miran latiẹya gbogbo lorilẹede Naijiria wa lara awọn ti wọn wa ninu ẹgbẹ naa wa nibi abẹwo naa ti Ahmed Bala ko sodi lọ. Amugbalẹgbẹ fun Aarẹ Buhari lori ọrọ iroyin ati ipolongo naa wa kan sara sawọn agba amuludun ọhun fun ipa ti wọn n ko lati rii pe iṣọkan ati alaafia di igi alọye lorilẹede Naijiria. Ọgbẹni Adeṣina fi kun un pe awọn olulaja atawọn to n lepa alaafia lorilẹede Naijiria nilo bayii, kii ṣe awọn ọbayejẹ ti yoo pagidina idagbasoko ati iṣọkan Naijiria. Bakan naa lo tun ṣalaye pe ijọba Buhari yoo tubọ maa ṣe atilẹyin to ba yẹ fun awọn ọmọ Naijiria to n ṣiṣẹ takuntakun lati mu alaafia gbooro sii.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-60006854
5sports
Anthony Joshua: Ajagba akẹ̀ṣẹ́ ọmọ Nàìjíríà lóun ṣetán láti f'ẹ̀ṣẹ́ dín dòdò ìyà fún AJ
Yoruba bọ, wọn ni o di oni karangida, adiẹ n jẹ ifun ara wọn. Bayii lọrọ ri abẹṣẹ ku bi ojo ọmọ Naijiria, Efe Ajagba to ni oun ṣetan lati fi ẹṣẹ din dodo iya fun ogbontarigi akẹṣẹ Anthony Joshua. Ilẹ Amẹrika ni Ajagba to ti ṣoju orilẹede Naijiria ri ninu idije ''Olympics'' fi ṣe ibugbe bayii lẹyin to ti wa niluu Eko fun ọpọlọpọ ọdun. Ọrọ naa da bi ẹni to maa ku pade ẹni to maa pa, nirori Joshua gan an funra rẹ ti sọ tẹlẹ pe o wu oun lati fija pẹta pẹlu akẹṣẹ to jẹ ọmọbibi ilẹ Afirika bi t'oun naa. Ajagba tiẹ ti bẹrẹ si ni sọ ọna ti o fi le fẹyin AJ gbalẹ ti wọn ba koju ara wọn. Ajagba sọ fawọn akọroyin pe ko ba wu oun ki Joshua gba lati ba oun ja lorilẹede Naijiria tawọn mejeeji ti wa. Abẹsẹ ku bi ojo ọmọ Naijiria ṣalaye pe lootọọ ni pe Joshua lagbara, amọ ọgban inu loun maa fi ṣẹ AJ leegun ẹyin tawọn koju ara awọn. O ni ati oun ati Joshua lawọn jọ lagbara ṣugbọn o ni ọgbọn ju ọgbọn lọ. Ajagba ni otitọ ni pe Joshua ti gba ami ẹyẹ goolu ninu idije ''Olympics'' ri, oun si tun ni abẹṣẹ ku bi ojo to lami lahaka taye ti aye n fẹ lọwọ bayii. Oun oun naa gboṣuba fun AJ fun awọn aṣeyọri rẹ lagbo ẹṣẹ kikan, amọ oun mọ awọn ibi ti Joshua ku si ninu ẹṣẹ kikan. Joshua gba awọn igbanu rẹ mẹtẹẹta, IBF, WBA ati WBO pada lọwọ Andy Ruiz Jr pada lẹyin ti Ruiz ti kọkọ lu u bi aṣọ ofi nigba ti wọn kọkọ koju ara wọn. Joshua naa fẹ ṣe bi agbọjẹ ninu ẹṣẹ kikan, oloogbe Muhammad Ali to ba George Foreman ja ni Zaire lọdun 1974. Amọ Ajagba ti kepe Joshua pe ko jẹ ki awọn ṣe ere ọwọ papọ ni Naijiria, o ni ti o ba ti ya eegun Joshua, o ti ya ọlọrẹ t'oun naa.
Anthony Joshua: Ajagba akẹ̀ṣẹ́ ọmọ Nàìjíríà lóun ṣetán láti f'ẹ̀ṣẹ́ dín dòdò ìyà fún AJ Yoruba bọ, wọn ni o di oni karangida, adiẹ n jẹ ifun ara wọn. Bayii lọrọ ri abẹṣẹ ku bi ojo ọmọ Naijiria, Efe Ajagba to ni oun ṣetan lati fi ẹṣẹ din dodo iya fun ogbontarigi akẹṣẹ Anthony Joshua. Ilẹ Amẹrika ni Ajagba to ti ṣoju orilẹede Naijiria ri ninu idije ''Olympics'' fi ṣe ibugbe bayii lẹyin to ti wa niluu Eko fun ọpọlọpọ ọdun. Ọrọ naa da bi ẹni to maa ku pade ẹni to maa pa, nirori Joshua gan an funra rẹ ti sọ tẹlẹ pe o wu oun lati fija pẹta pẹlu akẹṣẹ to jẹ ọmọbibi ilẹ Afirika bi t'oun naa. Ajagba tiẹ ti bẹrẹ si ni sọ ọna ti o fi le fẹyin AJ gbalẹ ti wọn ba koju ara wọn. Ajagba sọ fawọn akọroyin pe ko ba wu oun ki Joshua gba lati ba oun ja lorilẹede Naijiria tawọn mejeeji ti wa. Abẹsẹ ku bi ojo ọmọ Naijiria ṣalaye pe lootọọ ni pe Joshua lagbara, amọ ọgban inu loun maa fi ṣẹ AJ leegun ẹyin tawọn koju ara awọn. O ni ati oun ati Joshua lawọn jọ lagbara ṣugbọn o ni ọgbọn ju ọgbọn lọ. Ajagba ni otitọ ni pe Joshua ti gba ami ẹyẹ goolu ninu idije ''Olympics'' ri, oun si tun ni abẹṣẹ ku bi ojo to lami lahaka taye ti aye n fẹ lọwọ bayii. Oun oun naa gboṣuba fun AJ fun awọn aṣeyọri rẹ lagbo ẹṣẹ kikan, amọ oun mọ awọn ibi ti Joshua ku si ninu ẹṣẹ kikan. Joshua gba awọn igbanu rẹ mẹtẹẹta, IBF, WBA ati WBO pada lọwọ Andy Ruiz Jr pada lẹyin ti Ruiz ti kọkọ lu u bi aṣọ ofi nigba ti wọn kọkọ koju ara wọn. Joshua naa fẹ ṣe bi agbọjẹ ninu ẹṣẹ kikan, oloogbe Muhammad Ali to ba George Foreman ja ni Zaire lọdun 1974. Amọ Ajagba ti kepe Joshua pe ko jẹ ki awọn ṣe ere ọwọ papọ ni Naijiria, o ni ti o ba ti ya eegun Joshua, o ti ya ọlọrẹ t'oun naa.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-54009604
3politics
2023 Presidency: Iṣẹ́ Ọlọ́run tí mo gbé dáni kọjá ipò Ààrẹ Nàìjíríà – Bíṣọ̀ọ̀bù David Oyedepo
Bí oníwá àti ẹlẹ́yìn ṣe ti ń kéde láti fi èròńgbà àti ìpinu wọn hàn láti díje sípò Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, adarí ìjọ Living Faith Church Worldwide tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ mọ̀ sí Winners Chapel, Bíṣọ̀ọ̀bù David Oyedepo ní gbígbégbá òṣèlú fún òun ní àsìkò yìí dàbí kí ènìyàn máa padà sẹ́yìn. Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ níbi àpérò kan, Oyedepo ní ó ti jù fún òun láti gbégbá tàbí máa díje du ipò Ààrẹ fún òun lásìkò yìí. Bákan náà ló rọ àwọn ọmọ ìjọ rẹ̀ láti ní ìfarajìn sí sínsin Ọlọ́run bó ṣe tọ́ kí Ọlọ́run le máa tó wọn ní gbogbo ìgbésí ayé wọn. Oyedepo ní òun ní ìgbàgbọ́ nínú orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ni òun ṣì fi wà ní orílẹ̀ èdè yìí títí di àsìkò yìí tí òun sì ń fi gbogbo ìgbà àti tinútinú òun gbàdúrà pé kí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà dára ju bó ṣe wà yìí lọ. Ó fi kun pé bí àwọn kan bá ń pe òun láti wá ṣe Ààrẹ Nàìjíríà túnmọ̀ sí wí pé òun ń padà sẹ́yìn ni nítorí òun tí Ọlọ́run pe òun fún jẹ́ láti sin gbogbo àgbáyé. Ó tẹ̀síwájú wí pé láti ọdún 1984 ni òun ti rí ìpè Ọlọ́run láti sìn-ín . "Kódà èṣù gan náà ms wí pé kò sí wí pé kò sí bí ènìyàn ṣe máa jókòó ti Ọlọ́run tó ma wá jogun òfo." "Láti ìgbà tí mo ti wà ní ọmọ ọdún mọ́kàndínlógún ni mo ti máa ń gbàdúrà sí Ọlọ́run pé mi ò fẹ́ fi ìlú kan sílẹ̀ bí mo ṣe ba." Ó ní iṣẹ́ Ọlọ́run kò sú òun láti ọdún 1976 tí òun ti bá Ọlọ́run pàdé.
2023 Presidency: Iṣẹ́ Ọlọ́run tí mo gbé dáni kọjá ipò Ààrẹ Nàìjíríà – Bíṣọ̀ọ̀bù David Oyedepo Bí oníwá àti ẹlẹ́yìn ṣe ti ń kéde láti fi èròńgbà àti ìpinu wọn hàn láti díje sípò Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, adarí ìjọ Living Faith Church Worldwide tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ mọ̀ sí Winners Chapel, Bíṣọ̀ọ̀bù David Oyedepo ní gbígbégbá òṣèlú fún òun ní àsìkò yìí dàbí kí ènìyàn máa padà sẹ́yìn. Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ níbi àpérò kan, Oyedepo ní ó ti jù fún òun láti gbégbá tàbí máa díje du ipò Ààrẹ fún òun lásìkò yìí. Bákan náà ló rọ àwọn ọmọ ìjọ rẹ̀ láti ní ìfarajìn sí sínsin Ọlọ́run bó ṣe tọ́ kí Ọlọ́run le máa tó wọn ní gbogbo ìgbésí ayé wọn. Oyedepo ní òun ní ìgbàgbọ́ nínú orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ni òun ṣì fi wà ní orílẹ̀ èdè yìí títí di àsìkò yìí tí òun sì ń fi gbogbo ìgbà àti tinútinú òun gbàdúrà pé kí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà dára ju bó ṣe wà yìí lọ. Ó fi kun pé bí àwọn kan bá ń pe òun láti wá ṣe Ààrẹ Nàìjíríà túnmọ̀ sí wí pé òun ń padà sẹ́yìn ni nítorí òun tí Ọlọ́run pe òun fún jẹ́ láti sin gbogbo àgbáyé. Ó tẹ̀síwájú wí pé láti ọdún 1984 ni òun ti rí ìpè Ọlọ́run láti sìn-ín . "Kódà èṣù gan náà ms wí pé kò sí wí pé kò sí bí ènìyàn ṣe máa jókòó ti Ọlọ́run tó ma wá jogun òfo." "Láti ìgbà tí mo ti wà ní ọmọ ọdún mọ́kàndínlógún ni mo ti máa ń gbàdúrà sí Ọlọ́run pé mi ò fẹ́ fi ìlú kan sílẹ̀ bí mo ṣe ba." Ó ní iṣẹ́ Ọlọ́run kò sú òun láti ọdún 1976 tí òun ti bá Ọlọ́run pàdé.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-61372664
3politics
Makinde vs Adelabu: Makinde ní ìjọba Ọyọ yàtọ̀ sí ti Ọṣun àbí Ekiti tí APC lé dànù
Ẹsẹ ko gba ero nile ijọba to wa nilu Ibadan loni nigba ti ọpọ ero wa se abẹwo awa lẹyin rẹ si gomina Seyi Makinde lati safihan ifẹ ti wọn ni si. Nigba to n gbalejo awọn ọgọọrọ eeyan naa, Gomina Seyi Makinde ni se ni ẹgbẹ oselu APC dabi afomọ ti ko ni gbongbo, to si n wa gbongbo ti yoo dirọ mọ pẹlu asẹ ile ẹjọ. O fikun pe ohun to n waye ni ipinlẹ Ọyọ ko lee dabi awọn isẹlẹ to ti waye sẹyin nipinlẹ Ọsun ati Ekiti nibi ti idajọ ile ẹjọ ti le ijọba to wa lori aleefa kuro.
Makinde vs Adelabu: Makinde ní ìjọba Ọyọ yàtọ̀ sí ti Ọṣun àbí Ekiti tí APC lé dànù Ẹsẹ ko gba ero nile ijọba to wa nilu Ibadan loni nigba ti ọpọ ero wa se abẹwo awa lẹyin rẹ si gomina Seyi Makinde lati safihan ifẹ ti wọn ni si. Nigba to n gbalejo awọn ọgọọrọ eeyan naa, Gomina Seyi Makinde ni se ni ẹgbẹ oselu APC dabi afomọ ti ko ni gbongbo, to si n wa gbongbo ti yoo dirọ mọ pẹlu asẹ ile ẹjọ. O fikun pe ohun to n waye ni ipinlẹ Ọyọ ko lee dabi awọn isẹlẹ to ti waye sẹyin nipinlẹ Ọsun ati Ekiti nibi ti idajọ ile ẹjọ ti le ijọba to wa lori aleefa kuro.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-50399017
3politics
Nigeria population: Buhari tako ọmọ bẹẹrẹ òṣì bẹẹrẹ ní Nàìjíríà, ó ṣàgbékalẹ̀ ètò láti dẹ́kun rẹ̀
Aarẹ Muhammadu Buhari ti ṣe agbekalẹ eto ti yoo ṣe adinku ọmọ bẹẹrẹ oṣi bẹẹrẹ lorilẹede Naijiria. Buhari to ṣe agbekalẹ eto naa niluu Abuja sọ pe o ṣe pataki bayii lati mu ifeto sọmọ bibi lọkunkundun. Buhari tun ṣe agbekalẹ eto mii ti yoo ṣe iranwọ lori ati dẹkun bi awọn eeyan ṣe n pọ sii ni Naijiria. Buhari ṣe agbekalẹ eto ifeto sọmọ bibi Aarẹ Buhari ṣalaye pe ohun to bi eto ifeto sọmọ bibi wa ni lati mu ibayegbadun ba awọn ọmọ Naijiria. Buhari ni eyi wa lara awọn eto ijọba ẹgbẹ oṣelu APC to wa lode bayii. Eto yii yoo ṣe iranwọ lori bi adinku yoo ṣe ba bi ọpọ eeyan ṣe n bi ọmọ silẹ lọpọ yanturu. Ara awọn ọna ti ijọba fẹ gba lati ṣe eto ọhun ni nipa ilanilọyẹ lori ifeto sọmọ bibi. Aarẹ Buhari gbagbọ pe eto yii yoo ran ọpọ eeyan lọwọ lati fi alafao si aarin awọn ọmọ wọn. Buhari kọminu lori bi Naijiria ṣe pọ julọ l'Afrika Aarẹ Buhari ni orilẹede naijiria lo pọ julọ nilẹ Afirika nigba to tun jẹ orilẹede to wa ni ipo keje lagbaye. Buhari ni Naijiria wa lara awọn orilẹede diẹ lagbaaye to ni ọdọ julọ. Aarẹ ni ida mejilelaadọrin ninu ọgọrun awọn ọdọ yii ni ọjọ ori wọn ko to ọgbọn ọdun. Bakan naa ni Buhari sọ pe idaji awọn obinrin ninu awọn ọdọ yii lo wa ni asiko ti wọn ṣe abiamọ tori ọjọ ori bẹrẹ lati ọdun mẹẹdogun si ọdun mọkadinlaadọta. Ọna abayọ si ọmọ bẹẹrẹ oṣi bẹẹrẹ Buhari ni ijọba ko ni dẹkun lilo eto ẹkọ to peye lati maa la awọn eeyan lọyẹ. Aarẹ ni eto ẹkọ yoo ṣe iranwọ papaa julọ fawọn obinrin to ba jẹ ọmọde tori awọn ni wọn le gboyun nigba kugba. Buhari tun sọ pe eto ikaniyan to n bọ yoo tun ṣe iranwọ lati mọ ọna lati mu adinku ba ọmọ bẹẹrẹ oṣi bẹẹrẹ. Ni bayii, akọsilẹ fihan pe eeyan to wa ni Naijiria le ni ẹgbẹrun lọna igba eleyii yoo si tun pọ sii lọjọ iwaju.
Nigeria population: Buhari tako ọmọ bẹẹrẹ òṣì bẹẹrẹ ní Nàìjíríà, ó ṣàgbékalẹ̀ ètò láti dẹ́kun rẹ̀ Aarẹ Muhammadu Buhari ti ṣe agbekalẹ eto ti yoo ṣe adinku ọmọ bẹẹrẹ oṣi bẹẹrẹ lorilẹede Naijiria. Buhari to ṣe agbekalẹ eto naa niluu Abuja sọ pe o ṣe pataki bayii lati mu ifeto sọmọ bibi lọkunkundun. Buhari tun ṣe agbekalẹ eto mii ti yoo ṣe iranwọ lori ati dẹkun bi awọn eeyan ṣe n pọ sii ni Naijiria. Buhari ṣe agbekalẹ eto ifeto sọmọ bibi Aarẹ Buhari ṣalaye pe ohun to bi eto ifeto sọmọ bibi wa ni lati mu ibayegbadun ba awọn ọmọ Naijiria. Buhari ni eyi wa lara awọn eto ijọba ẹgbẹ oṣelu APC to wa lode bayii. Eto yii yoo ṣe iranwọ lori bi adinku yoo ṣe ba bi ọpọ eeyan ṣe n bi ọmọ silẹ lọpọ yanturu. Ara awọn ọna ti ijọba fẹ gba lati ṣe eto ọhun ni nipa ilanilọyẹ lori ifeto sọmọ bibi. Aarẹ Buhari gbagbọ pe eto yii yoo ran ọpọ eeyan lọwọ lati fi alafao si aarin awọn ọmọ wọn. Buhari kọminu lori bi Naijiria ṣe pọ julọ l'Afrika Aarẹ Buhari ni orilẹede naijiria lo pọ julọ nilẹ Afirika nigba to tun jẹ orilẹede to wa ni ipo keje lagbaye. Buhari ni Naijiria wa lara awọn orilẹede diẹ lagbaaye to ni ọdọ julọ. Aarẹ ni ida mejilelaadọrin ninu ọgọrun awọn ọdọ yii ni ọjọ ori wọn ko to ọgbọn ọdun. Bakan naa ni Buhari sọ pe idaji awọn obinrin ninu awọn ọdọ yii lo wa ni asiko ti wọn ṣe abiamọ tori ọjọ ori bẹrẹ lati ọdun mẹẹdogun si ọdun mọkadinlaadọta. Ọna abayọ si ọmọ bẹẹrẹ oṣi bẹẹrẹ Buhari ni ijọba ko ni dẹkun lilo eto ẹkọ to peye lati maa la awọn eeyan lọyẹ. Aarẹ ni eto ẹkọ yoo ṣe iranwọ papaa julọ fawọn obinrin to ba jẹ ọmọde tori awọn ni wọn le gboyun nigba kugba. Buhari tun sọ pe eto ikaniyan to n bọ yoo tun ṣe iranwọ lati mọ ọna lati mu adinku ba ọmọ bẹẹrẹ oṣi bẹẹrẹ. Ni bayii, akọsilẹ fihan pe eeyan to wa ni Naijiria le ni ẹgbẹrun lọna igba eleyii yoo si tun pọ sii lọjọ iwaju.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-60226802
2health
Pneumonia: Dókítà ní kòkòrò àìfojúrí ló ń fàá òtútù àyà
Ọpọ asọdun lo maa n waye nipa aisan kan ta n pe ni otutu aya eyi ti oloyinbo n pe ni Pneumonia. Koda, aisan yii wọpọ ni Naijiria, paapa laarin awọn ọmọde, ti ajọ Unicef si ti kede pe orilẹede Naijiria wa lara awọn ti aisan naa ti wọpọ lagbaye. Nigba to n ba BBC Yoruba sọrọ, Onisegun oyinbo kan, Dokita Afeez Oladele ni aisan otutu aya ko ni ohunkohun se pẹlu otutu rara nitori eeyan lee sun si ori ilẹ lasan tabi si aya si ẹrọ amuletutu lai wọ asọ, ti onitọun ko si ni ni otutu aya rara. O ni awọn kokoro kan ti a ko lee fi oju ri lo n fa aisan naa, ti a si lee ko awọn kokoro kekeke naa latinu afẹfẹ buruku, eefin, eedu, tabi ka lo ife ati ifọyin ẹni to ba ni aisan naa. O wa gba awọn obi nimọran lati maa tete gbe awọn ọmọde ti wọn ba kẹẹfin pe o n hu ikọ lọ sile iwosan fun itọju, ki aisan naa to bọwọ sori.
Pneumonia: Dókítà ní kòkòrò àìfojúrí ló ń fàá òtútù àyà Ọpọ asọdun lo maa n waye nipa aisan kan ta n pe ni otutu aya eyi ti oloyinbo n pe ni Pneumonia. Koda, aisan yii wọpọ ni Naijiria, paapa laarin awọn ọmọde, ti ajọ Unicef si ti kede pe orilẹede Naijiria wa lara awọn ti aisan naa ti wọpọ lagbaye. Nigba to n ba BBC Yoruba sọrọ, Onisegun oyinbo kan, Dokita Afeez Oladele ni aisan otutu aya ko ni ohunkohun se pẹlu otutu rara nitori eeyan lee sun si ori ilẹ lasan tabi si aya si ẹrọ amuletutu lai wọ asọ, ti onitọun ko si ni ni otutu aya rara. O ni awọn kokoro kan ti a ko lee fi oju ri lo n fa aisan naa, ti a si lee ko awọn kokoro kekeke naa latinu afẹfẹ buruku, eefin, eedu, tabi ka lo ife ati ifọyin ẹni to ba ni aisan naa. O wa gba awọn obi nimọran lati maa tete gbe awọn ọmọde ti wọn ba kẹẹfin pe o n hu ikọ lọ sile iwosan fun itọju, ki aisan naa to bọwọ sori.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-50509486
1entertainment
Yomi Fabiyi Oko Iyabo: Ẹgbẹ́ TAMPAN ti dá Yomi Fabiyi dúró lẹ́yìn tó gbé fíímù Oko Iyabo jáde
Saaju la ti mu iroyin wa fun yin pe apapọ ẹgbẹ awọn oṣere tiata ni Naijiria, TAMPAN ti fofin de Yomi Fabiyi pe ko lọ rọọkun nile na. Ninu atẹjade ti ẹgbẹ naa fi sita lọjọ Ẹti lo ti kede pe igbesẹ naa waye nitori iwa abuku ati eyi ti ko ba oju mu gẹgẹ bi oṣere ti Fabiyi hu nipa fiimu Ọkọ Iyabọ to gbe jade laipẹ yii. Fiimu naa to gbe jade ni ọjọ Aiku to kọja da lori ọrọ ẹsun ifipabanilopọ ti wọn fi kan osẹre miran, Baba Ijesha. TAMPAN sọ pe igbesẹ naa waye lẹyin ti oun gbọ awijare Yomi Fabiyi to jẹ olukọtan, olootu ati oludari fiimu naa, ati oludari keji, Ọgbẹni Dele Matti. "A ri pe wọn jẹbi hihu iwa ti ko bojumu fun akọṣẹmọṣẹ oni tiata. Awọn alaṣẹ TAMPAN sọ pe botilẹ jẹ pe Ọgbẹni Fabiyi taku pe ẹtọ oun gẹgẹ bi eniyan, ni lati gbe fiimu jade, eyi ti yoo sọ bi nakn ṣe ri gan-an lori iṣẹlẹ ọrọ Baba Ijesha, wọn ni alajọṣiṣẹpọ rẹ gba pe oun jẹbi, to si kabamọ ipa to ko ninu ṣiṣe fiimu naa. Ninu atẹjade ti ẹgbẹ naa fi si ori Instagram rẹ ni ikede naa ti jade. Awọn abajade iwadii ati idajọ ẹgbẹ TAMPAN nipa Yomi Fabiyi: Ọgbẹni Yomi Fabiyi mọọmọ ṣe fiimu naa lai bọwọ fun ilana to de fiimu ṣiṣe, eyi to tumọ si pe o sẹ isẹ naa pẹlu erongba lati da wahala silẹ laarin ilu. Ti iṣẹ naa (fiimu) kii ba ti i ṣe ti ile Sinima, ẹnikẹni ko ni ẹtọ lati lo orukọ eeyan ti iṣẹlẹ ṣẹlẹ si ninu fiimu. "Nitori naa, iwa aibikita ni bi Fabiyi ṣe lo orukọ, ati awọn iṣẹlẹ to waye loju aye, lai gba aṣẹ lọwọ awọn ti ọrọ kan. Ìtàn, agbekalẹ itan, ohùn, ọrọ, akori, orukọ, ati gbogbo nkan to nii sẹ pẹlu fiimu "Ọkọ Iyabọ" jẹ awsn nkan to ṣẹlẹ, eleyi to le mu ki ojuṣaaju waye lori ẹjọ naa to ti wa ni ile ẹjọ. Iwa aibikiti to hu ti tabuku si orukọ ẹgbẹ wa. Ẹni ti wọn jọ dari ere naa, Ọgbẹni Dele Matti, ti fihan pe oun jẹbi, o ti ronu piwada, a si daa duro fun oṣu mẹta pere. A paṣẹ ki gbogbo ọmọ ẹgbẹ wa to kopa ninu fiimu naa yọju siwaju igbimọ to wa fun yiyanju aawọ ati ilana isẹ wa, ni ọjọ kẹrinlelogun, oṣu Keje, ọdun2021. Lakotan, ẹgbẹ TAMPAN sọ pe ẹgbẹ awọn eeyan to jẹ ọmọluabi ni oun, ti ko si ni ṣe atilẹyin fun ohunkohun to ba le da wahala silẹ ni awujọ.
Yomi Fabiyi Oko Iyabo: Ẹgbẹ́ TAMPAN ti dá Yomi Fabiyi dúró lẹ́yìn tó gbé fíímù Oko Iyabo jáde Saaju la ti mu iroyin wa fun yin pe apapọ ẹgbẹ awọn oṣere tiata ni Naijiria, TAMPAN ti fofin de Yomi Fabiyi pe ko lọ rọọkun nile na. Ninu atẹjade ti ẹgbẹ naa fi sita lọjọ Ẹti lo ti kede pe igbesẹ naa waye nitori iwa abuku ati eyi ti ko ba oju mu gẹgẹ bi oṣere ti Fabiyi hu nipa fiimu Ọkọ Iyabọ to gbe jade laipẹ yii. Fiimu naa to gbe jade ni ọjọ Aiku to kọja da lori ọrọ ẹsun ifipabanilopọ ti wọn fi kan osẹre miran, Baba Ijesha. TAMPAN sọ pe igbesẹ naa waye lẹyin ti oun gbọ awijare Yomi Fabiyi to jẹ olukọtan, olootu ati oludari fiimu naa, ati oludari keji, Ọgbẹni Dele Matti. "A ri pe wọn jẹbi hihu iwa ti ko bojumu fun akọṣẹmọṣẹ oni tiata. Awọn alaṣẹ TAMPAN sọ pe botilẹ jẹ pe Ọgbẹni Fabiyi taku pe ẹtọ oun gẹgẹ bi eniyan, ni lati gbe fiimu jade, eyi ti yoo sọ bi nakn ṣe ri gan-an lori iṣẹlẹ ọrọ Baba Ijesha, wọn ni alajọṣiṣẹpọ rẹ gba pe oun jẹbi, to si kabamọ ipa to ko ninu ṣiṣe fiimu naa. Ninu atẹjade ti ẹgbẹ naa fi si ori Instagram rẹ ni ikede naa ti jade. Awọn abajade iwadii ati idajọ ẹgbẹ TAMPAN nipa Yomi Fabiyi: Ọgbẹni Yomi Fabiyi mọọmọ ṣe fiimu naa lai bọwọ fun ilana to de fiimu ṣiṣe, eyi to tumọ si pe o sẹ isẹ naa pẹlu erongba lati da wahala silẹ laarin ilu. Ti iṣẹ naa (fiimu) kii ba ti i ṣe ti ile Sinima, ẹnikẹni ko ni ẹtọ lati lo orukọ eeyan ti iṣẹlẹ ṣẹlẹ si ninu fiimu. "Nitori naa, iwa aibikita ni bi Fabiyi ṣe lo orukọ, ati awọn iṣẹlẹ to waye loju aye, lai gba aṣẹ lọwọ awọn ti ọrọ kan. Ìtàn, agbekalẹ itan, ohùn, ọrọ, akori, orukọ, ati gbogbo nkan to nii sẹ pẹlu fiimu "Ọkọ Iyabọ" jẹ awsn nkan to ṣẹlẹ, eleyi to le mu ki ojuṣaaju waye lori ẹjọ naa to ti wa ni ile ẹjọ. Iwa aibikiti to hu ti tabuku si orukọ ẹgbẹ wa. Ẹni ti wọn jọ dari ere naa, Ọgbẹni Dele Matti, ti fihan pe oun jẹbi, o ti ronu piwada, a si daa duro fun oṣu mẹta pere. A paṣẹ ki gbogbo ọmọ ẹgbẹ wa to kopa ninu fiimu naa yọju siwaju igbimọ to wa fun yiyanju aawọ ati ilana isẹ wa, ni ọjọ kẹrinlelogun, oṣu Keje, ọdun2021. Lakotan, ẹgbẹ TAMPAN sọ pe ẹgbẹ awọn eeyan to jẹ ọmọluabi ni oun, ti ko si ni ṣe atilẹyin fun ohunkohun to ba le da wahala silẹ ni awujọ.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-57783258
4religion
Sotitobire: Ìdájọ́ òdòdò ló fẹsẹ̀ múlẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ Pásítọ̀ Sotitobire - Agbẹjọ́rò fún ìjọba
Ọjọ Iṣẹgun, ọjọ kẹfa, oṣu Kẹwaa, ọdun 2020 ni ile ẹjọ giga ti ijọba ipinlẹ Ondo dajọ ẹwọn gbere fun Alfa Babatunde, to jẹ oludasilẹ ijọ Sotitobire Praising Chapel, ati awọn ọmọ ijọ rẹ marun, ti wọn fi ẹsun kan pe wọn lọwọ si bi ọmọ ọdun kan, Gold Kolawole ṣe di awati ninu ijọ naa ni ọdun 2019. Bo tilẹ jẹ pe agbẹjọro fun ijọba ipinlẹ Ondo lori ẹjọ naa, Adekola Olawoye, sọ pe idajọ ododo lo waye lori ọrọ naa, nitori pe "bi irọ ba lọ logun ọdun, ọjọ kan ni otitọ yoo ba". Amọ agbẹjọro to ṣoju awọn olujẹjọ, Akinyemi Omoware, sọ fun BBC pe awọn yoo pe ẹjọ kotẹmilọrun lori idajọ ile ẹjọ giga ọhun. Mi ò fẹ́ di ọlọ́lá jùlọ tí mo bá di gómìnà Ondo, màá tẹ̀lé ìfẹ́ aráàlù póńbélé - Ojon YPP Ojú àwọn èèyàn Ondo ti là pé ìnira ni ẹgbẹ́ APC mú wá - Jegede PDP Àwọn kan ṣónú bí wọ́n bá di gómìnà, ẹ fún wa láyè láti wá parí iṣẹ́ táa bẹ̀rẹ̀ - Akeredolu 'N500 dé fún gbogbo ọmọ tuntun lóṣooṣù bí mo bá di gómìnà Ondo - Adeleye AAC
Sotitobire: Ìdájọ́ òdòdò ló fẹsẹ̀ múlẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ Pásítọ̀ Sotitobire - Agbẹjọ́rò fún ìjọba Ọjọ Iṣẹgun, ọjọ kẹfa, oṣu Kẹwaa, ọdun 2020 ni ile ẹjọ giga ti ijọba ipinlẹ Ondo dajọ ẹwọn gbere fun Alfa Babatunde, to jẹ oludasilẹ ijọ Sotitobire Praising Chapel, ati awọn ọmọ ijọ rẹ marun, ti wọn fi ẹsun kan pe wọn lọwọ si bi ọmọ ọdun kan, Gold Kolawole ṣe di awati ninu ijọ naa ni ọdun 2019. Bo tilẹ jẹ pe agbẹjọro fun ijọba ipinlẹ Ondo lori ẹjọ naa, Adekola Olawoye, sọ pe idajọ ododo lo waye lori ọrọ naa, nitori pe "bi irọ ba lọ logun ọdun, ọjọ kan ni otitọ yoo ba". Amọ agbẹjọro to ṣoju awọn olujẹjọ, Akinyemi Omoware, sọ fun BBC pe awọn yoo pe ẹjọ kotẹmilọrun lori idajọ ile ẹjọ giga ọhun. Mi ò fẹ́ di ọlọ́lá jùlọ tí mo bá di gómìnà Ondo, màá tẹ̀lé ìfẹ́ aráàlù póńbélé - Ojon YPP Ojú àwọn èèyàn Ondo ti là pé ìnira ni ẹgbẹ́ APC mú wá - Jegede PDP Àwọn kan ṣónú bí wọ́n bá di gómìnà, ẹ fún wa láyè láti wá parí iṣẹ́ táa bẹ̀rẹ̀ - Akeredolu 'N500 dé fún gbogbo ọmọ tuntun lóṣooṣù bí mo bá di gómìnà Ondo - Adeleye AAC
https://www.bbc.com/yoruba/54447371
3politics
Yemi Osinbajo: Èrò ọmọ Nàíjíríà ṣọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ lórí ìkéde Osinbajo láti dupò ààrẹ Nàìjíríà
Lowurọ ọjọ Aje, ọjọ kọkanla ọdun 2022, ni igbakeji aarẹ Naijiria, Ọjọgbọn Yemi Osinbajo kede erongba rẹ lati dije fun ipo aarẹ, fun gbogbo aye. Eyi si ti fa ọpọlọpọ itakurọsọ lori ayelujara ati lagbo ijiroro ọrọ oṣelu gbogbo. Kii ṣe ikede rẹ gan an lo n fa awuyewuye nitori ọpọlọpọ lo wulẹ ti n reti pe yoo ri bẹẹ. Amọṣa, ohun to n fa ariyanjiyan lori rẹ ko ju bi ọrọ naa yoo ṣe ja si laarin igbakeji aarẹ orilẹede Naijiria, Ọjọgbọn Yẹmi Oṣinbajo pẹlu Aṣiwaju Bọla Ahmed Tinubu to jẹ ọga rẹ tẹlẹ. Bi awọn kan ṣe n sọ pe ko yẹ ki erin fọn ki ọmọ rẹ naa tun fọn; lawọn miran n woye pe ko si bi ọbọ ṣe ṣe ori ti inaki ko ṣe o. 'N ṣe lo yẹ ki Tinubu gba adura pe ki Osinbajo ju oun lọ gẹgẹ bii baba si ọmọ - Igun Osinbajo sọrọ Ninu ifọrọwerọ pẹlu BBC News Yoruba, Amofin Kayọde Ajulọ to jẹ gbajumọ amofin, ajafẹtọ araalu to tun jẹ alabaṣepọ Igbakeji aarẹ Muhammadu Buhari ni igbesẹ ti ọpọlọpọ awọn ọmọ Naijiria ti n reti ni igbesẹ ti Osinbajo gbe naa. O ṣalaye pe idi ti igbesẹ ati kede erongba rẹ ṣe pẹ bayii ko to jade ko ju wi pe igbakeji aarẹ Naijiria naa nilo asiko lati forikori pẹlawọn eekan gbogbo kaakiri lati lee mọ ibi ti yoo gbe ọrọ gba. Lori boya ọrọ naa ko ni fara jọ ẹsun ọdalẹ ti awọn eeyan kan fi n kan igbakeji aarẹ pẹlu bi o ṣe fẹ dije tako Tinubu, ti ọpọ woye gẹgẹ bii oloore rẹ ni. Amofin Ajulọ ṣalaye pe, ni ilẹ Yoruba, gbogbo obi lo maa n gbadura ki ọmọ wọn ju awọn lọ. O darukọ awọn eekan ilẹ Yoruba bii Baba Abraham Adesanya, Baba Daodu, Baba Ayọ Adebanjọ ati Mama Abibatu Mọgaji maa n gba fun Aṣiwaju nigba naa ni pe yoo ga ju wọn lọ , to si ri bẹẹ. "Adura to yẹ ki aṣiwaju maa gba bayii fun Osinbajo bayii naa ni pe iwọ ọmọ mi o waa ga ju mi lọ." Ọrọ yii dabi ọmọ to fẹ ba baba rẹ du iyawo ni - Igun Tinubu ero rẹ Ninu ọrọ tirẹ, Abdulhakeen Adegoke, adari ẹgbẹ Yoruba Welfare Group ṣalaye fun BBC News yoruba pe ohun ti ko yẹ ko waye ni ikede erongba igbakeji aarẹ Osinbajo pe oun naa fẹ dije lẹyin ti ẹni ti a lee pe ni ọga ọga rẹ ti bọ si gbangba lati sọ pe oun fẹ dije fun ipo naa. Abdulhakeen Adegoke ni osibajo ti ṣi ẹsẹ gbe lori igbesẹ naa nitori ko si bi igbesẹ rẹ ko ṣe ni di igbesẹ Yoruba lati di aarẹ lowo ati pe ni iwoye toun o, itanje lasan lawon eekan ni apap ariwa Naijiria n fun un ti wọn n sọ oe awọn wa lẹyin. O wa rọ awọn agbagba Yoruba lati pe ajọ to nironu fun yiyanju ọrọ ọhun ki alaafia lee jọba laaarin awọn mejeeji. To ba jẹ pe ṣaaju igba ti Aṣiwaju kede tirẹ ni Osinbajo ti kede ni, ọpọ gan ni yoo maa rọ aṣiwaju pe ko sinmi naa ki ọmọ rẹ, iyẹn Aṣiwaju Osinbajo lee dije. "Ọrọ yii dabi ọmọ to fẹ ba baba to bii du iyawo. Ki awọn baba wa nilẹ Yoruba tete pe aro ati ọdọfin inu wa silẹ." Owurọ ọjọ kọkanla, oṣu Kẹrin, ọdun 2022, ni igbakeji aarẹ Naijiria, Ọjọgbọn Yemi Osinbajo kede erongba rẹ lati dije fun ipo aarẹ, fun gbogbo aye. Osinbajo ninu fidio kan to fi si oju opo Twitter rẹ lo ti kede igbesẹ naa. Eyi waye lẹyin to ti kọkọ kede fun awọn gomina kan to wa ninu ẹgbẹ osẹlu All Progressives Congress, APC, lọjọ Aiku. Igbakeji aarẹ, Yemi Osinbajo ti kede erongba rẹ lati dije fun ipo aarẹ Naijiria ninu eto idibo ọdun 2023. Osinbajo ninu fidio kan to fi si oju opo Twitter rẹ ni owurọ ọjọ Aje lo ti sisọ loju eegun pe oun maa dije fun ipo aarẹ. Osinbajo ni "Pẹlu irẹlẹ ọkan ni mo fi n kede erongba mi lati dije fun ipo aarẹ Naijiria labẹ asia ẹgbẹ oselu APC. A maa mu ẹkunrẹrẹ awọn koko ọrọ to sọ nipa erongba rẹ lati dije naa wa fun yin laipẹ. saaju la ti mu iroyin wa fun yin pe lẹyin ọpọlọpọ akoko ijiroro ati ifikuluku, o dabi ẹni pe igbakeji aarẹ orilẹede Naijiria, Ọjọgbọn Yẹmi Osinbajo ti ṣetan bayii lẹyin o rẹyin lati dije fun ipo aarẹ orilẹede Naijiria ldun 2023. Kii ṣe iroyin abẹnu mọ pe oniruuru ẹgbẹ, ọgba ati igun lo ti bọ sigboro lati gbe lẹyin agba amofin naa pe ki oun pẹlu darapọ mọ awọn oloṣelu to fẹ dije fun aṣia ẹgbẹ oṣelu APC fun ipo aarẹ lorilẹede Naijiria. Ni oṣu karun un ọdun 2022 ni eto idibo lati mọ ẹni ti ẹgbẹ oṣelu APC yoo fa kalẹ fun idije ipo aarẹ lasiko idibo apapọ ọdun 2023 yoo waye. Gẹgẹ bi awọn iroyin kan to jade lati ile aarẹ, Aso Rock Villa nilu Abuja lọjọ Aiku ṣe sọ, igbakeji aarẹ orilẹede Naijiria naa ti bun awọn gomina bii mejila kan gbọ nipa erongba rẹ lati dije. Iroyin naa sọ pe, Ọjọgbọn Yẹmi Osinbajo fi to awọn gomina naa ninu eyi ti Nasir El-Rufai (Kaduna), Dapo Abiodun (Ogun), Abdullahi Sule (Nasarawa), Babagana Zulum (Borno) ati Babajide Sanwo-Olu (Eko) leti lasiko apejẹ iṣinu awẹ Ramadan, Iftar to pe nibi to ti jẹ ko di mimọ fawọn gomina naa nipa erongba rẹ lati tẹsiwaju pẹlu iṣẹ ti ọga rẹ, Aarẹ Muhammadu Buhari ba ṣe ku lasiko ti saa iṣejọba rẹ ba pari ldun 2023. Bọla Tinubu jẹ ọkan lara awọn eekan ẹgbẹ oṣelu APC, ohun si ni gomina ipinlẹ Eko laarin ọdun 199 si 2007. Okorocha ni gomina ipinlẹ Imo tẹlẹ, igba akọkọ rẹ si kọ niyi lati dije, lẹyin to ti kọkọ gbe igba ibo fun ipo aarẹ labẹ ẹgbẹ oṣelu AA nigba kan ri. Rochas Okorocha fi erongba rẹ lati dije han ninu lẹta kan to kọ ranṣẹ si aarẹ ile aṣofin agba, Sẹnetọ Ahmad Lawan lọjọ kẹrindinlọgbọn oṣu kini ọdun 2022. Oun ni obinrin akọkọ to jade lati kede pe oun fẹ dije fun ipo aarẹ lọdun 2023. Ko tii kede ẹgbẹ oṣelu kankan ti o wa bayii na. Ohun to sọ ni pe ẹgbẹ oṣelu to ba ni iran kan naa pẹlu oun loun yoo ba lọ. loṣu kẹta ọdun 2023 ni Dele Mọmọdu kede pe oun naa yoo dije ipo aarẹ lẹgbẹ oṣelu PDP. Igba akọkọ kọ niyi ti Dele Mọmọdu yoo maa fifẹhan si didije fun ipo aarẹ ni Naijiria. Yahaya Bello ni gomina ipinlẹ Kogi lọwọ yii. Laipẹ yii loun pẹlu kede pe oun naa nifẹ si ipo aarẹ lọdun 2023. Awọn miran to tun ti gbe igbesẹ yii kan naa ni aarẹ ile aṣofin agba tẹlẹ ri, Dokita Bukọla Saraki, alaga igbimọ awọn gomina lorilẹede Naijiria, NGF to tun jẹ gomina ipinlẹ Ekiti, Ọmọwe Kayọde Fayẹmi, minisita fọrọ oṣiṣẹ ati igbanisiṣẹ, Dokita Chris Ngige ati bẹẹ lọ.
Yemi Osinbajo: Èrò ọmọ Nàíjíríà ṣọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ lórí ìkéde Osinbajo láti dupò ààrẹ Nàìjíríà Lowurọ ọjọ Aje, ọjọ kọkanla ọdun 2022, ni igbakeji aarẹ Naijiria, Ọjọgbọn Yemi Osinbajo kede erongba rẹ lati dije fun ipo aarẹ, fun gbogbo aye. Eyi si ti fa ọpọlọpọ itakurọsọ lori ayelujara ati lagbo ijiroro ọrọ oṣelu gbogbo. Kii ṣe ikede rẹ gan an lo n fa awuyewuye nitori ọpọlọpọ lo wulẹ ti n reti pe yoo ri bẹẹ. Amọṣa, ohun to n fa ariyanjiyan lori rẹ ko ju bi ọrọ naa yoo ṣe ja si laarin igbakeji aarẹ orilẹede Naijiria, Ọjọgbọn Yẹmi Oṣinbajo pẹlu Aṣiwaju Bọla Ahmed Tinubu to jẹ ọga rẹ tẹlẹ. Bi awọn kan ṣe n sọ pe ko yẹ ki erin fọn ki ọmọ rẹ naa tun fọn; lawọn miran n woye pe ko si bi ọbọ ṣe ṣe ori ti inaki ko ṣe o. 'N ṣe lo yẹ ki Tinubu gba adura pe ki Osinbajo ju oun lọ gẹgẹ bii baba si ọmọ - Igun Osinbajo sọrọ Ninu ifọrọwerọ pẹlu BBC News Yoruba, Amofin Kayọde Ajulọ to jẹ gbajumọ amofin, ajafẹtọ araalu to tun jẹ alabaṣepọ Igbakeji aarẹ Muhammadu Buhari ni igbesẹ ti ọpọlọpọ awọn ọmọ Naijiria ti n reti ni igbesẹ ti Osinbajo gbe naa. O ṣalaye pe idi ti igbesẹ ati kede erongba rẹ ṣe pẹ bayii ko to jade ko ju wi pe igbakeji aarẹ Naijiria naa nilo asiko lati forikori pẹlawọn eekan gbogbo kaakiri lati lee mọ ibi ti yoo gbe ọrọ gba. Lori boya ọrọ naa ko ni fara jọ ẹsun ọdalẹ ti awọn eeyan kan fi n kan igbakeji aarẹ pẹlu bi o ṣe fẹ dije tako Tinubu, ti ọpọ woye gẹgẹ bii oloore rẹ ni. Amofin Ajulọ ṣalaye pe, ni ilẹ Yoruba, gbogbo obi lo maa n gbadura ki ọmọ wọn ju awọn lọ. O darukọ awọn eekan ilẹ Yoruba bii Baba Abraham Adesanya, Baba Daodu, Baba Ayọ Adebanjọ ati Mama Abibatu Mọgaji maa n gba fun Aṣiwaju nigba naa ni pe yoo ga ju wọn lọ , to si ri bẹẹ. "Adura to yẹ ki aṣiwaju maa gba bayii fun Osinbajo bayii naa ni pe iwọ ọmọ mi o waa ga ju mi lọ." Ọrọ yii dabi ọmọ to fẹ ba baba rẹ du iyawo ni - Igun Tinubu ero rẹ Ninu ọrọ tirẹ, Abdulhakeen Adegoke, adari ẹgbẹ Yoruba Welfare Group ṣalaye fun BBC News yoruba pe ohun ti ko yẹ ko waye ni ikede erongba igbakeji aarẹ Osinbajo pe oun naa fẹ dije lẹyin ti ẹni ti a lee pe ni ọga ọga rẹ ti bọ si gbangba lati sọ pe oun fẹ dije fun ipo naa. Abdulhakeen Adegoke ni osibajo ti ṣi ẹsẹ gbe lori igbesẹ naa nitori ko si bi igbesẹ rẹ ko ṣe ni di igbesẹ Yoruba lati di aarẹ lowo ati pe ni iwoye toun o, itanje lasan lawon eekan ni apap ariwa Naijiria n fun un ti wọn n sọ oe awọn wa lẹyin. O wa rọ awọn agbagba Yoruba lati pe ajọ to nironu fun yiyanju ọrọ ọhun ki alaafia lee jọba laaarin awọn mejeeji. To ba jẹ pe ṣaaju igba ti Aṣiwaju kede tirẹ ni Osinbajo ti kede ni, ọpọ gan ni yoo maa rọ aṣiwaju pe ko sinmi naa ki ọmọ rẹ, iyẹn Aṣiwaju Osinbajo lee dije. "Ọrọ yii dabi ọmọ to fẹ ba baba to bii du iyawo. Ki awọn baba wa nilẹ Yoruba tete pe aro ati ọdọfin inu wa silẹ." Owurọ ọjọ kọkanla, oṣu Kẹrin, ọdun 2022, ni igbakeji aarẹ Naijiria, Ọjọgbọn Yemi Osinbajo kede erongba rẹ lati dije fun ipo aarẹ, fun gbogbo aye. Osinbajo ninu fidio kan to fi si oju opo Twitter rẹ lo ti kede igbesẹ naa. Eyi waye lẹyin to ti kọkọ kede fun awọn gomina kan to wa ninu ẹgbẹ osẹlu All Progressives Congress, APC, lọjọ Aiku. Igbakeji aarẹ, Yemi Osinbajo ti kede erongba rẹ lati dije fun ipo aarẹ Naijiria ninu eto idibo ọdun 2023. Osinbajo ninu fidio kan to fi si oju opo Twitter rẹ ni owurọ ọjọ Aje lo ti sisọ loju eegun pe oun maa dije fun ipo aarẹ. Osinbajo ni "Pẹlu irẹlẹ ọkan ni mo fi n kede erongba mi lati dije fun ipo aarẹ Naijiria labẹ asia ẹgbẹ oselu APC. A maa mu ẹkunrẹrẹ awọn koko ọrọ to sọ nipa erongba rẹ lati dije naa wa fun yin laipẹ. saaju la ti mu iroyin wa fun yin pe lẹyin ọpọlọpọ akoko ijiroro ati ifikuluku, o dabi ẹni pe igbakeji aarẹ orilẹede Naijiria, Ọjọgbọn Yẹmi Osinbajo ti ṣetan bayii lẹyin o rẹyin lati dije fun ipo aarẹ orilẹede Naijiria ldun 2023. Kii ṣe iroyin abẹnu mọ pe oniruuru ẹgbẹ, ọgba ati igun lo ti bọ sigboro lati gbe lẹyin agba amofin naa pe ki oun pẹlu darapọ mọ awọn oloṣelu to fẹ dije fun aṣia ẹgbẹ oṣelu APC fun ipo aarẹ lorilẹede Naijiria. Ni oṣu karun un ọdun 2022 ni eto idibo lati mọ ẹni ti ẹgbẹ oṣelu APC yoo fa kalẹ fun idije ipo aarẹ lasiko idibo apapọ ọdun 2023 yoo waye. Gẹgẹ bi awọn iroyin kan to jade lati ile aarẹ, Aso Rock Villa nilu Abuja lọjọ Aiku ṣe sọ, igbakeji aarẹ orilẹede Naijiria naa ti bun awọn gomina bii mejila kan gbọ nipa erongba rẹ lati dije. Iroyin naa sọ pe, Ọjọgbọn Yẹmi Osinbajo fi to awọn gomina naa ninu eyi ti Nasir El-Rufai (Kaduna), Dapo Abiodun (Ogun), Abdullahi Sule (Nasarawa), Babagana Zulum (Borno) ati Babajide Sanwo-Olu (Eko) leti lasiko apejẹ iṣinu awẹ Ramadan, Iftar to pe nibi to ti jẹ ko di mimọ fawọn gomina naa nipa erongba rẹ lati tẹsiwaju pẹlu iṣẹ ti ọga rẹ, Aarẹ Muhammadu Buhari ba ṣe ku lasiko ti saa iṣejọba rẹ ba pari ldun 2023. Bọla Tinubu jẹ ọkan lara awọn eekan ẹgbẹ oṣelu APC, ohun si ni gomina ipinlẹ Eko laarin ọdun 199 si 2007. Okorocha ni gomina ipinlẹ Imo tẹlẹ, igba akọkọ rẹ si kọ niyi lati dije, lẹyin to ti kọkọ gbe igba ibo fun ipo aarẹ labẹ ẹgbẹ oṣelu AA nigba kan ri. Rochas Okorocha fi erongba rẹ lati dije han ninu lẹta kan to kọ ranṣẹ si aarẹ ile aṣofin agba, Sẹnetọ Ahmad Lawan lọjọ kẹrindinlọgbọn oṣu kini ọdun 2022. Oun ni obinrin akọkọ to jade lati kede pe oun fẹ dije fun ipo aarẹ lọdun 2023. Ko tii kede ẹgbẹ oṣelu kankan ti o wa bayii na. Ohun to sọ ni pe ẹgbẹ oṣelu to ba ni iran kan naa pẹlu oun loun yoo ba lọ. loṣu kẹta ọdun 2023 ni Dele Mọmọdu kede pe oun naa yoo dije ipo aarẹ lẹgbẹ oṣelu PDP. Igba akọkọ kọ niyi ti Dele Mọmọdu yoo maa fifẹhan si didije fun ipo aarẹ ni Naijiria. Yahaya Bello ni gomina ipinlẹ Kogi lọwọ yii. Laipẹ yii loun pẹlu kede pe oun naa nifẹ si ipo aarẹ lọdun 2023. Awọn miran to tun ti gbe igbesẹ yii kan naa ni aarẹ ile aṣofin agba tẹlẹ ri, Dokita Bukọla Saraki, alaga igbimọ awọn gomina lorilẹede Naijiria, NGF to tun jẹ gomina ipinlẹ Ekiti, Ọmọwe Kayọde Fayẹmi, minisita fọrọ oṣiṣẹ ati igbanisiṣẹ, Dokita Chris Ngige ati bẹẹ lọ.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-61064215
5sports
IAAF World Championships: Abiyamọ kan di lobìnrin tó leè sáré "100 meters" jùlọ l'àgbáyé
Obinrin ọmọ ọdun mejilelogun kan lati orilẹ-ede Jamaica ti wọ inu iwe itan gẹgẹ bi obinrin to lee sare ori papa oniwọn ẹsẹ ọgọrun un julọ l'agbaye. Shelly-Ann Fraser-Pryce to jẹ ọlọmọ kan tun ni ẹni to dagba ju l'gbaye to gba ife ẹyẹ naa lẹyin to gba ife wura ni idije agbaye to n lọ lọwọ ni Doha, lorilẹ-ede Qatar. Dalemoṣu yii lo sa ere ori papa naa larin iṣẹju mẹwaa o le diẹ, lati gba ife ẹlẹẹkẹjọ iru rẹ ti yoo gba. Lẹyin to gba ife ẹyẹ naa tan, o ni inu oun dun gidigidi. O ṣalaye siwaju sii pe, aṣiri aṣeyọri oun ni iwa irẹlẹ ti oun ni ati bi oun ṣe mu iṣẹ oun lokunkundun. Bi o tilẹ jẹ pe ọpọlọpọ awọn ololufe ere ori papa ni ko yọju lati wo Shelly-Ann ni igba to n sa ere naa, o ni oun ko bikita rara. Ṣaaju akoko yii ni Shelly-Ann ti kopa ninu awọn idije agbaye miran bii; idije Olympic ti Beijin lọdun 2008, idije agbaye Berlin lọdun 2009, idije Olympic ti Londo lọdun 2012, ati bẹẹbẹẹ lọ.
IAAF World Championships: Abiyamọ kan di lobìnrin tó leè sáré "100 meters" jùlọ l'àgbáyé Obinrin ọmọ ọdun mejilelogun kan lati orilẹ-ede Jamaica ti wọ inu iwe itan gẹgẹ bi obinrin to lee sare ori papa oniwọn ẹsẹ ọgọrun un julọ l'agbaye. Shelly-Ann Fraser-Pryce to jẹ ọlọmọ kan tun ni ẹni to dagba ju l'gbaye to gba ife ẹyẹ naa lẹyin to gba ife wura ni idije agbaye to n lọ lọwọ ni Doha, lorilẹ-ede Qatar. Dalemoṣu yii lo sa ere ori papa naa larin iṣẹju mẹwaa o le diẹ, lati gba ife ẹlẹẹkẹjọ iru rẹ ti yoo gba. Lẹyin to gba ife ẹyẹ naa tan, o ni inu oun dun gidigidi. O ṣalaye siwaju sii pe, aṣiri aṣeyọri oun ni iwa irẹlẹ ti oun ni ati bi oun ṣe mu iṣẹ oun lokunkundun. Bi o tilẹ jẹ pe ọpọlọpọ awọn ololufe ere ori papa ni ko yọju lati wo Shelly-Ann ni igba to n sa ere naa, o ni oun ko bikita rara. Ṣaaju akoko yii ni Shelly-Ann ti kopa ninu awọn idije agbaye miran bii; idije Olympic ti Beijin lọdun 2008, idije agbaye Berlin lọdun 2009, idije Olympic ti Londo lọdun 2012, ati bẹẹbẹẹ lọ.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-49898089
2health
Coronavirus in Nigeria: Ǹjẹ́ ṣé òògùn apakòkòrò le pa ààrùn coronavirus?
Oriṣiiriṣii nnkan lawọn eeyan n sọ pe o le wo aarun coronavirus ti o ba gbogbo aye finra lọwọ. Laipẹ yii ni aarẹ orilẹede Amẹrika sọ oogun apakokoro pe o le wo aarun aarun coronavirus. Ko si ohun to jọ bẹẹ raa! Ajọ eto ilera lagbaye, WHO sọ pe iwadii si n lọ lọwọ lori ati wa oogun tabi abẹrẹ to le wo coronovirus ṣugbọn ko sii oogun rẹ bayii. Alaye lẹkunrẹrẹ fidio yii.
Coronavirus in Nigeria: Ǹjẹ́ ṣé òògùn apakòkòrò le pa ààrùn coronavirus? Oriṣiiriṣii nnkan lawọn eeyan n sọ pe o le wo aarun coronavirus ti o ba gbogbo aye finra lọwọ. Laipẹ yii ni aarẹ orilẹede Amẹrika sọ oogun apakokoro pe o le wo aarun aarun coronavirus. Ko si ohun to jọ bẹẹ raa! Ajọ eto ilera lagbaye, WHO sọ pe iwadii si n lọ lọwọ lori ati wa oogun tabi abẹrẹ to le wo coronovirus ṣugbọn ko sii oogun rẹ bayii. Alaye lẹkunrẹrẹ fidio yii.
https://www.bbc.com/yoruba/52416211
1entertainment
Yoruba Films: Òṣèrè tíátà Muideen Oladapo gbàràdá lórí ètò 'Ṣé o láyà?'
Oṣere tiata Yoruba, Muideen Oladapo fihan lori eto BBC Yoruba, ''Ṣe o Laya'' pe oun laya gbangba. Bi o ti n dahun awọn ibeere ti wọn bi i, bẹẹ naa lo n ṣe atupalẹ idahun rẹ si awọn ibeere naa. Muideen fihan pe oun gbọ ede Yoruba daadaa gẹgẹ bi oṣere ere tiata Yoruba.
Yoruba Films: Òṣèrè tíátà Muideen Oladapo gbàràdá lórí ètò 'Ṣé o láyà?' Oṣere tiata Yoruba, Muideen Oladapo fihan lori eto BBC Yoruba, ''Ṣe o Laya'' pe oun laya gbangba. Bi o ti n dahun awọn ibeere ti wọn bi i, bẹẹ naa lo n ṣe atupalẹ idahun rẹ si awọn ibeere naa. Muideen fihan pe oun gbọ ede Yoruba daadaa gẹgẹ bi oṣere ere tiata Yoruba.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-52339308
1entertainment
Mide Martins: Gbajúgbajà òṣèré ṣàlàyé ohun tí ojú rẹ̀ rí lóko sinimá
Kò sí iṣẹ́ tàbí òwò tí ènìyàn bá ń ṣe tí kò ní àwọn ewu tirẹ̀. Gbajúgbajà òṣèré tíátà, Mide Martins Abiodun ti tú pẹrẹpẹ́rẹ̀ ọ̀rọ̀ lórí ohun tí ojú rẹ̀ rí láìpẹ́ yìí nígbà tí ó ń ṣe sinimá rẹ̀ kan, Onitemi tó ṣẹ̀ṣẹ̀ jáde. Mide Martins ṣàlàyé pé lásìkò tí òun ń ya abala eré náà lọ́wọ́ ni ẹsẹ̀ òun yẹ̀ gẹ̀rẹ̀, tí òun ṣubú, tí òun sì forí gbá táńgaran àlẹ̀mọ́lé ìyẹn táìsì (tiles). Ó ní òun fi orí gbá taisi naa gidigidi àti pé Ọlọ́run ló yọ òun tí òun kò fi pàdánù ọpọlọ lórí ìjàmbá náà tó wáyé. Bákan náà ló fi kun pé Ọlọ́run ló kó òun yọ, tí òun fóríbọ́ lọ́wọ́ ìṣẹ̀lẹ̀ tí kò bá di ibá míì fún òun. Nígbà tó fi fọ́nrán kan nínú eré náà léde lórí ẹ̀rọ Instagram rẹ̀ dúpẹ́ lọ́wọ́ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ fún àtìlẹyìn tí wọ́n ṣe fún òun lórí sinimá náà. Kí ló ti ṣẹlẹ̀ sẹ́yìn laarin awọn osere tiata? Ní bí ọjọ́ mélòó sẹ́yìn ni Mide Martins fi fọ́nrán kan léde níbi tó ti ń sunkún nítorí pé ilé iṣẹ tó bá dòwòpọ̀ kọ̀ láti fi àwọn ibì kan nínú sinimá rẹ̀ tó ṣẹ̀ṣẹ̀ gbé jáde sí inú fíìmù náà. Nínú fọ́nrán náà ló ti ṣàlàyé gbogbo àwọn ohun tó là kọjá láti ri dájú pé iṣẹ́ náà kẹ́sẹ járí. Ìyá Rainbow bú sígbé nígbà tó ń ṣeré lọ́wọ́ Kìí ṣe ìgbà àkọ́kọ́ nìyìí tí àwọn òṣèré tíátà máa ń la ewu kọjá tàbí tí wọn yóò rí ìrírí tí yóò pa wọ́n lẹ́kún nígbà tí wọ́n bá ń ṣe iṣẹ́ òòjọ́ wọn. Yoruba ni ọrọ arokan nii fa ẹkun asunundakẹ wa nitori ẹkun lo n ba ikun wa, ọrọ lo si n ba moko moro wa. Nigba miran, ti ẹda ba si ro arokan, omije ni yoo maa ja bọ ni oju rẹ, o si le jẹ omije ayọ abi ti idakeji rẹ. Amọ ti ẹni to n ro arokan yii ba wa jẹ agbalagba, ti onitọ̀ọun si sadede maa wa ẹkun mu lairotẹlẹ, o ni ohun to ri. Bi ọrọ se jẹ ree pẹlu gbajumọ osere tiata kan, mama Idowu Phillips, ti ọpọ eeyan mọ si Mama Rainbow. Ọpọ osere tiata lo la ẹnu silẹ, lai le pa de mọ nigba ti Mama Rainbow bẹrẹ ẹkun alagbara yii. Oko ere tiata ni wọn wa, nibi ti wọn ti n ya sinima kan, ti wọn si fun iya agbalagba naa ni ojuse kan lati se. Mama Rainbow, ti yoo pe ẹni ọgọrin ọdun lọdun yii, ni wọn fun ni ojuse lati sun ẹkun ninu ere naa ni apa kan sinima ọhun. Amọ ọrọ naa kuro ni ere tabi awada nigba ti Mama Rainbow ko dakẹ ẹsun sisun, to si fi iriri igbe aye rẹ wọ inu ere to n se. Ojuse ti wọn fun naa lo se ni laanu pupọ, arokan ti Mama ro nipa ere naa, ati ọpọ ohun to sẹlẹ nile aye, ti oju rẹ ti ri si lo fa ẹkun asun un dakẹ naa wa. Ta ni Mide Martins? Gbajúgbajà òṣèré tíátà Yorùbá ní Mide Martins. Ó jẹ́ ọmọ bíbí gbajúgbajà òṣèré Funmi Martins tó di olóògbé lọdún 2002. Lẹ́yìn tí ìyá rẹ̀ papòdà ní Mide bẹ̀rẹ̀ eré tíátà láti ri pé orípa ìyá rẹ̀ kò parẹ́. Ní ọjọ́ kejìlá ọdún 1979 ni wọ́n bí Mide Martins. Ó fẹ́ adarí eré, Afeez Abiodun tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ mọ̀ sí Afeez ọwọ́ tí Ọlọ́run sì fi ọmọ ta wọ́n lọ́rẹ.
Mide Martins: Gbajúgbajà òṣèré ṣàlàyé ohun tí ojú rẹ̀ rí lóko sinimá Kò sí iṣẹ́ tàbí òwò tí ènìyàn bá ń ṣe tí kò ní àwọn ewu tirẹ̀. Gbajúgbajà òṣèré tíátà, Mide Martins Abiodun ti tú pẹrẹpẹ́rẹ̀ ọ̀rọ̀ lórí ohun tí ojú rẹ̀ rí láìpẹ́ yìí nígbà tí ó ń ṣe sinimá rẹ̀ kan, Onitemi tó ṣẹ̀ṣẹ̀ jáde. Mide Martins ṣàlàyé pé lásìkò tí òun ń ya abala eré náà lọ́wọ́ ni ẹsẹ̀ òun yẹ̀ gẹ̀rẹ̀, tí òun ṣubú, tí òun sì forí gbá táńgaran àlẹ̀mọ́lé ìyẹn táìsì (tiles). Ó ní òun fi orí gbá taisi naa gidigidi àti pé Ọlọ́run ló yọ òun tí òun kò fi pàdánù ọpọlọ lórí ìjàmbá náà tó wáyé. Bákan náà ló fi kun pé Ọlọ́run ló kó òun yọ, tí òun fóríbọ́ lọ́wọ́ ìṣẹ̀lẹ̀ tí kò bá di ibá míì fún òun. Nígbà tó fi fọ́nrán kan nínú eré náà léde lórí ẹ̀rọ Instagram rẹ̀ dúpẹ́ lọ́wọ́ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ fún àtìlẹyìn tí wọ́n ṣe fún òun lórí sinimá náà. Kí ló ti ṣẹlẹ̀ sẹ́yìn laarin awọn osere tiata? Ní bí ọjọ́ mélòó sẹ́yìn ni Mide Martins fi fọ́nrán kan léde níbi tó ti ń sunkún nítorí pé ilé iṣẹ tó bá dòwòpọ̀ kọ̀ láti fi àwọn ibì kan nínú sinimá rẹ̀ tó ṣẹ̀ṣẹ̀ gbé jáde sí inú fíìmù náà. Nínú fọ́nrán náà ló ti ṣàlàyé gbogbo àwọn ohun tó là kọjá láti ri dájú pé iṣẹ́ náà kẹ́sẹ járí. Ìyá Rainbow bú sígbé nígbà tó ń ṣeré lọ́wọ́ Kìí ṣe ìgbà àkọ́kọ́ nìyìí tí àwọn òṣèré tíátà máa ń la ewu kọjá tàbí tí wọn yóò rí ìrírí tí yóò pa wọ́n lẹ́kún nígbà tí wọ́n bá ń ṣe iṣẹ́ òòjọ́ wọn. Yoruba ni ọrọ arokan nii fa ẹkun asunundakẹ wa nitori ẹkun lo n ba ikun wa, ọrọ lo si n ba moko moro wa. Nigba miran, ti ẹda ba si ro arokan, omije ni yoo maa ja bọ ni oju rẹ, o si le jẹ omije ayọ abi ti idakeji rẹ. Amọ ti ẹni to n ro arokan yii ba wa jẹ agbalagba, ti onitọ̀ọun si sadede maa wa ẹkun mu lairotẹlẹ, o ni ohun to ri. Bi ọrọ se jẹ ree pẹlu gbajumọ osere tiata kan, mama Idowu Phillips, ti ọpọ eeyan mọ si Mama Rainbow. Ọpọ osere tiata lo la ẹnu silẹ, lai le pa de mọ nigba ti Mama Rainbow bẹrẹ ẹkun alagbara yii. Oko ere tiata ni wọn wa, nibi ti wọn ti n ya sinima kan, ti wọn si fun iya agbalagba naa ni ojuse kan lati se. Mama Rainbow, ti yoo pe ẹni ọgọrin ọdun lọdun yii, ni wọn fun ni ojuse lati sun ẹkun ninu ere naa ni apa kan sinima ọhun. Amọ ọrọ naa kuro ni ere tabi awada nigba ti Mama Rainbow ko dakẹ ẹsun sisun, to si fi iriri igbe aye rẹ wọ inu ere to n se. Ojuse ti wọn fun naa lo se ni laanu pupọ, arokan ti Mama ro nipa ere naa, ati ọpọ ohun to sẹlẹ nile aye, ti oju rẹ ti ri si lo fa ẹkun asun un dakẹ naa wa. Ta ni Mide Martins? Gbajúgbajà òṣèré tíátà Yorùbá ní Mide Martins. Ó jẹ́ ọmọ bíbí gbajúgbajà òṣèré Funmi Martins tó di olóògbé lọdún 2002. Lẹ́yìn tí ìyá rẹ̀ papòdà ní Mide bẹ̀rẹ̀ eré tíátà láti ri pé orípa ìyá rẹ̀ kò parẹ́. Ní ọjọ́ kejìlá ọdún 1979 ni wọ́n bí Mide Martins. Ó fẹ́ adarí eré, Afeez Abiodun tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ mọ̀ sí Afeez ọwọ́ tí Ọlọ́run sì fi ọmọ ta wọ́n lọ́rẹ.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-60744565
3politics
Ìlera Nnamdi Kanu ń burú si, àìsàn ń ṣe é láti inú - Agbẹjọ́rò
Ifeanyi Ejiofor agbẹjọro fun adari ikọ ajijagbara IPOB, Nnamdi Kanu, ti sọrọ sita lori ilera onibara rẹ lẹyin to lugbadi arun miiran. Ejiofor, ninu atẹjade to fi ransẹ sita fawọn akọroyin lọjọ Aje ni onibara oun ni arun to n se eeyan ni inu ati ẹnu, ti oloyinbo pe ni Gastrointestinal Distorder. O ni eyi to mu ki aya ma ta Kanu ni ọpọ igba. O tẹsiwaju pe ileẹjọ giga to wa niluu Abuja labẹ isakoso Adajọ Binta Nyako, palasẹ fun ajọ DSS lati pese ilera to peye fun Nnamdi Kanu sugbọn wọn kọ. O wa ke gbajawire sita lẹyin to ṣe abẹwo si adari IPOB naa ni ọọfisi awọn DSS niluu Abuja lọjọ Ajẹ. “Ni bayi, Nnamdi Kanu n jẹ irora nitori aisan yii, ti o si nilo itọju ni kiakia. “Sugbọn o ṣe ni laanu pe ajọ DSS ko fun ni anfani lati ṣe itọju ara ẹ. “Kete ti a gbọ, ni agbẹjọro agba wa Oloye Mike Ozekhome pasẹ pe ki a bẹrẹ isẹ lati fi ofin si ifiyajẹni naa. Igbakeji alaga ẹgbẹ oṣelu PDP tẹlẹ, Olabode George ti fi aidunnu rẹ han si bi ẹgbẹ oṣelu PDP ko ṣe ni nkan gboogi lati fi dije dupo ni ilẹ Yoruba ni idibo ọdun to n bọ. Ninu ọrọ rẹ lori eto tẹlifiṣọn Arise TV lo ti fi ero rẹ han. Bode George ni ẹgbẹ oṣelu PDP ko dabi ẹgbẹ oṣelu APC to jẹ pe iha Guusu Naijiria ni wọn ti mu ẹni ti yoo dije du ipo aarẹ ni Naijiria ni idibo ọdun to n bọ. Bio tilẹ jẹpe ko darukọ Bola Tinubu, o ṣe afiwe nipa rẹ ati ẹgbẹ oṣelu APC. O ni ti ilẹ Yoruba ko ba ni ipa kan patọ to fẹ lepa ninu eto idibo naa, ko si idi ti awọn eniyan ni ilẹ Yoruba yoo fi dibo fun ẹgbẹ oselu PDP. ‘’Bawo ni mo se fẹ se ipolongo idibo ni ilẹ Yoruba ki wọn wa dibo fun ẹni ti ẹgbẹ oṣelu gbe?’’ A gbọdọ mọ wipe ẹgbẹ oṣelu alatako PDP mu oludije sipo aarẹ ni ilẹ Yoruba nitori naa awọn ni ohun ti wọn fẹ ta, amọ kini ẹgbẹ oṣelu PDP fẹ ta fun awọn ara ilẹ Niajiria? ‘’Ki awn to wa ni iha Ariwa Niajiria fi ọrọ naa yẹ ara wọn wo, ṣe wọn le faramọ ki oludije sipo aarẹ, igbakeji rẹ ati alaga ẹgbẹ ki wọn wa lati iha Guusu Naijiria, se ara wọn le gba iru rẹ.’’ ‘’Ohun ti mo n sọ ni ki ẹ jẹ ki idajoẹ odoodo ati ṣiṣe didara laarin awọn eniyan jọ wọn loju.’’ ‘’Alaga ẹgbẹ oṣelu PDP, Iyorchia Ayu gbọdọ fi ipo silẹ’’
Ìlera Nnamdi Kanu ń burú si, àìsàn ń ṣe é láti inú - Agbẹjọ́rò Ifeanyi Ejiofor agbẹjọro fun adari ikọ ajijagbara IPOB, Nnamdi Kanu, ti sọrọ sita lori ilera onibara rẹ lẹyin to lugbadi arun miiran. Ejiofor, ninu atẹjade to fi ransẹ sita fawọn akọroyin lọjọ Aje ni onibara oun ni arun to n se eeyan ni inu ati ẹnu, ti oloyinbo pe ni Gastrointestinal Distorder. O ni eyi to mu ki aya ma ta Kanu ni ọpọ igba. O tẹsiwaju pe ileẹjọ giga to wa niluu Abuja labẹ isakoso Adajọ Binta Nyako, palasẹ fun ajọ DSS lati pese ilera to peye fun Nnamdi Kanu sugbọn wọn kọ. O wa ke gbajawire sita lẹyin to ṣe abẹwo si adari IPOB naa ni ọọfisi awọn DSS niluu Abuja lọjọ Ajẹ. “Ni bayi, Nnamdi Kanu n jẹ irora nitori aisan yii, ti o si nilo itọju ni kiakia. “Sugbọn o ṣe ni laanu pe ajọ DSS ko fun ni anfani lati ṣe itọju ara ẹ. “Kete ti a gbọ, ni agbẹjọro agba wa Oloye Mike Ozekhome pasẹ pe ki a bẹrẹ isẹ lati fi ofin si ifiyajẹni naa. Igbakeji alaga ẹgbẹ oṣelu PDP tẹlẹ, Olabode George ti fi aidunnu rẹ han si bi ẹgbẹ oṣelu PDP ko ṣe ni nkan gboogi lati fi dije dupo ni ilẹ Yoruba ni idibo ọdun to n bọ. Ninu ọrọ rẹ lori eto tẹlifiṣọn Arise TV lo ti fi ero rẹ han. Bode George ni ẹgbẹ oṣelu PDP ko dabi ẹgbẹ oṣelu APC to jẹ pe iha Guusu Naijiria ni wọn ti mu ẹni ti yoo dije du ipo aarẹ ni Naijiria ni idibo ọdun to n bọ. Bio tilẹ jẹpe ko darukọ Bola Tinubu, o ṣe afiwe nipa rẹ ati ẹgbẹ oṣelu APC. O ni ti ilẹ Yoruba ko ba ni ipa kan patọ to fẹ lepa ninu eto idibo naa, ko si idi ti awọn eniyan ni ilẹ Yoruba yoo fi dibo fun ẹgbẹ oselu PDP. ‘’Bawo ni mo se fẹ se ipolongo idibo ni ilẹ Yoruba ki wọn wa dibo fun ẹni ti ẹgbẹ oṣelu gbe?’’ A gbọdọ mọ wipe ẹgbẹ oṣelu alatako PDP mu oludije sipo aarẹ ni ilẹ Yoruba nitori naa awọn ni ohun ti wọn fẹ ta, amọ kini ẹgbẹ oṣelu PDP fẹ ta fun awọn ara ilẹ Niajiria? ‘’Ki awn to wa ni iha Ariwa Niajiria fi ọrọ naa yẹ ara wọn wo, ṣe wọn le faramọ ki oludije sipo aarẹ, igbakeji rẹ ati alaga ẹgbẹ ki wọn wa lati iha Guusu Naijiria, se ara wọn le gba iru rẹ.’’ ‘’Ohun ti mo n sọ ni ki ẹ jẹ ki idajoẹ odoodo ati ṣiṣe didara laarin awọn eniyan jọ wọn loju.’’ ‘’Alaga ẹgbẹ oṣelu PDP, Iyorchia Ayu gbọdọ fi ipo silẹ’’
https://www.bbc.com/yoruba/articles/cgrdm04dr3ro
1entertainment
Wọ́n ti yọ Portable bíi jìgá kúrò nínú àwọn tí yóò gba àmì ẹ̀yẹ ‘Headies’ nítorí wòtòwótò
Awọn to n ṣagbatẹru ami ẹyẹ Headies, ti yọ orukọ Habeeb Okikiola, ti ọpọ mọ si Portbale kuro lara awọn ti yoo lanfaani lati gba ami ẹyẹ naa lọdun yii. Ninu atẹjade kan loju opo Instagram ni ileeṣẹ Smooth Promotions Limited, to n ṣagbatẹru eto ami ẹyẹ naa ti fi ikede ọhun sita. Atẹjade naa ni “A kabamọ lati kede pe lẹyin awọn ọrọ kobakungbe ti ọgbẹni Okikiola, ti ọpọ mọ si Portable n sọ, eyii to mu ki ilẹeṣẹ ọlọpaa Naijiria atawọn araalu maa sọrọ nipa rẹ, a ti pinnu lati yọ Portable kuro lara awọn ti a fẹ fun ni ami ẹyẹ.” “Igbesẹ wa lati fofin de ọgbẹni Okikiola ko ṣẹyin awọn iwa kobakungbe kan to n wu lori ikanni ibanidọrẹ lori ayelujara.” “Lojọ karundinlọgbọ, oṣu Karun un, o dunkoko pe oun yoo pa, ati pe oun yoo ṣe ijamba fun awọn miran ti a fa kalẹ fun ami ẹyẹ naa ti kii ba ṣe oun lo gba ami ẹyẹ ọhun.” Atẹjade naa tẹsiwaju pe “Lọjọ kejidinlogun, oṣu Keje, ọdun 2022, ọgbẹni Okikiola sọ ninu fidio kan pe oun ni oun da ẹgbẹ okunkun ‘One million boys’to n da ilu ru silẹ.” “Ko tan sibẹ, lọjọ kẹtadinlogun, oṣu Kẹfa, ọdun 2022, ọgbẹni Habeeb Okikiola tun ya ara rẹ ninu fidio kan, nibi to ti paṣẹ fun awọn ọrẹ rẹ lati lu ọrẹ rẹ mii to fẹsun aṣemaṣe kan, iyẹn DJ Chicken, bii bara.” Lara ami ẹyẹ ti Headies fa Portable kalẹ fun tẹlẹ ni olorin to ta lẹnu julọ larin adugbo ati olorin to ṣẹṣẹ n bọ loke amọ ti irawọ rẹ ti tan. Iwọnba eeyan perete lo mọ Portable tẹlẹ, amọ irawọ rẹ buyọ lẹyin awo orin ‘Zazoo Zehh’ ti oun ati Olamide ati Pocolee gbe jade.
Wọ́n ti yọ Portable bíi jìgá kúrò nínú àwọn tí yóò gba àmì ẹ̀yẹ ‘Headies’ nítorí wòtòwótò Awọn to n ṣagbatẹru ami ẹyẹ Headies, ti yọ orukọ Habeeb Okikiola, ti ọpọ mọ si Portbale kuro lara awọn ti yoo lanfaani lati gba ami ẹyẹ naa lọdun yii. Ninu atẹjade kan loju opo Instagram ni ileeṣẹ Smooth Promotions Limited, to n ṣagbatẹru eto ami ẹyẹ naa ti fi ikede ọhun sita. Atẹjade naa ni “A kabamọ lati kede pe lẹyin awọn ọrọ kobakungbe ti ọgbẹni Okikiola, ti ọpọ mọ si Portable n sọ, eyii to mu ki ilẹeṣẹ ọlọpaa Naijiria atawọn araalu maa sọrọ nipa rẹ, a ti pinnu lati yọ Portable kuro lara awọn ti a fẹ fun ni ami ẹyẹ.” “Igbesẹ wa lati fofin de ọgbẹni Okikiola ko ṣẹyin awọn iwa kobakungbe kan to n wu lori ikanni ibanidọrẹ lori ayelujara.” “Lojọ karundinlọgbọ, oṣu Karun un, o dunkoko pe oun yoo pa, ati pe oun yoo ṣe ijamba fun awọn miran ti a fa kalẹ fun ami ẹyẹ naa ti kii ba ṣe oun lo gba ami ẹyẹ ọhun.” Atẹjade naa tẹsiwaju pe “Lọjọ kejidinlogun, oṣu Keje, ọdun 2022, ọgbẹni Okikiola sọ ninu fidio kan pe oun ni oun da ẹgbẹ okunkun ‘One million boys’to n da ilu ru silẹ.” “Ko tan sibẹ, lọjọ kẹtadinlogun, oṣu Kẹfa, ọdun 2022, ọgbẹni Habeeb Okikiola tun ya ara rẹ ninu fidio kan, nibi to ti paṣẹ fun awọn ọrẹ rẹ lati lu ọrẹ rẹ mii to fẹsun aṣemaṣe kan, iyẹn DJ Chicken, bii bara.” Lara ami ẹyẹ ti Headies fa Portable kalẹ fun tẹlẹ ni olorin to ta lẹnu julọ larin adugbo ati olorin to ṣẹṣẹ n bọ loke amọ ti irawọ rẹ ti tan. Iwọnba eeyan perete lo mọ Portable tẹlẹ, amọ irawọ rẹ buyọ lẹyin awo orin ‘Zazoo Zehh’ ti oun ati Olamide ati Pocolee gbe jade.
https://www.bbc.com/yoruba/articles/czr3e9nz1jgo
3politics
Wọ́n fẹ́ fi ìgbálẹ̀ àti pankẹ́rẹ́ lé mi kúrò láàfin torí Adeleke, Ọlọrun ló yọ mí  – Ataoja Osogbo
Ataoja ti ilu Osogbo, Oba Jimoh Oyetunji, ti ki gomina ti wọn ṣẹṣẹ dibo yan nipinlẹ Osun, Ademola Adeleke ku oriire. Ọba Oyetunji, ninu fidio kan to lu ori ayelujara pa, lasiko to n ki Adeleke nigba ti gomina tuntun naa ṣabẹwo si aafin rẹ sọ pe, awọn eeyan kan dunkoko mọ oun pe awọn yoo fi pankẹrẹ le oun kuro ninu afin amọ Ọlọrun lo ko oun yọ. Ti ẹ ko ba gbagbe, Adeleke ti kọkọ bẹ aafin Ataoja wo, nibi ti ọba alade naa ti gbe awọn jaduku kan to kọlu awọn alatilẹyin ẹgbẹ PDP ṣepe ninu aafin ọhun. Igbesẹ ti Ataoja gbe naa ko tẹ awọn araalu kan lọrun, eyii to mu ki wọn fẹsun kan ori ade ọhun pe o n ṣatilẹyin fun ẹgbẹ oṣelu kan ju awọn miran lọ. Amọ nigba ti Ataoja n sọrọ lasiko ti Adeleke de ba a lalejo lẹyin to jawe olubori ninu idibo gomina tan, o ni kii ṣe Adeleke nikan lo ṣe oriire, nitori oun naa ṣe oriire lẹyin idibo naa. O sọ pe awọn eeyan kan ko ba ti fi pankẹrẹ le oun danu kuro laafin. Ataoja ni “Mo ki gbogbo awa ti Ọlọrun yan gomina tuntun fun pe a ku oriire o, Ọlọrun yoo jẹ ki oriire naa o kalẹ.” “Ẹ jẹ ki wọn mọ pe ayọ mi ti de... ki wọn maa sọ pe awọn yoo fi igbalẹ gba mi bọ sita ninu aafin pẹlu pankẹrẹ.” “Ọlọrun lo yọ mi, kii ṣe Ademola nikan lo ṣoriire, Ataoja Jimoh naa ṣe oriire.” “Ki eku ile o gbọ, ko sọ fun t’oko, kii ṣe emi ni ẹ o fi pankẹrẹ le.” Ataoja pari ọrọ rẹ pe lagbara Ọlọrun, ti Adeleke ba pari saa rẹ tan, yoo ṣe ọdun mẹrin mii si, ti yoo fi pe ọdun mẹjọ lori oye. O wa fikun pe lẹyin naa ni oun yoo tun kede ẹlomiran ti yoo di gomina ipinlẹ Osun.
Wọ́n fẹ́ fi ìgbálẹ̀ àti pankẹ́rẹ́ lé mi kúrò láàfin torí Adeleke, Ọlọrun ló yọ mí  – Ataoja Osogbo Ataoja ti ilu Osogbo, Oba Jimoh Oyetunji, ti ki gomina ti wọn ṣẹṣẹ dibo yan nipinlẹ Osun, Ademola Adeleke ku oriire. Ọba Oyetunji, ninu fidio kan to lu ori ayelujara pa, lasiko to n ki Adeleke nigba ti gomina tuntun naa ṣabẹwo si aafin rẹ sọ pe, awọn eeyan kan dunkoko mọ oun pe awọn yoo fi pankẹrẹ le oun kuro ninu afin amọ Ọlọrun lo ko oun yọ. Ti ẹ ko ba gbagbe, Adeleke ti kọkọ bẹ aafin Ataoja wo, nibi ti ọba alade naa ti gbe awọn jaduku kan to kọlu awọn alatilẹyin ẹgbẹ PDP ṣepe ninu aafin ọhun. Igbesẹ ti Ataoja gbe naa ko tẹ awọn araalu kan lọrun, eyii to mu ki wọn fẹsun kan ori ade ọhun pe o n ṣatilẹyin fun ẹgbẹ oṣelu kan ju awọn miran lọ. Amọ nigba ti Ataoja n sọrọ lasiko ti Adeleke de ba a lalejo lẹyin to jawe olubori ninu idibo gomina tan, o ni kii ṣe Adeleke nikan lo ṣe oriire, nitori oun naa ṣe oriire lẹyin idibo naa. O sọ pe awọn eeyan kan ko ba ti fi pankẹrẹ le oun danu kuro laafin. Ataoja ni “Mo ki gbogbo awa ti Ọlọrun yan gomina tuntun fun pe a ku oriire o, Ọlọrun yoo jẹ ki oriire naa o kalẹ.” “Ẹ jẹ ki wọn mọ pe ayọ mi ti de... ki wọn maa sọ pe awọn yoo fi igbalẹ gba mi bọ sita ninu aafin pẹlu pankẹrẹ.” “Ọlọrun lo yọ mi, kii ṣe Ademola nikan lo ṣoriire, Ataoja Jimoh naa ṣe oriire.” “Ki eku ile o gbọ, ko sọ fun t’oko, kii ṣe emi ni ẹ o fi pankẹrẹ le.” Ataoja pari ọrọ rẹ pe lagbara Ọlọrun, ti Adeleke ba pari saa rẹ tan, yoo ṣe ọdun mẹrin mii si, ti yoo fi pe ọdun mẹjọ lori oye. O wa fikun pe lẹyin naa ni oun yoo tun kede ẹlomiran ti yoo di gomina ipinlẹ Osun.
https://www.bbc.com/yoruba/articles/cz9l5mq37r4o
5sports
Chichi Igbo: Ọ̀pọ̀ máa ń rò pé mo ní nǹkan ọkùnrin lábẹ́ torí ìrísí mi jọ ti ọkùnrin
Ọkan lara awọn ọmọ ẹgbẹ agbabọọlu lobinrin fun orilẹede Naijiria, Super Falcons, to ti fẹyin ti ni Chichi Igbo jẹ. Ọdun mejidinlogun si lo fi gba bọọlu, ko to fẹyin ti Chichi ni isan, idi ati egungun lile ju awọn ọkunrin miran lọ , ti irisi rẹ ko si yatọ si tawọn ọkunrin amọ obinrin ni. Nigba to n ba BBC sọrọ lori oju ati ohun ti awọn eeyan awujọ n sọ nipa rẹ, Chichi ni ọpọ eeyan lo ti fi ẹnu pa oun lai tii ku. O wa koro oju si awọn ọrọ ibajẹ ti ọpọ eeyan maa n sọ nipa rẹ nitori pe irisi rẹ jọ ti ọkunrin. O si gba awọn eeyan nimọran lati lati ye pa awọn eeyan nipa ọrọ ti wọn ba kọ lawọn oju opo itakun agbaye.
Chichi Igbo: Ọ̀pọ̀ máa ń rò pé mo ní nǹkan ọkùnrin lábẹ́ torí ìrísí mi jọ ti ọkùnrin Ọkan lara awọn ọmọ ẹgbẹ agbabọọlu lobinrin fun orilẹede Naijiria, Super Falcons, to ti fẹyin ti ni Chichi Igbo jẹ. Ọdun mejidinlogun si lo fi gba bọọlu, ko to fẹyin ti Chichi ni isan, idi ati egungun lile ju awọn ọkunrin miran lọ , ti irisi rẹ ko si yatọ si tawọn ọkunrin amọ obinrin ni. Nigba to n ba BBC sọrọ lori oju ati ohun ti awọn eeyan awujọ n sọ nipa rẹ, Chichi ni ọpọ eeyan lo ti fi ẹnu pa oun lai tii ku. O wa koro oju si awọn ọrọ ibajẹ ti ọpọ eeyan maa n sọ nipa rẹ nitori pe irisi rẹ jọ ti ọkunrin. O si gba awọn eeyan nimọran lati lati ye pa awọn eeyan nipa ọrọ ti wọn ba kọ lawọn oju opo itakun agbaye.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-53372798
3politics
2023: Kò ni sí àyè fún fóònù lílò nínú ojúkòó ìdìbò, ìdí rèé – INEC
Ajọ eleto idibo orilẹede Naijiria (INEC) ti tẹnumọ fifofin de lilo foonu alagbeka nibi ojuko idibo nigba ti gbogbo eniyan ba n kopa ninu eto idibo gbogbogbo ọdun to n bọ. Alaga ajọ eleto idibo naa, Ọjọgbọ Mahmood Yakubu sọ eyi ni ọjọ Aje nibi ipade apero ajọ naa pẹlu awọn tọrọ kan nipa koko ọrọ ti wọn ṣepade le lori, “ipa ti owo n n ni lori idibo.” Wọn n ṣe eyi ṣaaju idibo ọdun 2023. Lara awọn to kopa nibi ipade apero naa ni aṣoju ajọ ọlọpaa, ti ajọ EFCC, ti ajọ ICPC, ajọ to n ri si igbohunsafẹfẹ, awọn ileeṣẹ iroyin, awọn ẹgbẹ oṣiṣẹ ijọba atawọn olugbaninimọran laarin awọn ẹgbẹ oṣelu (IPAC). “Awọn araalu ko gbọdọ gba ki wọn fi owo tan wọn lati ra ibo wọn. Bakan naa, wọn gbudọ kopa gidi ninu fifopin si lilo owo lọna aitọ lasiko idibo nipa ki wọn maa fi ẹjọ iru nnkan bẹẹ sun ajọ INEC tabi awọn ajọ mii to lee kapa rẹ. Lafikun, Awọn adari oṣiṣẹ alaabo gbudọ rii daju pe eyi jẹ koko iṣẹ ayẹwo wọn ṣaaju ati lasiko idibo.” Yakubu sọ bẹẹ. Alaga ajọ INEC fi kun un pe ki awọn to maa n ni anfani lati ba araalu sọrọ ninu gbigbogun ti tita ati rira ibo, awọn bii: Ile ifowopamọ, awọn ile ijọsin, awọn adari ilu nigberiko, awọn oniroyin, ẹgbẹ oṣiṣẹ ijọba ati paapaa julọ, awọn araalu. “Ẹ jẹ ki n lo akoko yii lati fi ran gbogbo araalu leti pe ofin ti a gbe le lilo ẹrọ alagbeka foonu ni ojukoo idibo ṣi wa digbi. Fun igba diẹ bayii, a ti ṣe atunto awọn ibudo idibo wa ki wọn baa le gbe apoti idibo sunmọ ẹgbẹ ojuko idibo lati mu ilana idibo ya ati lati ṣe idiwọ fun awọn karanbani oludibo kan ti yoo fẹ maa fi iwe idibo ti wọn tẹka si han awọn to fẹ ra ibo”. “A n rọ awọn oludibo pe ki wọn ke si awọn oṣiṣẹ ajọ eleto idibo nigbakuugba ti wọn ba rii pe awọn eeyan n ru awọn ofin to ṣe koko yii.” O ni oun tun fẹ fi akoko naa fi da awọn ọmọ Naijiria loju pe awọn ni ipinu lati rii pe ilana ṣiṣe eto idibo ati abajade eto idibo to yanranti lo waye ni Naijria. “A nigbagbọ pe gbogbo ọmọ Naijiria gan fẹ ka ṣe bẹẹ ,” Yakubu sọ eyi. Yakubu wa fi da awọn araalu loju pe INEC yoo tẹsiwaju lati ṣe awọn igbesẹ ti yoo gbogun ti iwa tita ati rira ibo to si fi kun un pe awọn ni ifọkansin fun awọn araalu. O ni INEC ti fẹ ṣe amulo awọn ohun elo imọ ẹrọ igbalode lati rii daju idibo ti ko ni si idiwọ lo waye lọdun 2023. Igbakeji Ọga agba ọlọpaa, Bala Ciroma sọ pe awọn ti fi panpẹ ofin mu ọpọlọpọ awọn to kopa ninu ibo rira to si tun fi kun un ọpọlọpọ tọọgi lawọn ti mu ti wọn n foju wina ofin nile ẹjọ bayii. Gẹgẹ bo ṣe sọ, awọn ọlọpaa yoo tun fi iṣẹ kun iṣẹ wọn lati rii daju pe awọn oloṣelu to maa n lọ kaakiri pẹlu ẹru owo nla nla lati fa oju awọn oludibo mọra yoo bọ si gbaga ọlọpaa. Esi yii waye nigba ti aṣoju ẹgbẹ olugbaninimọran laarin awọn oloṣelu mẹnu ba ọrọ “ta ibo koo se’bẹ”. Bakan naa ni ọga agba ajọ to n ri si igbohunsafẹfẹ ka abala ofin wọn to ni ṣe pẹlu idibo fun awọn oniroyin to si ki wọn nilọ lati ma jẹ ki awọn oloṣelu lo wọn. \nO tun ni ki awọn ile iṣẹ igbohunsafẹfẹ rii pe wọn ni akọsilẹ awọn owo iṣẹ ti wọn ba gba lasiko idibo tori ile iṣẹ ti wọn ba gbamu pẹlu iwa to ru ofin alafia ilu ko ni lọ lai jẹ iya.
2023: Kò ni sí àyè fún fóònù lílò nínú ojúkòó ìdìbò, ìdí rèé – INEC Ajọ eleto idibo orilẹede Naijiria (INEC) ti tẹnumọ fifofin de lilo foonu alagbeka nibi ojuko idibo nigba ti gbogbo eniyan ba n kopa ninu eto idibo gbogbogbo ọdun to n bọ. Alaga ajọ eleto idibo naa, Ọjọgbọ Mahmood Yakubu sọ eyi ni ọjọ Aje nibi ipade apero ajọ naa pẹlu awọn tọrọ kan nipa koko ọrọ ti wọn ṣepade le lori, “ipa ti owo n n ni lori idibo.” Wọn n ṣe eyi ṣaaju idibo ọdun 2023. Lara awọn to kopa nibi ipade apero naa ni aṣoju ajọ ọlọpaa, ti ajọ EFCC, ti ajọ ICPC, ajọ to n ri si igbohunsafẹfẹ, awọn ileeṣẹ iroyin, awọn ẹgbẹ oṣiṣẹ ijọba atawọn olugbaninimọran laarin awọn ẹgbẹ oṣelu (IPAC). “Awọn araalu ko gbọdọ gba ki wọn fi owo tan wọn lati ra ibo wọn. Bakan naa, wọn gbudọ kopa gidi ninu fifopin si lilo owo lọna aitọ lasiko idibo nipa ki wọn maa fi ẹjọ iru nnkan bẹẹ sun ajọ INEC tabi awọn ajọ mii to lee kapa rẹ. Lafikun, Awọn adari oṣiṣẹ alaabo gbudọ rii daju pe eyi jẹ koko iṣẹ ayẹwo wọn ṣaaju ati lasiko idibo.” Yakubu sọ bẹẹ. Alaga ajọ INEC fi kun un pe ki awọn to maa n ni anfani lati ba araalu sọrọ ninu gbigbogun ti tita ati rira ibo, awọn bii: Ile ifowopamọ, awọn ile ijọsin, awọn adari ilu nigberiko, awọn oniroyin, ẹgbẹ oṣiṣẹ ijọba ati paapaa julọ, awọn araalu. “Ẹ jẹ ki n lo akoko yii lati fi ran gbogbo araalu leti pe ofin ti a gbe le lilo ẹrọ alagbeka foonu ni ojukoo idibo ṣi wa digbi. Fun igba diẹ bayii, a ti ṣe atunto awọn ibudo idibo wa ki wọn baa le gbe apoti idibo sunmọ ẹgbẹ ojuko idibo lati mu ilana idibo ya ati lati ṣe idiwọ fun awọn karanbani oludibo kan ti yoo fẹ maa fi iwe idibo ti wọn tẹka si han awọn to fẹ ra ibo”. “A n rọ awọn oludibo pe ki wọn ke si awọn oṣiṣẹ ajọ eleto idibo nigbakuugba ti wọn ba rii pe awọn eeyan n ru awọn ofin to ṣe koko yii.” O ni oun tun fẹ fi akoko naa fi da awọn ọmọ Naijiria loju pe awọn ni ipinu lati rii pe ilana ṣiṣe eto idibo ati abajade eto idibo to yanranti lo waye ni Naijria. “A nigbagbọ pe gbogbo ọmọ Naijiria gan fẹ ka ṣe bẹẹ ,” Yakubu sọ eyi. Yakubu wa fi da awọn araalu loju pe INEC yoo tẹsiwaju lati ṣe awọn igbesẹ ti yoo gbogun ti iwa tita ati rira ibo to si fi kun un pe awọn ni ifọkansin fun awọn araalu. O ni INEC ti fẹ ṣe amulo awọn ohun elo imọ ẹrọ igbalode lati rii daju idibo ti ko ni si idiwọ lo waye lọdun 2023. Igbakeji Ọga agba ọlọpaa, Bala Ciroma sọ pe awọn ti fi panpẹ ofin mu ọpọlọpọ awọn to kopa ninu ibo rira to si tun fi kun un ọpọlọpọ tọọgi lawọn ti mu ti wọn n foju wina ofin nile ẹjọ bayii. Gẹgẹ bo ṣe sọ, awọn ọlọpaa yoo tun fi iṣẹ kun iṣẹ wọn lati rii daju pe awọn oloṣelu to maa n lọ kaakiri pẹlu ẹru owo nla nla lati fa oju awọn oludibo mọra yoo bọ si gbaga ọlọpaa. Esi yii waye nigba ti aṣoju ẹgbẹ olugbaninimọran laarin awọn oloṣelu mẹnu ba ọrọ “ta ibo koo se’bẹ”. Bakan naa ni ọga agba ajọ to n ri si igbohunsafẹfẹ ka abala ofin wọn to ni ṣe pẹlu idibo fun awọn oniroyin to si ki wọn nilọ lati ma jẹ ki awọn oloṣelu lo wọn. \nO tun ni ki awọn ile iṣẹ igbohunsafẹfẹ rii pe wọn ni akọsilẹ awọn owo iṣẹ ti wọn ba gba lasiko idibo tori ile iṣẹ ti wọn ba gbamu pẹlu iwa to ru ofin alafia ilu ko ni lọ lai jẹ iya.
https://www.bbc.com/yoruba/articles/cn0j0ljv40ro
2health
Coronavirus: Ọ̀pọ̀ àwọn arìnrìnàjò wá sí Nàíjíríà ló kọjá àbẹ̀wò tó lágbára
Nibayii ti arun Coronavirus ti wọ orilẹede Naijiria, ijọba wa ko sun rara, lati dena itankalẹ arun naa. Amọ ijọba wa ti n gbe igbesẹ lati dena itankalẹ arun naa bayi bẹrẹ lati awọn papakọ ofurufu ilẹ wa. BBC Yoruba ṣe abẹwo si papakọ ofurufu wa, ta si ri itu meje ti awọn osisẹ ibẹ n pa lati ri pe wọn se ayẹwo fun awọn eeyan naa. Ẹ wo fidio yii lati mọ bo se n lọ nibẹ.
Coronavirus: Ọ̀pọ̀ àwọn arìnrìnàjò wá sí Nàíjíríà ló kọjá àbẹ̀wò tó lágbára Nibayii ti arun Coronavirus ti wọ orilẹede Naijiria, ijọba wa ko sun rara, lati dena itankalẹ arun naa. Amọ ijọba wa ti n gbe igbesẹ lati dena itankalẹ arun naa bayi bẹrẹ lati awọn papakọ ofurufu ilẹ wa. BBC Yoruba ṣe abẹwo si papakọ ofurufu wa, ta si ri itu meje ti awọn osisẹ ibẹ n pa lati ri pe wọn se ayẹwo fun awọn eeyan naa. Ẹ wo fidio yii lati mọ bo se n lọ nibẹ.
https://www.bbc.com/yoruba/afrika-51687918
End of preview. Expand in Data Studio
README.md exists but content is empty.
Downloads last month
29